Efesu 2 – YCB & SZ-PL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Efesu 2:1-22

Ìṣọdààyè nínú Kristi

1Ní ti ẹ̀yin, ẹ̀yin ni ó sì ti sọ di ààyè, nígbà ti ẹ̀yin ti kú nítorí ìrékọjá àti àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín, 22.2: Kl 1.13.nínú èyí tí ẹ̀yin ti gbé rí, àní bí ìlànà ti ayé yìí, gẹ́gẹ́ bí aláṣẹ agbára ojú ọ̀run, ẹ̀mí tí n ṣiṣẹ́ ni ìsinsin yìí nínú àwọn ọmọ aláìgbọ́ràn. 3Nínú àwọn ẹni tí gbogbo wa pẹ̀lú ti wà rí nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ara wa, a ń mú ìfẹ́ ara àti ti inú ṣẹ, àti nípa ìṣẹ̀dá àwa sì ti jẹ́ ọmọ ìbínú, gẹ́gẹ́ bí àwọn ìyókù pẹ̀lú. 4Ṣùgbọ́n Ọlọ́run, ẹni tí í ṣe ọlọ́rọ̀ ni àánú, nítorí ìfẹ́ ńlá rẹ̀ tí ó fi fẹ́ wa, 5nígbà tí àwa tilẹ̀ ti kú nítorí ìrékọjá wa, ó sọ wá di ààyè pẹ̀lú Kristi, oore-ọ̀fẹ́ ni a ti fi gbà yín là. 6Ọlọ́run sì ti jí wa dìde pẹ̀lú Kristi, ó sì ti mú wa jókòó pẹ̀lú rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run nínú Kristi Jesu. 7Pé ni gbogbo ìgbà tí ń bọ̀ kí ó bà á lè fi ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí o pọ̀ rékọjá hàn fún wa nínú ìṣeun rẹ̀ sì wà nínú Kristi Jesu. 82.8: Ga 2.16.Nítorí oore-ọ̀fẹ́ ní a fi gbà yín là nípa ìgbàgbọ́. Èyí kì í ṣe nípa agbára ẹ̀yin fúnrayín: ẹ̀bùn Ọlọ́run ni: 9Kì í ṣe nípa àwọn iṣẹ́, kí ẹnikẹ́ni má ba à ṣògo. 10Nítorí àwa ni iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ tí a ti dá nínú Kristi Jesu fún àwọn iṣẹ́ rere, èyí tí Ọlọ́run ti pèsè tẹ́lẹ̀, fún wa láti ṣe.

Ọ̀kan nínú Kristi

11Nítorí náà ẹ rántí pé, nígbà àtijọ́ rí, ẹ̀yin tí ẹ ti jẹ́ Kèfèrí nípa ti ìbí, tí àwọn tí a ń pè ní “aláìkọlà” láti ọwọ́ àwọn tí ń pe ara wọn “akọlà” (Èyí ti a fi ọwọ́ ènìyàn ṣe sí ni ni ara)— 122.12: Isa 57.19.Ẹ rántí pé ni àkókò náà ẹ̀yin wà láìní Kristi, ẹ jẹ́ àjèjì sí Israẹli, àti àjèjì sí àwọn májẹ̀mú ìlérí náà, láìní ìrètí, àti láìní Ọlọ́run ni ayé. 13Ṣùgbọ́n nísinsin yìí nínú Kristi Jesu ẹ̀yin tí ó ti jìnà réré nígbà àtijọ́ rí ni a mú súnmọ́ tòsí, nípa ẹ̀jẹ̀ Kristi.

14Nítorí òun ni àlàáfíà wa, ẹni tí o ti ṣe méjèèjì ni ọ̀kan, tí ó sì ti wó ògiri ìkélé ti ìkórìíra èyí tí ń bẹ láàrín yín. 15Ó sì ti fi òpin sí ọ̀tá náà nínú ara rẹ̀, àní sí òfin àti àṣẹ wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ nínú ìlànà, kí ó lè sọ àwọn méjèèjì di ẹni tuntun kan nínú ara rẹ̀, kí ó sì ṣe ìlàjà 16àti kí ó lè mú àwọn méjèèjì bá Ọlọ́run làjà nínú ara kan nípa àgbélébùú; nípa èyí tí yóò fi pa ìṣọ̀tá náà run. 172.17: Isa 57.19.Ó sì ti wá, ó sì ti wàásù àlàáfíà fún ẹ̀yin tí o jìnnà réré, àti àlàáfíà fún àwọn tí o súnmọ́ tòsí. 18Nítorí nípa rẹ̀ ni àwa méjèèjì ti ni àǹfààní sọ́dọ̀ baba nípa Ẹ̀mí kan.

19Ǹjẹ́ nítorí náà ẹ̀yin kì í ṣe àlejò àti àjèjì mọ́, ṣùgbọ́n àjùmọ̀jogún ọmọ ìbílẹ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn mímọ́, àti àwọn ará ilé Ọlọ́run; 20a sì ń gbé yín ró lórí ìpìlẹ̀ àwọn aposteli, àti àwọn wòlíì, pẹ̀lú Jesu Kristi fúnrarẹ̀ gẹ́gẹ́ bí pàtàkì òkúta igun ilé; 21Nínú rẹ ni gbogbo ilé náà, tí a ń kọ wà papọ̀ ṣọ̀kan tí ó sì ń dàgbàsókè láti di tẹmpili mímọ́ kan nínú Olúwa: 22Nínú rẹ̀ ni a ń gbé ẹ̀yin pẹ̀lú ró pẹ̀lú fún ibùjókòó Ọlọ́run nínú Ẹ̀mí rẹ̀.

Słowo Życia

Efezjan 2:1-22

Ożywieni dzięki Chrystusowi

1Kiedyś byliście duchowo martwi, pogrążeni w grzechach i przestępstwach. 2Żyliście jak cały ten świat, posłuszny swojemu duchowemu władcy, panującemu nad siłami zła, który obecnie działa przez zbuntowanych ludzi. 3Kiedyś my wszyscy, tak jak oni, byliśmy podporządkowani pragnieniom naszego ciała i zmysłowym przyjemnościom. Dlatego, podobnie jak wszystkich innych ludzi, czekał nas Boży sąd.

4Ale Bóg, który jest Bogiem pełnym miłości, tak bardzo nas pokochał, 5że chociaż byliśmy duchowo martwi i pogrążeni w grzechach, razem z Chrystusem przywrócił nas do życia. W ten sposób, dzięki swojej łasce, uratował także was. 6On wskrzesił nas i juz teraz umieścił w niebie—należymy bowiem do Chrystusa. 7Łaska, którą Bóg okazał nam dzięki Chrystusowi Jezusowi, będzie w nadchodzących wiekach dowodem Jego dobroci.

8Zbawienie nie jest waszą zasługą, ale darem od Boga, który przyjęliście wierząc w Jego łaskę. 9Bóg zbawił was przecież nie ze względu na wasze dobre uczynki, nie macie się więc czym szczycić! 10Wszystko to pochodzi bowiem od Niego! To On, dzięki Jezusowi Chrystusowi, sprawił, że staliśmy się innymi, nowymi ludźmi. On również chce, abyśmy czynili dobro i już od dawna to dla nas zaplanował.

Jedno w Chrystusie

11Nie zapominajcie więc, że kiedyś byliście poganami i że ci, którzy mają na ciele znak obrzezania, pogardliwie nazywali was nieobrzezanymi. 12Żyliście wtedy bez Chrystusa. Nie należeliście też do Izraela—narodu wybranego przez Boga. Dlatego obietnice, płynące z Bożego przymierza z Izraelem, nie dotyczyły was. Żyliście więc na tym świecie bez nadziei i bez Boga. 13Teraz jednak wy, niegdyś obcy Bogu, staliście się Mu bliscy dzięki przelanej krwi Chrystusa, do którego należycie. 14On bowiem dał nam pokój, ponieważ przez swoją śmierć zjednoczył Żydów i pogan. Zburzył dzielący ich mur wrogości 15i pozbawił mocy Prawo Mojżesza wraz z jego przykazaniami. Uczynił to, aby z Żydów i pogan stworzyć jeden nowy naród i zaprowadzić między nimi pokój. 16Przez swoją śmierć na krzyżu pojednał z Bogiem jednych i drugich, co więcej—umieścił ich w jednym ciele! Zlikwidował w ten sposób wzajemną wrogość. 17Chrystus przyniósł tę nowinę o pokoju zarówno wam, którzy byliście obcy Bogu, jak i bliskim Mu Żydom. 18To dzięki Niemu, przez jednego Ducha, wszyscy mamy dostęp do Boga Ojca.

19Nie jesteście już więc cudzoziemcami ani obcymi! Staliście się obywatelami nieba i należycie do Bożej rodziny. 20Jesteście jak dom, zbudowany na fundamencie apostołów i proroków, którego kamieniem węgielnym jest sam Jezus Chrystus. 21To On bowiem łączy ze sobą poszczególne elementy tej budowli i sprawia, że wznosi się ona jako święta świątynia dla Pana. 22Dzięki Niemu jesteście częścią budowli, w której mieszka Boży Duch!