Gẹnẹsisi 18 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 18:1-33

Àwọn àlejò mẹ́ta

1Olúwa sì farahan Abrahamu nítòsí àwọn igi ńlá Mamre, bí ó ti jókòó ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ rẹ̀, nígbà tí ọjọ́-kanrí tí oòrùn sì mú. 218.2: Hb 13.2.Abrahamu gbójú sókè, ó sì rí àwọn ọkùnrin mẹ́ta tí wọn dúró nítòsí rẹ̀. Nígbà tí ó rí wọn, ó sáré láti lọ pàdé wọn, ó sì tẹríba bí ó ti ń kí wọn.

3Ó wí pé, “Bí mo bá rí ojúrere yín Olúwa mi, ẹ má ṣe lọ láì yà sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ yín. 4Ẹ jẹ́ kí a bu omi díẹ̀ wá kí ẹ̀yin kí ó wẹ ẹsẹ̀ yín, kí ẹ sì sinmi lábẹ́ igi níhìn-ín. 5Ẹ jẹ́ kí n wá oúnjẹ wá fún un yín, kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ, kí ara sì tù yín, kí ẹ si tẹ̀síwájú ní ọ̀nà yín, nígbà tí ẹ ti yà ní ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ yín.”

Wọn sì wí pé “Ó dára.”

6Abrahamu sì yára tọ Sara aya rẹ̀ lọ nínú àgọ́, ó wí pé, “Tètè mú òṣùwọ̀n ìyẹ̀fun dáradára mẹ́ta kí o sì pò ó pọ̀, kí o sì ṣe oúnjẹ.”

7Abrahamu sì tún sáré lọ sí ibi agbo ẹran, ó sì mú ọmọ màlúù kan fún ìránṣẹ́ rẹ̀, ìránṣẹ́ náà sì tètè ṣè é. 8Ó sì mú wàrà àti mílíìkì àti màlúù tí ó ti pèsè, ó sì gbé síwájú wọn. Ó sì dúró nítòsí wọn lábẹ́ igi bí wọn ti ń jẹ ẹ́.

9Wọn béèrè pé, “Sara aya rẹ ńkọ́?”

Ó dáhùn pé, “Ó wà nínú àgọ́.”

1018.10: Ro 9.9.Nígbà náà ni Olúwa wí fún un pé, “Èmi yóò sì tún padà tọ̀ ọ́ wá nítòótọ́ ní ìwòyí àmọ́dún; Sara aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.”

Sara sì ń dẹtí gbọ́ láti ẹnu-ọ̀nà àgọ́ tí ó wà lẹ́yìn ọkùnrin náà. 11Abrahamu àti Sara sì ti di arúgbó: Sara sì ti kọjá àsìkò ìbímọ. 1218.12: 1Pt 3.6.Nítorí náà, Sara rẹ́rìn-ín nínú ara rẹ̀ bí ó ti ń rò ó lọ́kàn rẹ̀ pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo ti di arúgbó tán tí olúwa mi pẹ̀lú sì ti gbó jọ̀kújọ̀kú, èmi yóò ha tún lè bímọ?”

13Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abrahamu pé, “Kín ló dé tí Sara fi rẹ́rìn-ín tí ó sì wí pé, ‘Èmi yóò ha bímọ nítòótọ́, nígbà tí mo di ẹni ogbó tán?’ 1418.14: Mt 19.26; Mk 10.27; Lk 1.37; Ro 9.9.Ǹjẹ́ ohunkóhun wà tí ó ṣòro jù fún Olúwa? Èmi ó padà tọ̀ ọ́ wá ní ìwòyí àmọ́dún, Sara yóò sì bí ọmọkùnrin.”

15Ẹ̀rù sì ba Sara, ó sì sẹ́ pé òun kò rẹ́rìn-ín.

Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Dájúdájú ìwọ rẹ́rìn-ín.”

Abrahamu bẹ Olúwa nítorí Sodomu

16Nígbà tí àwọn ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, wọn kọjú sí ọ̀nà Sodomu, Abrahamu sì sìn wọ́n dé ọ̀nà. 17Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ǹjẹ́ èmi yóò ha pa ohun tí mo fẹ́ ṣe mọ́ fún Abrahamu bí? 1818.18: Gẹ 12.3; Ap 3.25; Ga 3.8.Dájúdájú Abrahamu yóò sá à di orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára, àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni a ó bùkún fún nípasẹ̀ rẹ̀. 19Nítorí tí èmi ti yàn án láti kọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ará ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, láti máa pa ọ̀nà Olúwa mọ nípa ṣíṣe olóòtítọ́ àti olódodo: kí Olúwa le è mú ìlérí rẹ̀ fún Abrahamu ṣẹ.”

20Olúwa sì wí pé, igbe Sodomu àti Gomorra pọ̀ púpọ̀ àti pé ẹ̀ṣẹ̀ wọn burú jọjọ. 21“Èmi yóò sọ̀kalẹ̀ síbẹ̀ láti ṣe ìwádìí igbe tí ó dé sí etí ìgbọ́ mi nípa wọn, kí èmi sì mọ òtítọ́ tí ó wà níbẹ̀.”

22Àwọn ọkùnrin náà yí padà, wọ́n sì ń lọ sí ìhà Sodomu. Ṣùgbọ́n Abrahamu dúró níbẹ̀ níwájú Olúwa. 23Nígbà náà ni Abrahamu súnmọ́ ọ̀dọ̀ Olúwa, ó sì wí pé, “Ìwọ yóò ha pa olódodo ènìyàn àti ènìyàn búburú run papọ̀ bí?” 24“Bí ó bá ṣe pé Ìwọ rí àádọ́ta olódodo nínú ìlú náà, Ìwọ yóò ha run ún, Ìwọ kì yóò ha dá ìlú náà sí nítorí àwọn àádọ́ta olódodo tí ó wà nínú rẹ̀ náà? 25Kò jẹ́ rí bẹ́ẹ̀! Dájúdájú Ìwọ kì yóò ṣe ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀, láti pa olódodo pẹ̀lú àwọn ènìyàn rere àti àwọn ènìyàn búburú. Dájúdájú, Ìwọ kì yóò ṣe èyí tí ó tọ́ bi?”

26Olúwa wí pé, “Bí mo bá rí àádọ́ta (50) olódodo ní ìlú Sodomu, èmi yóò dá ìlú náà sí nítorí tiwọn.”

27Abrahamu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Wò ó nísinsin yìí, níwọ̀n bí èmi ti ní ìgboyà láti bẹ̀rẹ̀ sí sọ̀rọ̀ níwájú Olúwa, èmi ẹni tí í ṣe erùpẹ̀ àti eérú, 28bí ó bá ṣe pe olódodo márùn-dínláàádọ́ta (45) ni ó wà nínú ìlú, Ìwọ yóò ha pa ìlú náà run nítorí ènìyàn márùn-ún bí?”

Olúwa dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo márùn-dínláàádọ́ta nínú rẹ̀.”

29Òun sì tún wí lẹ́ẹ̀kan si pé, “Bí ó bá ṣe pé ogójì (40) ni ńkọ́?”

Olúwa sì tún wí pé, “Èmi kì yóò pa ìlú náà run bí mo bá rí olódodo ogójì nínú rẹ̀.”

30Abrahamu sì tún bẹ Olúwa pé, “Kí Olúwa má ṣe bínú, ṣùgbọ́n èmi yóò sọ̀rọ̀. Bí ó bá ṣe pé ọgbọ̀n (30) ni a rí níbẹ̀ ńkọ́?”

Olúwa dáhùn pé, “Bí mó bá rí ọgbọ̀n, Èmi kì yóò pa ìlú run.”

31Abrahamu wí pé, “Níwọ́n bí mo ti ní ìgboyà láti bá Olúwa sọ̀rọ̀ báyìí, jẹ́ kí n tẹ̀síwájú. Bí o bá ṣe pé olódodo ogún péré ni ó wà nínú ìlú náà ńkọ́?”

Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi kì yóò pa á run nítorí ogún ènìyàn náà.”

32Abrahamu sì wí pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú Olúwa. Jẹ́ kí ń béèrè lẹ́ẹ̀kan si. Bí ó bá ṣe pé ènìyàn mẹ́wàá ni ó jẹ́ olódodo ńkọ́?”

Olúwa wí pé, “Nítorí ènìyàn mẹ́wàá náà, Èmi kì yóò pa á run.”

33Olúwa sì bá tirẹ̀ lọ, nígbà tí ó bá Abrahamu sọ̀rọ̀ tán, Abrahamu sì padà sílé.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

Начало 18:1-33

Три гостя Ибрахима

1Вечный явился Ибрахиму у великих деревьев Мамре, когда тот сидел у входа в свой шатёр во время дневного зноя. 2Ибрахим поднял взгляд и увидел, что неподалёку стоят три человека; увидев их, он побежал от входа в шатёр им навстречу и поклонился до земли.

3Он сказал:

– Если я нашёл милость в Твоих глазах, Владыка, то не пройди мимо Твоего раба. 4Пусть принесут немного воды, чтобы вам вымыть ноги и отдохнуть под этим деревом, 5а я принесу вам что-нибудь поесть. Вы подкрепитесь и продолжите свой путь – раз уж вы пришли ко мне, вашему рабу.

– Очень хорошо, – ответили они. – Делай, как говоришь.

6И Ибрахим поспешил в шатёр к Сарре и сказал:

– Скорее, достань три меры18:6 Букв.: «три саты», что равняется 22 л (примерно 14 кг муки). лучшей муки, замеси тесто и испеки лепёшек.

7Затем он побежал к стаду, выбрал лучшего, нежного телёнка и отдал слуге, который быстро приготовил его. 8Потом он принёс творога, молока и приготовленного телёнка и поставил перед ними. Пока они ели, он стоял рядом с ними под деревом.

9– Где твоя жена Сарра? – спросили они.

– Там, в шатре, – ответил он.

10Тогда Вечный сказал:

– Я непременно вернусь к тебе в следующем году, примерно в это же время, и у Сарры, твоей жены, будет сын.

Сарра слушала, стоя у Него за спиной, у входа в шатёр. 11Ибрахим и Сарра были уже стары и в преклонных годах, и то, что обычно бывает у женщин, у Сарры прекратилось. 12Поэтому Сарра рассмеялась про себя, подумав: «Я уже состарилась, и господин мой стар; мне ли иметь ещё такую радость?»

13Тогда Вечный сказал Ибрахиму:

– Почему Сарра смеётся и говорит: «Неужели у меня в самом деле будет ребёнок, ведь я стара?» 14Есть ли что-нибудь слишком трудное для Вечного? Я вернусь к вам через год в назначенное время, и у Сарры будет сын.

15Сарра испугалась и солгала, сказав:

– Я не смеялась.

Но Он сказал:

– Нет, ты смеялась.

Просьба Ибрахима о сохранении города Содома

16Гости поднялись и пошли в сторону Содома. Ибрахим отправился с ними, чтобы проводить их.

17Вечный сказал:

– Скрою ли Я от Ибрахима то, что собираюсь сделать? 18От Ибрахима непременно произойдёт великий и сильный народ, и все народы на земле получат благословение через него. 19Ведь Я избрал его, чтобы он заповедал своим детям и всем своим потомкам хранить путь Вечного, поступая правильно и справедливо, чтобы Вечный исполнил то, что обещал Ибрахиму.

20Вечный сказал:

– Вопль против Содома и Гоморры так велик, их грех так тяжек, 21что Я сойду и посмотрю, верен ли вопль, достигший Меня, так ли скверно они поступают. Если нет, Я узнаю.

22Двое мужчин повернулись и пошли к Содому, но Вечный остался со стоящим перед Ним Ибрахимом. 23Ибрахим приблизился к Нему и сказал:

– Неужели Ты уничтожишь праведного вместе с грешным? 24Что, если в городе есть пятьдесят праведников? Неужели Ты уничтожишь и не пощадишь этого места ради пятидесяти праведников? 25Не можешь Ты сделать такое – погубить праведного вместе с нечестивым, обойтись с праведным и нечестивым одинаково. Не можешь Ты сделать так! Разве Судья всей земли может творить неправду?

26Вечный сказал:

– Если Я найду в Содоме пятьдесят праведников, то пощажу ради них всё это место.

27Тогда Ибрахим сказал вновь:

– Вот я осмелился говорить с Владыкой, хотя я лишь прах и пепел; 28что, если число праведных на пять меньше пятидесяти? Уничтожишь ли Ты весь город из-за пяти человек?

– Если Я найду там сорок пять, – ответил Вечный, – то не уничтожу его.

29Ибрахим обратился к Нему ещё раз:

– Что, если там найдутся лишь сорок?

Вечный ответил:

– Ради сорока Я не сделаю этого.

30Тогда тот сказал:

– Да не разгневается Владыка, но позволит мне сказать. Что, если найдутся там только тридцать?

Вечный ответил:

– Я не сделаю этого, если найду там тридцать.

31Ибрахим сказал:

– Вот я был так смел, что решился говорить Владыке: что, если найдутся там лишь двадцать?

Вечный сказал:

– Ради двадцати Я не уничтожу его.

32Тогда Ибрахим сказал:

– Да не разгневается Владыка, но позволит мне сказать ещё лишь один раз. Что, если найдутся там лишь десять?

Вечный ответил:

– Ради десяти Я не уничтожу его.

33Когда Вечный закончил говорить с Ибрахимом, Он ушёл, а Ибрахим вернулся домой.