Gẹnẹsisi 1 – YCB & CST

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 1:1-31

Ìbẹ̀rẹ̀ dídá ayé

11.1: Jh 1.1.Ní ìbẹ̀rẹ̀ ohun gbogbo Ọlọ́run dá àwọn ọ̀run àti ayé. 2Ayé sì wà ní rúdurùdu, ó sì ṣófo, òkùnkùn sì wà lójú ibú omi, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì ń rábàbà lójú omi.

31.3: 2Kọ 4.6.Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà,” ìmọ́lẹ̀ sì wà. 4Ọlọ́run rí i pé ìmọ́lẹ̀ náà dára, ó sì ya ìmọ́lẹ̀ náà sọ́tọ̀ kúrò lára òkùnkùn. 5Ọlọ́run sì pe ìmọ́lẹ̀ náà ní “Ọ̀sán” àti òkùnkùn ní “Òru.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní.

61.6-8: 2Pt 3.5.Ọlọ́run sì wí pé “Jẹ́ kí òfúrufú kí ó wà ní àárín àwọn omi, láti pààlà sí àárín àwọn omi.” 7Ọlọ́run sì dá òfúrufú láti ya omi tí ó wà ní òkè òfúrufú kúrò lára omi tí ó wà ní orí ilẹ̀. Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 8Ọlọ́run sì pe òfúrufú ní “Ọ̀run,” àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kejì.

9Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi abẹ́ ọ̀run wọ́ papọ̀ sí ojú kan, kí ilẹ̀ gbígbẹ sì farahàn.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 10Ọlọ́run sì pe ilẹ̀ gbígbẹ náà ní “ilẹ̀,” àti àpapọ̀ omi ní “òkun.” Ọlọ́run sì rí i wí pé ó dára.

11Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó hu ọ̀gbìn: ewéko ti yóò máa mú èso wá àti igi tí yóò máa so èso ní irú tirẹ̀, tí ó ní irúgbìn nínú.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 12Ilẹ̀ sì hù ọ̀gbìn: ewéko tí ó ń so èso ní irú tirẹ̀, àti igi tí ń so èso, tí ó ní irúgbìn nínú ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì ri pé ó dára. 13Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ jẹ́ ọjọ́ kẹta.

14Ọlọ́run sì wí pé “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà ní ojú ọ̀run, láti pààlà sí àárín ọ̀sán àti òru, kí wọn ó sì máa wà fún ààmì láti mọ àwọn àsìkò, àti àwọn ọjọ́ àti àwọn ọdún, 15Kí wọn ó jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ní ojú ọ̀run, láti tan ìmọ́lẹ̀ sí orí ilẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 16Ọlọ́run dá ìmọ́lẹ̀ ńláńlá méjì, ìmọ́lẹ̀ tí ó tóbi láti ṣe àkóso ọ̀sán àti ìmọ́lẹ̀ tí ó kéré láti ṣe àkóso òru. Ó sì dá àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú. 17Ọlọ́run sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ sí ojú ọ̀run láti máa tan ìmọ́lẹ̀ si orí ilẹ̀, 18láti ṣàkóso ọ̀sán àti òru àti láti pààlà sí àárín ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn: Ọlọ́run sì rí i pé ó dára. 19Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ jẹ́ ọjọ́ kẹrin.

20Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi kí ó kún fún àwọn ohun alààyè, kí àwọn ẹyẹ kí ó sì máa fò ní òfúrufú.” 21Nítorí náà Ọlọ́run dá àwọn ẹ̀dá alààyè ńláńlá sí inú Òkun, àwọn ohun ẹlẹ́mìí àti àwọn ohun tí ń rìn ní onírúurú tiwọn, àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́ ní onírúurú tiwọn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára. 22Ọlọ́run súre fún wọn, ó sì wí pé, “Ẹ máa bí sí i, ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ kún inú omi Òkun, kí àwọn ẹyẹ náà sì máa pọ̀ sí i ní orí ilẹ̀.” 23Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ jẹ́ ọjọ́ karùn-ún.

24Ọlọ́run sì wí pé, “Kí ilẹ̀ kí ó mú ohun alààyè jáde ní onírúurú wọn: ẹran ọ̀sìn, àwọn ohun afàyàfà àti àwọn ẹran inú igbó, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní irú tirẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 25Ọlọ́run sì dá ẹranko inú igbó àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ní irú tirẹ̀ àti gbogbo ohun alààyè tí ń rìn ní ilẹ̀ ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.

261.26,27: Gẹ 5.1; Mt 19.4; Mk 10.6; Kl 3.10; Jk 3.9.Lẹ́yìn náà ni Ọlọ́run wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a dá ènìyàn ní àwòrán ara wa, gẹ́gẹ́ bí àwa ti rí, kí wọn kí ó jẹ ọba lórí ẹja Òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run, ẹran ọ̀sìn, gbogbo ilẹ̀ àti lórí ohun gbogbo tí ń rìn lórí ilẹ̀.”

271.27,28: Gẹ 5.1,2.1.27: Mt 19.4; Mk 10.6.Nítorí náà, Ọlọ́run dá ènìyàn ní àwòrán ara rẹ̀,

ní àwòrán Ọlọ́run ni Ó dá a,

akọ àti abo ni Ó dá wọn.

28Ọlọ́run sì súre fún wọn, Ọlọ́run sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, kí ẹ sì gbilẹ̀, kí ẹ ṣe ìkápá ayé. Ẹ ṣe àkóso àwọn ẹja inú Òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó ń rìn ní orí ilẹ̀.”

29Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo fi gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ń so èso fún un yín bí oúnjẹ àti àwọn igi eléso pẹ̀lú. Gbogbo rẹ̀ yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín. 30Àti fún àwọn ẹranko inú igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ohun afàyàfà: gbogbo ohun tó ní èémí ìyè nínú ni mo fi ewéko fún bí oúnjẹ.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.

31Ọlọ́run sì rí àwọn ohun gbogbo tí ó dá, ó dára gidigidi. Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀, ó jẹ́ ọjọ́ kẹfà.

Nueva Versión Internacional (Castilian)

Génesis 1:1-31

La creación

1Dios, en el principio,

creó los cielos y la tierra.

2La tierra era un caos total,

las tinieblas cubrían el abismo,

y el Espíritu1:2 Espíritu. Alt. viento o soplo. de Dios se movía

sobre la superficie de las aguas.

3Y dijo Dios: «¡Que exista la luz!»

Y la luz llegó a existir.

4Dios consideró que la luz era buena

y la separó de las tinieblas.

5A la luz la llamó «día»,

y a las tinieblas, «noche».

Y vino la noche, y llegó la mañana:

ese fue el primer día.

6Y dijo Dios: «¡Que exista el firmamento

en medio de las aguas, y que las separe!»

7Y así sucedió: Dios hizo el firmamento

y separó las aguas que están abajo,

de las aguas que están arriba.

8Al firmamento Dios lo llamó «cielo».

Y vino la noche, y llegó la mañana:

ese fue el segundo día.

9Y dijo Dios: «¡Que las aguas debajo del cielo

se reúnan en un solo lugar,

y que aparezca lo seco!»

Y así sucedió. 10A lo seco Dios lo llamó «tierra»,

y al conjunto de aguas lo llamó «mar».

Y Dios consideró que esto era bueno.

11Y dijo Dios: «¡Que haya vegetación sobre la tierra;

que esta produzca hierbas que den semilla,

y árboles que den su fruto con semilla,

todos según su especie!»

Y así sucedió. 12Comenzó a brotar la vegetación:

hierbas que dan semilla,

y árboles que dan su fruto con semilla,

todos según su especie.

Y Dios consideró que esto era bueno.

13Y vino la noche, y llegó la mañana:

ese fue el tercer día.

14Y dijo Dios: «¡Que haya luces en el firmamento

que separen el día de la noche;

que sirvan como señales de las estaciones,

de los días y de los años,

15y que brillen en el firmamento

para iluminar la tierra!»

Y sucedió así. 16Dios hizo los dos grandes astros:

el astro mayor para gobernar el día,

y el menor para gobernar la noche.

También hizo las estrellas.

17Dios colocó en el firmamento

los astros para alumbrar la tierra.

18Los hizo para gobernar el día y la noche,

y para separar la luz de las tinieblas.

Y Dios consideró que esto era bueno.

19Y vino la noche, y llegó la mañana:

ese fue el cuarto día.

20Y dijo Dios: «¡Que rebosen de seres vivientes las aguas,

y que vuelen las aves sobre la tierra

a lo largo del firmamento!»

21Y creó Dios los grandes animales marinos,

y todos los seres vivientes

que se mueven y pululan en las aguas

y todas las aves,

según su especie.

Y Dios consideró que esto era bueno,

22y los bendijo con estas palabras:

«Sed fructíferos y multiplicaos;

llenad las aguas de los mares.

¡Que las aves se multipliquen sobre la tierra!»

23Y vino la noche, y llegó la mañana:

ese fue el quinto día.

24Y dijo Dios: «¡Que produzca la tierra seres vivientes:

animales domésticos, animales salvajes

y reptiles, según su especie!»

Y sucedió así. 25Dios hizo los animales domésticos,

los animales salvajes y todos los reptiles,

según su especie.

Y Dios consideró que esto era bueno,

26y dijo: «Hagamos al ser humano

a nuestra imagen y semejanza.

Que tenga dominio sobre los peces del mar,

y sobre las aves del cielo;

sobre los animales domésticos,

sobre los animales salvajes,1:26 los animales salvajes (Siríaca); toda la tierra (TM).

y sobre todos los reptiles

que se arrastran por el suelo».

27Y Dios creó al ser humano a su imagen;

lo creó a imagen de Dios.

Hombre y mujer los creó,

28y los bendijo con estas palabras:

«Sed fructíferos y multiplicaos;

llenad la tierra y sometedla;

dominad a los peces del mar y a las aves del cielo,

y a todos los reptiles que se arrastran por el suelo».

29También les dijo: «Yo os doy de la tierra

todas las plantas que producen semilla

y todos los árboles que dan fruto con semilla;

todo esto os servirá de alimento.

30Y doy la hierba verde como alimento

a todas las fieras de la tierra,

a todas las aves del cielo

y a todos los seres vivientes

que se arrastran por la tierra».

Y así sucedió. 31Dios miró todo lo que había hecho,

y consideró que era muy bueno.

Y vino la noche, y llegó la mañana:

ese fue el sexto día.