Gẹnẹsisi 14 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 14:1-24

Abramu gba Lọti là

1Ní àsìkò yìí ni Amrafeli ọba Ṣinari, Arioku ọba Ellasari, Kedorlaomeri ọba Elamu àti Tidali ọba Goyimu 2jáde lọ láti bá Bera ọba Sodomu, Birṣa ọba Gomorra, Ṣenabu ọba Adma, Ṣemeberi ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí nì ni Soari) jagun. 3Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí ni ó kó ogun wọn jọ pọ̀ sí Àfonífojì Siddimu (Òkun iyọ̀). 4Fún ọdún méjìlá gbáko ni wọ́n ti ń sin Kedorlaomeri bí ẹrú. Ṣùgbọ́n nígbà tí ó di ọdún kẹtàlá wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i.

5Ní ọdún kẹrìnlá, ni Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí wọ́n ti jọ ni májẹ̀mú àṣepọ̀ wá, wọ́n ṣígun, wọ́n sì ṣẹ́gun ará Refaimu ní Aṣteroti-Karnaimu, àwọn ará Susimu ni Hamu, àwọn ará Emimu ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Kiriataimu, 6àti àwọn ará Hori ní orí òkè wọ̀n-ọn-nì Seiri, títí ó fi dé Eli-Parani ní etí ijù. 7Wọ́n sì tún yípadà lọ sí En-Miṣpati (èyí yìí ni Kadeṣi), wọ́n sì ṣẹ́gun gbogbo ilẹ̀ àwọn Amaleki, àti àwọn ará Amori tí ó tẹ̀dó sí Hasason Tamari pẹ̀lú.

8Nígbà náà ni ọba Sodomu, ọba Gomorra, ọba Adma, ọba Ṣeboimu àti ọba Bela (èyí ni Soari), kó àwọn ọmọ-ogun wọn, wọ́n sì pa ibùdó ogun wọn sí Àfonífojì Siddimu, 9láti kojú ìjà sí Kedorlaomeri ọba Elamu, Tidali ọba Goyimu, Amrafeli ọba Ṣinari àti Arioku ọba Ellasari (ọba mẹ́rin kọjú ìjà sí ọba márùn-ún). 10Àfonífojì Siddimu sì kún fún kòtò ọ̀dà-ilẹ̀, nígbà tí ọba Sodomu àti ọba Gomorra sì sá, díẹ̀ nínú àwọn ọkùnrin ogun náà ṣubú sínú àwọn kòtò náà, àwọn tókù sì sálọ sì orí òkè. 11Àwọn ọba mẹ́rẹ̀ẹ̀rin náà sì kó gbogbo ẹrù Sodomu àti Gomorra àti oúnjẹ wọn; wọ́n sì lọ. 12Wọ́n sì mú Lọti ọmọ arákùnrin Abramu tí ń gbé ní Sodomu àti gbogbo ohun ìní rẹ̀.

13Ẹnìkan tí ó sá àsálà sì wá ròyìn fún Abramu, ará Heberu ni. Abramu sá ti tẹ̀dó sí ẹ̀gbẹ́ igi ńlá igbó Mamre ará Amori, arákùnrin Eṣkolu àti Aneri: àwọn ẹni tí ó ń bá Abramu ní àṣepọ̀. 14Nígbà tí Abramu gbọ́ wí pé, a di Lọti ní ìgbèkùn, ó kó àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ tí a bí sí ilẹ̀ rẹ̀ tí ó sì ti kọ́ ni ogun jíjà jáde, wọ́n jẹ́ okòó-lé-lọ́ọ̀dúnrún ó dín méjì ènìyàn (318), ó sì lépa wọn títí dé Dani. 15Ní ọ̀gànjọ́ òru, Abramu pín àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sí méjì, ó sì kọlù wọ́n, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì lé wọn títí dé Hoba tí ó wà ní apá òsì Damasku. 16Gbogbo ìkógun ni ó rí gbà padà àti ọmọ arákùnrin rẹ̀, Lọti pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, àti àwọn obìnrin pẹ̀lú àwọn ènìyàn tókù.

1714.17-20: Hb 7.1-10.Nígbà tí Abramu ti ṣẹ́gun Kedorlaomeri àti àwọn ọba tí ó pẹ̀lú rẹ̀, ọba Sodomu lọ pàdé rẹ̀ ní Àfonífojì Ṣafe (èyí tí ó túmọ̀ sí Àfonífojì Ọba).

18Melkisedeki ọba Salẹmu (Jerusalẹmu) sì mú oúnjẹ àti ọtí wáìnì jáde wá. Òun ni àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo. 19Ó sì súre fún Abramu wí pé,

“Ìbùkún ni fún Abramu ti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo

Ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.

20Ìbùkún sì ni fún Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ,

tí ó fi àwọn ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́.”

Abramu sì fún un ní ìdámẹ́wàá ohun gbogbo.

21Ọba Sodomu sì wí fún Abramu pé, “Kó àwọn ènìyàn mi fún mi, ṣùgbọ́n mú àwọn ẹrù fún ara rẹ.”

22Ṣùgbọ́n Abramu dá ọba Sodomu lóhùn pé, “Mo ti búra fún Olúwa, Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ó dá ọ̀run àti ayé, mo sì ti gbọ́wọ́ sókè, 23pé, èmi kì yóò mú láti fọ́nrán òwú títí dé okùn bàtà, àti pé, èmi kí yóò mú ohun kan tí ṣe tìrẹ, kí ìwọ kí ó má ba à wí pé, ‘Mo sọ Abramu di ọlọ́rọ̀.’ 24Èmi kì yóò gba ohunkóhun yàtọ̀ sí ohun tí àwọn ọkùnrin mi ti jẹ́, ṣùgbọ́n fi ìpín fún àwọn ọkùnrin tí ó bá mi lọ, Aneri, Eṣkolu àti Mamre. Jẹ́ kí wọn kí ó gba ìpín wọn.”

Bibelen på hverdagsdansk

1. Mosebog 14:1-24

Abram redder Lot

1På det tidspunkt udbrød der krig i landet. Amrafel, kongen af Shinear, Arjok, kongen af Ellasar, Kedorlaomer, kongen af Elam, og Tidal, kongen af Gojim, 2kæmpede mod Bera, kongen af Sodoma, Birsha, kongen af Gomorra, Shinab, kongen af Adma, Shemeber, kongen af Sebojim, og kongen af Bela—også kaldet Zoar.

3De sidstnævnte konger allierede sig og mobiliserede deres hære i Siddims dal ved Det Døde Hav.14,3 På hebraisk: Salthavet. 4I 12 år havde de været undertrykt af Kedorlaomer, men i det trettende år gjorde de oprør, 5og nu i det fjortende år var Kedorlaomer og hans allierede på vej imod dem. Efter at disse allierede hære havde slået refaitterne i Ashterot-Karnajim, zuzitterne i Ham, emitterne på Kirjatajimsletten 6og horitterne i Seirs bjerge og forfulgt dem helt til El-Paran ved ørkenens udkant, 7vendte de om og kom til En-Mishpat—det senere Kadesh—hvor de slog amalekitterne og de amoritter, der boede i Hatzetzon-Tamar.

8Men nu rykkede kongerne af Sodoma, Gomorra, Adma, Sebojim og Bela altså ud i Siddims dal imod 9kong Kedorlaomer og hans allierede. Det var fire konger mod fem. 10Siddims dal var imidlertid fuld af asfaltgruber, og da Sodomas og Gomorras konger blev slået på flugt, faldt nogle af deres folk ned i gruberne, mens resten flygtede op i bjergene. 11Sejrherrerne kunne nu uden videre plyndre Sodoma og Gomorra for ejendele og levnedsmidler, hvorefter de drog bort. 12De tog Lot, Abrams nevø, og alt hvad han ejede, med sig—for han boede jo i Sodoma. 13En mand, som var undsluppet, kom og fortalte hebræeren Abram, hvad der var sket. Abram boede stadig i egelunden, der tilhørte amoritten Mamre, som var bror til Eshkol og Aner—Abrams allierede.

14Da Abram hørte, at Lot var taget til fange, sammenkaldte han alle sine mandlige slaver, 318 i alt, og satte efter Kadorlaomers folk, til han indhentede dem oppe ved Dan. 15Han og folkene spredte sig, og i nattens løb overrumplede de fjenderne, slog dem og forfulgte dem helt til Hoba nord for Damaskus. 16Det lykkedes på den måde Abram at befri Lot og de øvrige krigsfanger, og han tog alt det med tilbage, som fjenderne havde taget i krigsbytte.

Melkizedek velsigner Abram

17Da Abram vendte tilbage efter sejren over Kedorlaomer og de andre konger, kom Sodomas konge ham i møde i Shavedalen—også kaldet Kongedalen. 18Også Melkizedek, Jerusalems konge, som var den højeste Guds præst, kom ham i møde. Han havde brød og vin med. 19-20Han velsignede Abram med følgende ord: „Lovet være den højeste Gud, han, som er himlens og jordens skaber, han, som gav dig sejr over dine fjender. Må den højeste Guds velsignelse hvile over dig, Abram.” Så gav Abram ham en tiendedel af alt krigsbyttet.

21Sodomas konge sagde til Abram: „Giv mig bare mine tilfangetagne folk tilbage. Krigsbyttet må du beholde.”

22Men Abram svarede: „Jeg sværger ved Herren, den højeste Gud, himlens og jordens Skaber, 23at jeg ikke vil tage noget, som tilhører dig, ikke så meget som en tråd eller en sandalrem! Du skal ikke senere kunne sige, at du gjorde Abram rig. 24Men lad mine unge mænd få betaling for deres arbejde, og giv mine allierede, Aner, Eshkol og Mamre, deres del af krigsbyttet.”