Efesu 6 – YCB & BPH

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Efesu 6:1-24

Àwọn ọmọ àti àwọn òbí

1Ẹ̀yin ọmọ, ẹ máa gbọ́ tí àwọn òbí i yín nínú Olúwa: nítorí pé èyí ní ó tọ́. 26.2: Ek 20.12.“Bọ̀wọ̀ fún baba àti ìyá rẹ,” èyí tí í ṣe òfin kìn-ín-ní pẹ̀lú ìlérí, 36.3: De 5.16.“ki ó lé dára fún ọ, àti kí ìwọ lè wà pẹ́ ní ayé.”

4Àti ẹ̀yin baba, ẹ má ṣe mú àwọn ọmọ yín bínú, ṣùgbọ́n ẹ máa tọ́ wọn nínú ẹ̀kọ́ àti ìkìlọ̀ Olúwa.

Àwọn ẹrú àti olówó wọn

5Ẹ̀yin ọmọ ọ̀dọ̀, ẹ máa gbọ́ ti àwọn olúwa yín nípá ti ara, pẹ̀lú ìbẹ̀rù àti ìwárìrì, nínú òtítọ́ ọkàn yín, bí ẹni pé sí Kristi. 6Gbọ́ ọ̀rọ̀ sí wọn lẹ́nu kì í ṣe láti rí ojúrere wọn nígbà tí ojú wọn bá ń bẹ lára rẹ, ṣùgbọ́n bí ẹrú Kristi, ní ṣíṣe ìfẹ́ Ọlọ́run láti inú ọkàn rẹ. 7Ẹ máa fi gbogbo ọkàn yin ṣe iṣẹ́ ìsìn bí sí Olúwa, kì í sí ṣe sí ènìyàn. 8Bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé ohun rere tí olúkúlùkù bá ṣe òun náà ní yóò sí gbà padà lọ́dọ̀ Olúwa, ìbá à ṣe ẹrú, tàbí òmìnira.

9Àti ẹ̀yin ọ̀gá, ẹ máa ṣe irú ìtọ́jú kan náà sí àwọn ẹrú yin, ẹ máa dín ìbẹ̀rù yín kù bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé Olúwa ẹ̀yin tìkára yín ń bẹ ní ọ̀run; kò sì ṣí ojúsàájú ènìyàn lọ́dọ̀ rẹ̀.

Ìhámọ́ra Ọlọ́run

10Ní àkótán, ara mí, ẹ jẹ́ alágbára nínú Olúwa, àti nínú agbára ipá rẹ̀. 11Ẹ gbé gbogbo ìhámọ́ra Ọlọ́run wọ̀, kí ẹ̀yin lè kọ ojú ìjà sí àrékérekè èṣù. 12Nítorí pé kì í ṣe ẹ̀jẹ̀ àti ẹran-ara ní àwa ń bá jìjàkadì, ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè, àwọn ọlọ́lá, àwọn aláṣẹ ìbí òkùnkùn ayé yìí, àti àwọn ẹ̀mí búburú ní ojú ọ̀run. 13Nítorí náà, ẹ gbé gbogbo ìhámọ́ra Ọlọ́run wọ̀, kí ẹ̀yin lè dúró tiiri sí ọjọ́ ibi, nígbà tí ẹ̀yin bá sì ti ṣe ohun gbogbo tan kí ẹ sì dúró. 146.14: Isa 11.5; 59.17; 1Tẹ 5.8.Ẹ dúró nítorí náà lẹ́yìn tí ẹ fi àmùrè òtítọ́ dì ẹ̀gbẹ́ yin, tí ẹ sì ti di ìgbàyà òdodo mọ́ra. 156.15: Isa 52.7.Tí ẹ sì ti fi ìmúra ìhìnrere àlàáfíà wọ ẹsẹ̀ yín ní bàtà. 16Ní àfikún, ẹ mú apata ìgbàgbọ́, nípa èyí tí ẹ̀yin lè máa fi paná gbogbo ọfà iná ẹni ibi náà. 17Kí ẹ sì mú àṣíborí ìgbàlà, àti idà ẹ̀mí, tí í ṣe ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.

18Pẹ̀lú gbogbo àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ni kí ẹ máa gbàdúrà nígbà gbogbo nínú Ẹ̀mí, kí ẹ sì máa ṣọ́ra sí i nínú ìdúró ṣinṣin gbogbo àti ẹ̀bẹ̀ fún gbogbo ènìyàn mímọ́. 19Kí ẹ sì máa gbàdúrà fún mí pẹ̀lú, kí Ọlọ́run lè fún mí ní ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí èmi lè máa fì ìgboyà sọ àwọn ohun ìjìnlẹ̀ ìhìnrere náà. 20Nítorí èyí tí èmí jẹ́ ikọ̀ nínú ẹ̀wọ̀n: kí èmi lè máa fi ìgboyà sọ̀rọ̀ nínú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ fún mí láti máa sọ.

Àwọn ìkíni ìkẹyìn

216.21-22: Kl 4.7-8. Tikiku, arákùnrin olùfẹ́ àti ìránṣẹ́ olóòtítọ́ nínú Olúwa yóò sọ ohun gbogbo dí mí mọ̀ fún yín, kí ẹ̀yin pẹ̀lú lè mọ̀ bí nǹkan ti rí fún mí àti bí mo tí ń ṣe sí. 22Ẹni tí mo rán sí yín nítorí èyí náà, kí ẹ lè mọ̀ bí a tí wà, kì òun lè tu ọkàn yín nínú.

23Àlàáfíà fún àwọn ará, àti ìfẹ́ pẹ̀lú ìgbàgbọ́, láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wà, àti Olúwa wà Jesu Kristi.

24Kí oore-ọ̀fẹ́ wà pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó fẹ́ Olúwa wa Jesu Kristi ni àìṣẹ̀tàn.

Bibelen på hverdagsdansk

Efeserbrevet 6:1-24

Forholdet mellem børn og forældre

Kol. 3,20-22

1Til jer børn, som hører Herren til, siger jeg: Adlyd jeres forældre, for det er Guds vilje for jer. 2Der står jo skrevet: „Du skal ære din far og din mor,” og det er det første af budene, som har et løfte tilknyttet, nemlig dette: 3„…så du kan få et godt og langt liv på jorden.”6,3 Eller „…i landet.” 2.Mos. 20,12, 5.Mos. 5,16 fra LXX.

4Til jer forældre siger jeg: Vær ikke hårdhændede over for jeres børn, så de bliver oprørske, men vejled dem og advar dem, som Herren selv ville gøre det.

Forholdet mellem slaver og herrer

Kol. 3,23–4,1

5Til jer, som er slaver, siger jeg: Adlyd jeres jordiske herrer. Vis samme respekt og hengivenhed over for dem som over for Kristus. 6I skal ikke kun arbejde hårdt, når jeres herre holder øje med jer. Nej, I skal arbejde som Kristi tjenere, der af hele deres hjerte ønsker at gøre Guds vilje. 7Udfør villigt jeres arbejde, som var det Herren selv og ikke mennesker, I arbejdede for. 8Husk, at Herren vil lønne jer for godt udført arbejde, lige meget om I er slaver eller ej.

9Og I herrer skal tænke i de samme baner over for jeres slaver. Lad være med at underkue dem, for I ved, at I og jeres slaver har den samme Herre i Himlen, og han ser ikke på folks status i samfundet.

Den kristnes kamp og udrustning

10Til sidst vil jeg minde jer om at hente styrke fra Herren og hans vældige kraft. 11Ifør jer hele Guds rustning, så I kan forsvare jer mod Satans lumske angreb. 12Den kamp, vi står i, er jo ikke mod mennesker, men imod åndelige magter, autoriteter og herskere i denne mørke verden, mod en hær af onde ånder i himmelrummet.

13Derfor skal I tage hele Guds udrustning på, så I kan forsvare jer imod den Ondes angreb og stå fast, indtil alle angrebene er overstået. 14Spænd sandheden som bælte om livet. Tag ret levevis på som brynje 15og budskabet om fred som støvler, så I kan stå fast.6,15 Meningen er uklar. Kan måske også oversættes: „…og tag som støvler på fødderne villighed til at bringe fredens gode budskab.” 16Løft troens skjold, som I kan bruge til at stoppe Satans brændende pile. 17Tag frelsens hjelm på og forsvar jer med Åndens sværd, som er Guds ord. 18Vær altid i bøn til Gud under Åndens inspiration, hvad enten det er forbøn eller bøn om hjælp. Vær udholdende og årvågne, når I beder for alle dem, der hører Kristus til.

19Bed også for mig, at Gud må give mig de rette ord, så jeg med frimodighed kan kommunikere det budskab om Kristus, som Gud har åbenbaret for os, 20og som er årsag til, at jeg sidder i fængsel. Bed om, at jeg må have frimodighed til at fortsætte med at tale om det, for jeg ved, at det er den opgave, Herren har sendt mig for at udføre.

Afsluttende ord og velsignelse

21Dette brev bliver overbragt jer af Tykikos, som er en elsket medkristen og en trofast medarbejder i Herrens tjeneste. Han kan fortælle jer mere nyt herfra. 22Jeg sender ham til jer, for at I kan høre, hvordan det går os, og for at han kan være til opmuntring for jer.

23Fred, kærlighed og tro fra Gud Fader og Herren Jesus Kristus være med jer, kære venner. 24Guds nåde være over alle, som med en udødelig kærlighed elsker Jesus Kristus, vores Herre.