Gẹnẹsisi 1 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Gẹnẹsisi 1:1-31

Ìbẹ̀rẹ̀ dídá ayé

11.1: Jh 1.1.Ní ìbẹ̀rẹ̀ ohun gbogbo Ọlọ́run dá àwọn ọ̀run àti ayé. 2Ayé sì wà ní rúdurùdu, ó sì ṣófo, òkùnkùn sì wà lójú ibú omi, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì ń rábàbà lójú omi.

31.3: 2Kọ 4.6.Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà,” ìmọ́lẹ̀ sì wà. 4Ọlọ́run rí i pé ìmọ́lẹ̀ náà dára, ó sì ya ìmọ́lẹ̀ náà sọ́tọ̀ kúrò lára òkùnkùn. 5Ọlọ́run sì pe ìmọ́lẹ̀ náà ní “Ọ̀sán” àti òkùnkùn ní “Òru.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní.

61.6-8: 2Pt 3.5.Ọlọ́run sì wí pé “Jẹ́ kí òfúrufú kí ó wà ní àárín àwọn omi, láti pààlà sí àárín àwọn omi.” 7Ọlọ́run sì dá òfúrufú láti ya omi tí ó wà ní òkè òfúrufú kúrò lára omi tí ó wà ní orí ilẹ̀. Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 8Ọlọ́run sì pe òfúrufú ní “Ọ̀run,” àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kejì.

9Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi abẹ́ ọ̀run wọ́ papọ̀ sí ojú kan, kí ilẹ̀ gbígbẹ sì farahàn.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 10Ọlọ́run sì pe ilẹ̀ gbígbẹ náà ní “ilẹ̀,” àti àpapọ̀ omi ní “òkun.” Ọlọ́run sì rí i wí pé ó dára.

11Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó hu ọ̀gbìn: ewéko ti yóò máa mú èso wá àti igi tí yóò máa so èso ní irú tirẹ̀, tí ó ní irúgbìn nínú.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 12Ilẹ̀ sì hù ọ̀gbìn: ewéko tí ó ń so èso ní irú tirẹ̀, àti igi tí ń so èso, tí ó ní irúgbìn nínú ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì ri pé ó dára. 13Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ jẹ́ ọjọ́ kẹta.

14Ọlọ́run sì wí pé “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà ní ojú ọ̀run, láti pààlà sí àárín ọ̀sán àti òru, kí wọn ó sì máa wà fún ààmì láti mọ àwọn àsìkò, àti àwọn ọjọ́ àti àwọn ọdún, 15Kí wọn ó jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ní ojú ọ̀run, láti tan ìmọ́lẹ̀ sí orí ilẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 16Ọlọ́run dá ìmọ́lẹ̀ ńláńlá méjì, ìmọ́lẹ̀ tí ó tóbi láti ṣe àkóso ọ̀sán àti ìmọ́lẹ̀ tí ó kéré láti ṣe àkóso òru. Ó sì dá àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú. 17Ọlọ́run sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ sí ojú ọ̀run láti máa tan ìmọ́lẹ̀ si orí ilẹ̀, 18láti ṣàkóso ọ̀sán àti òru àti láti pààlà sí àárín ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn: Ọlọ́run sì rí i pé ó dára. 19Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ jẹ́ ọjọ́ kẹrin.

20Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi kí ó kún fún àwọn ohun alààyè, kí àwọn ẹyẹ kí ó sì máa fò ní òfúrufú.” 21Nítorí náà Ọlọ́run dá àwọn ẹ̀dá alààyè ńláńlá sí inú Òkun, àwọn ohun ẹlẹ́mìí àti àwọn ohun tí ń rìn ní onírúurú tiwọn, àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́ ní onírúurú tiwọn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára. 22Ọlọ́run súre fún wọn, ó sì wí pé, “Ẹ máa bí sí i, ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ kún inú omi Òkun, kí àwọn ẹyẹ náà sì máa pọ̀ sí i ní orí ilẹ̀.” 23Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ jẹ́ ọjọ́ karùn-ún.

24Ọlọ́run sì wí pé, “Kí ilẹ̀ kí ó mú ohun alààyè jáde ní onírúurú wọn: ẹran ọ̀sìn, àwọn ohun afàyàfà àti àwọn ẹran inú igbó, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní irú tirẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀. 25Ọlọ́run sì dá ẹranko inú igbó àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ní irú tirẹ̀ àti gbogbo ohun alààyè tí ń rìn ní ilẹ̀ ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.

261.26,27: Gẹ 5.1; Mt 19.4; Mk 10.6; Kl 3.10; Jk 3.9.Lẹ́yìn náà ni Ọlọ́run wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a dá ènìyàn ní àwòrán ara wa, gẹ́gẹ́ bí àwa ti rí, kí wọn kí ó jẹ ọba lórí ẹja Òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run, ẹran ọ̀sìn, gbogbo ilẹ̀ àti lórí ohun gbogbo tí ń rìn lórí ilẹ̀.”

271.27,28: Gẹ 5.1,2.1.27: Mt 19.4; Mk 10.6.Nítorí náà, Ọlọ́run dá ènìyàn ní àwòrán ara rẹ̀,

ní àwòrán Ọlọ́run ni Ó dá a,

akọ àti abo ni Ó dá wọn.

28Ọlọ́run sì súre fún wọn, Ọlọ́run sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, kí ẹ sì gbilẹ̀, kí ẹ ṣe ìkápá ayé. Ẹ ṣe àkóso àwọn ẹja inú Òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó ń rìn ní orí ilẹ̀.”

29Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo fi gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ń so èso fún un yín bí oúnjẹ àti àwọn igi eléso pẹ̀lú. Gbogbo rẹ̀ yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín. 30Àti fún àwọn ẹranko inú igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ohun afàyàfà: gbogbo ohun tó ní èémí ìyè nínú ni mo fi ewéko fún bí oúnjẹ.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.

31Ọlọ́run sì rí àwọn ohun gbogbo tí ó dá, ó dára gidigidi. Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀, ó jẹ́ ọjọ́ kẹfà.

Bibelen på hverdagsdansk

1. Mosebog 1:1-31

Hvordan Gud skaber universet

1I begyndelsen skabte Gud himlen og jorden. 2Jorden var øde og tom, og urdybet lå hen i totalt mørke, men Guds Ånd svævede over de mørke vande.

3Så sagde Gud: „Der skal blive lys!” og så var der lys. 4Gud glædede sig over lyset, og han satte skel mellem lyset og mørket. 5Tiden med lys kaldte han dag, og tiden med mørke kaldte han nat. Det blev aften, og det blev morgen. Det var den første dag.

6Så sagde Gud: „Der skal være en hvælving midt i alt vandet til at dele det.” 7Og Gud dannede en hvælving, så vandet ovenfor den blev adskilt fra vandet nedenfor den. 8Hvælvingen kaldte han himmel. Det blev aften, og det blev morgen. Det var den anden dag.

9Dernæst sagde Gud: „Vandet under himmelhvælvingen skal samle sig, så det tørre land kommer til syne.” Og sådan skete det. 10Det tørre land kaldte han jord, og de steder, hvor vandet var, kaldte han hav; og Gud glædede sig over sit værk.

11Derpå sagde Gud: „Grønne planter, der bærer frø, skal spire frem af jorden, og frugttræer, som bærer frugt med kerner, skal vokse op, så de kan formere sig, hver efter sin art.” Og sådan blev det. 12Op af jorden spirede grønne planter, som bar frø, og træer, som bar frugt med kerner, hver efter sin art. Og Gud glædede sig over sit værk. 13Det blev aften, og det blev morgen. Det var den tredje dag.

14-15Så sagde Gud: „Der skal være lysgivere på himmelhvælvingen, som sætter skel mellem dag og nat, og som markerer årstidernes skiften og festdagenes begyndelse.” Og sådan blev det. 16Gud frembragte to store lys på himlen til at skinne på jorden, det største lys, solen, til at herske om dagen, og det mindre, månen, til at herske om natten sammen med stjernerne. 17Han satte dem på himmelhvælvingen til at lyse på jorden, 18til at sætte skel mellem dagen og natten. Og han glædede sig over sit værk. 19Det blev aften, og det blev morgen. Det var den fjerde dag.

20Dernæst sagde Gud: „Vandet skal vrimle med fisk og andet liv, og der skal være et mylder af fugle i luften.” Og sådan blev det. 21Gud skabte de store havdyr og en mangfoldighed af fisk og fugle; og han glædede sig over sit værk. 22Han velsignede dem og sagde: „Formér jer og bliv mange. Fiskene skal fylde havene, og fuglene skal fylde luften.” 23Det blev aften, og det blev morgen. Det var den femte dag.

24Derpå sagde Gud: „Af jorden skal der fremstå alle slags dyr—kvæg, krybdyr og alle mulige vilde dyr.” Og sådan blev det. 25Gud dannede alle slags vilde dyr, krybdyr og husdyr, alle i stand til at formere sig, hver efter sin art; og Gud glædede sig over sit værk.

26Så sagde Gud: „Lad os frembringe et levende væsen, der ligner os. Det skal herske over alt dyrelivet—fiskene i havet, fuglene i luften og de tamme og vilde dyr på jorden.” 27Da skabte Gud to mennesker, som lignede ham. De blev skabt som mand og kvinde. 28Gud velsignede dem og sagde: „Formér jer og bliv mange, bred jer over hele jorden og tag den i besiddelse! Hersk over fiskene, fuglene og alle de andre dyr på jorden.” 29Gud fortsatte: „Se! Jeg giver jer alle de frøbærende planter på jorden som føde, og I må også spise frugt fra de mange frugttræer. 30Jeg giver græsset og alt grønt til føde for dyrene og fuglene.” Og sådan blev det. 31Gud betragtede nu hele sit skaberværk, og han var ovenud tilfreds med det. Det blev aften, og det blev morgen. Det var den sjette dag.