Daniẹli 2 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Daniẹli 2:1-49

Àlá Nebukadnessari

1Ní ọdún kejì ìjọba Nebukadnessari, ó lá àlá, èyí tí ó mú kí ọkàn an rẹ̀ dàrú, kò sì le è sùn. 2Nígbà náà ni ọba yára pe àwọn onídán, àwọn aláfọ̀ṣẹ, àwọn oṣó àti àwọn awòràwọ̀; àwọn tó ní ìmọ̀ àti àṣírí i títúmọ̀ ìràwọ̀, ọba pè wọ́n kí wọn wá sọ àlá tí ó lá. Nígbà tí wọ́n dé, tí wọ́n dúró níwájú ọba, 3ọba sì wí fún wọn pé, “Mo ti lá àlá kan èyí tí ó mú kí ọkàn mi dàrú, mo sì fẹ́ mọ ìtumọ̀ àlá náà.”

4Nígbà náà ni àwọn awòràwọ̀ dá ọba lóhùn ní èdè Aramaiki pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Sọ àlá yìí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ àwa yóò sì sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọ.”

5Ọba dá àwọn awòràwọ̀ lóhùn pé, “Ohun náà ti kúrò lórí mi: tí ẹ̀yin kò bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, èmi yóò gé e yín sí wẹ́wẹ́, ilé e yín yóò sì di ààtàn. 6Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi, èmi yóò fún un yín ní ẹ̀bùn, ọrẹ àti ọláńlá tí ó pọ̀. Nítorí náà, ẹ sọ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀ fún mi.”

7Lẹ́ẹ̀kan sí i, “Wọ́n tún dáhùn pé, jẹ́ kí ọba sọ àlá náà fún ìránṣẹ́ rẹ̀, àwa yóò sì túmọ̀ rẹ̀.”

8Nígbà náà ni ọba sọ pé, “Èmi mọ̀ dájú wí pé ẹ̀yin fẹ́ fi àkókò ṣòfò nítorí pé ẹ̀yin ti mọ̀ pé nǹkan ti lọ ní orí mi: 9Tí ẹ̀yin kò bá lè sọ àlá mi, ìjìyà kan ṣoṣo ló wà fún un yín. Ẹ̀yin ti gbèrò láti pa irọ́ àti láti sọ àwọn ọ̀rọ̀ ti ó lè si ni lọ́nà fún mi, títí tí nǹkan yóò fi yí wọ́. Nítorí náà ẹ rọ́ àlá náà fún mi, èmi yóò sì mọ̀ pé ẹ lè túmọ̀ rẹ̀ fún mi.”

10Àwọn awòràwọ̀ sì dá ọba lóhùn pé, “Kò sí ènìyàn kan ní ayé tí ó lè sọ nǹkan tí ọba béèrè! Kò sí ọba náà bí ó ti wù kí ó tóbi àti kí ó lágbára tó, tí í béèrè irú nǹkan bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àwọn onídán tàbí aláfọ̀ṣẹ tàbí awòràwọ̀. 11Nǹkan tí ọba béèrè yìí ṣòro púpọ̀. Kò sí ẹni tí ó lè fihan ọba àfi àwọn òrìṣà, tí wọn kì í gbé láàrín ènìyàn.”

12Èyí mú kí ọba bínú, ó sì kanra, nítorí náà ó pàṣẹ kí a pa gbogbo àwọn amòye Babeli run. 13Nítorí náà àṣẹ yìí jáde lọ wí pé kí a pa àwọn amòye, wọ́n ránṣẹ́ pe Daniẹli pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ láti pa wọ́n.

14Nígbà tí Arioku, olórí àwọn olùṣọ́ ọba, jáde láti lọ pa àwọn amòye Babeli, Daniẹli sọ̀rọ̀ fún un pẹ̀lú ọgbọ́n àti òye. 15Ó béèrè lọ́wọ́ olórí àwọn olùṣọ́ ọba wí pé, “Èéṣe tí àṣẹ ọba fi yá kánkán bẹ́ẹ̀?” Arioku sì ṣe àlàyé ọ̀rọ̀ náà fún Daniẹli. 16Nígbà náà ni Daniẹli wọlé tọ ọba lọ, ó sì tọrọ kí ọba fún òun ní ààyè, òun yóò fi ìtumọ̀ àlá náà hàn fún ọba.

17Nígbà náà ni Daniẹli padà lọ sí ilé e rẹ̀, ó sì sọ fún àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ rẹ̀ Hananiah, Miṣaeli àti Asariah. 18Ó sọ fún wọn pé kí wọn béèrè fún àánú Ọlọ́run, Olúwa ọ̀run, nítorí àṣírí yìí, kí Daniẹli pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ má ba ṣègbé pẹ̀lú àwọn ọlọ́gbọ́n Babeli yòókù, tí ó wà ní Babeli. 19Ní òru, àṣírí náà hàn sí Daniẹli ní ojú ìran. Nígbà náà ni Daniẹli fi ògo fún Ọlọ́run ọ̀run 20Daniẹli wí pé:

“Ọpẹ́ ni fún orúkọ Ọlọ́run láé àti láéláé;

tirẹ̀ ni ọgbọ́n àti agbára

21Ó yí ìgbà àti àkókò padà;

ó mú ọba jẹ, ó ń mú wọn kúrò.

Ó fún àwọn amòye ní ọgbọ́n

àti ìmọ̀ fún àwọn tí ó ní òye.

22Ó fi ohun ìjìnlẹ̀ àti àṣírí hàn;

ó mọ ohun tí ó pamọ́ nínú òkùnkùn

àti ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìmọ́lẹ̀ wà

23Mo dúpẹ́, mo sì fi ìyìn fún ọ, ìwọ Ọlọ́run àwọn baba mi:

ó ti fún mi ní ọgbọ́n àti agbára

ó ti fi àwọn nǹkan tí a béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ hàn fún mi

nítorí tí ìwọ ti fi àlá ọba hàn wá.”

Daniẹli túmọ̀ àlá

24Nígbà náà ni Daniẹli tọ́ Arioku lọ, ẹni tí ọba yàn láti pa àwọn amòye Babeli run, Daniẹli wí fún un pé, “Má ṣe pa àwọn amòye Babeli run. Mú mi lọ sí ọ̀dọ̀ ọba, èmi yóò sísọ ìtumọ̀ àlá rẹ̀ fún un.”

25Lẹ́sẹ̀kan náà, Arioku yára mú Daniẹli lọ sí iwájú ọba, ó sọ fún ọba pé, “Èmi ti rí ọkùnrin kan lára àwọn àjèjì tí ó wá láti Juda, ẹni tí ó lè sọ ìtumọ̀ àlá náà fún ọba.”

26Ọba béèrè lọ́wọ́ Daniẹli ẹni tí a tún ń pè ní Belṣassari pé, “Ṣé ìwọ lè sọ ohun tí mo rí nínú àlá mi àti ìtumọ̀ ọ rẹ̀ fún mi?”

27Daniẹli dá ọba lóhùn pé, “Kò sí awòràwọ̀ kan, apògèdè, onídán tàbí aláfọ̀ṣẹ tí ó lè ṣe àlàyé àṣírí tí ọba béèrè fún 28ṣùgbọ́n, Ọlọ́run kan ń bẹ ní ọ̀run tí ó ń fi àṣírí hàn. Ó ti fihan ọba Nebukadnessari, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ìkẹyìn ọjọ́. Àlá àti ìran tí o rí nígbà tí o dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ ni ìwọ̀nyí:

29“Ọba, bí ìwọ ṣe sùn sórí ibùsùn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn rẹ ń ro àwọn ohun tó ń bọ̀, olùfihàn àṣírí ń fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ fún ọ. 30Ṣùgbọ́n fún èmi, a fi àṣírí yìí hàn mí, kì í ṣe pé mo ní ọgbọ́n tí ó pọ̀ ju ti alààyè kankan lọ, ṣùgbọ́n nítorí kí ọba lè mọ ìtumọ̀ àlá àti kí ó lè mọ ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ̀.

31“Ìwọ ọba ń wo, ère ńlá kan tí ó dúró níwájú rẹ, ère náà ga, ó sì dára láti wò, ìrísí i rẹ̀ ba ni lẹ́rù jọjọ. 32Orí ère náà jẹ́ kìkì wúrà, àyà rẹ̀ àti ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ fàdákà, inú àti ẹ̀gbẹ́ itan rẹ̀ jẹ́ idẹ, 33àwọn ẹsẹ̀ rẹ̀ jẹ́ irin, àwọn àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀ jẹ́ apá kan irin àti apá kan amọ̀. 34Bí ó ṣe ń wò, òkúta kan wá, tí kò wá láti ọwọ́ ẹnìkankan. Ó kọlu ère náà ní àtẹ́lẹsẹ̀ irin àti amọ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. 35Nígbà náà ni irin, amọ̀, idẹ, fàdákà àti wúrà fọ́ sí wẹ́wẹ́ lẹ́sẹ̀kan náà, ó sì dàbí ìyàngbò tí a fẹ́ kúrò lórí ọkà ní àsìkò ẹ̀ẹ̀rùn. Afẹ́fẹ́ gbé gbogbo rẹ̀ lọ láìṣẹ́ku ọ̀kan mọ́, òkúta tí ó fọ́ ère náà sì di òkè ńlá, ó sì gba gbogbo ayé.

36“Èyí ni àlá náà, nígbà yìí ni a ó wá sọ ìtumọ̀ rẹ̀ fún ọba. 37Ìwọ ọba jẹ́ ọba àwọn ọba. Ọlọ́run ọ̀run ti fi ìjọba agbára, títóbi àti ògo fún ọ; 38ní ọwọ́ rẹ ló fi gbogbo ènìyàn, àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run sí. Ní ibi gbogbo tí wọ́n ń gbé, ó ti fi ọ́ ṣe olórí i wọn. Ìwọ ni orí wúrà náà.

39“Lẹ́yìn èyí ni ìjọba mìíràn yóò dìde, tí kò ní lágbára tó tìrẹ, lẹ́yìn in rẹ̀, ìjọba kẹta tí yóò dàbí idẹ, èyí tí yóò jẹ ọba lórí i gbogbo ayé. 40Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ìjọba kẹrin yóò wà, ìjọba náà yóò lágbára bí irin, gẹ́gẹ́ bí irin ti í fọ́, tó sì ń lọ gbogbo nǹkan àti bí irin ti í fọ́ nǹkan sí wẹ́wẹ́, bẹ́ẹ̀ ni yóò fọ́ tí yóò sì lọ gbogbo àwọn tókù. 41Bí o ṣe rí i tí àtẹ́lẹsẹ̀ àti ọmọ ìka ẹsẹ̀ jẹ́ apá kan amọ̀ àti apá kan irin, bẹ́ẹ̀ ni ìjọba yóò ṣe pín; ṣùgbọ́n yóò sì ní agbára irin díẹ̀ nínú rẹ̀, bí ó ṣe rí i tí irin dàpọ̀ mọ́ amọ̀. 42Bí ọmọ ìka ẹsẹ̀ ṣe jẹ́ apá kan irin àti apá kan amọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìjọba yìí yóò lágbára lápákan tí kò sì ní lágbára lápákan. 43Gẹ́gẹ́ bí o ti rí i tí irin dàpọ̀ mọ́ amọ̀, báyìí ni àwọn ènìyàn yóò ṣe dàpọ̀ mọ́ ara wọn ní ti ìgbéyàwó, ṣùgbọ́n wọn kò ní wà ní ìṣọ̀kan, bí irin kò ṣe dàpọ̀ mọ́ amọ̀.

44“Ní àsìkò àwọn ọba náà, Ọlọ́run ọ̀run yóò gbé ìjọba èyí tí kò le è bàjẹ́ kalẹ̀, èyí tí a kò ní fi lé ẹlòmíràn lọ́wọ́. Yóò sì run gbogbo ìjọba, yóò sì mú wọn wá sí òpin, ṣùgbọ́n ìjọba yìí yóò dúró láéláé.” 45Gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i pé a gé òkúta láti ara òkè, láì ti ọwọ́ ẹnikẹ́ni wá, òkúta èyí tí ó fọ́ irin, idẹ, amọ̀, fàdákà àti wúrà sí wẹ́wẹ́.

“Ọlọ́run tí ó tóbi ti fihan ọba, ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú. Òtítọ́ ni àlá náà, bẹ́ẹ̀ ni ìtumọ̀ rẹ̀ ṣe é gbẹ́kẹ̀lé.”

46Nígbà náà, ni Nebukadnessari ọba dojúbolẹ̀ níwájú u Daniẹli ó sì fi orí balẹ̀ fún un, ó sì pàṣẹ pé kí wọn kí ó mu ọrẹ àti òórùn tùràrí fún Daniẹli 47Ọba wí fún Daniẹli pé, “Dájúdájú Ọlọ́run rẹ ni Ọlọ́run àwọn ọlọ́run àti Olúwa àwọn ọba gbogbo àti olùfihàn àwọn àṣírí, nítorí tí ìwọ lè fi àṣírí yìí hàn.”

48Nígbà náà ni ọba gbé Daniẹli ga, ó sì fún un ní ẹ̀bùn ńlá tí ó pọ̀. Ó sì fi ṣe olórí i gbogbo agbègbè ìjọba Babeli àti olórí gbogbo àwọn amòye Babeli. 49Daniẹli béèrè lọ́wọ́ ọba, ó sì yan Ṣadraki, Meṣaki, àti Abednego gẹ́gẹ́ bí alábojútó ìgbèríko Babeli ṣùgbọ́n Daniẹli fúnrarẹ̀ wà ní ààfin ọba.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

Даниял 2:1-49

Сон Навуходоносора

1На втором году правления Навуходоносора (в 603 г. до н. э.) приснились ему сны; он встревожился духом и не мог заснуть. 2Тогда царь призвал всех чародеев, волшебников, колдунов и астрологов, чтобы они рассказали, что ему приснилось. Когда они пришли и встали перед царём, 3он сказал им:

– Мне снился сон, и я тревожусь духом, желая понять, что это был за сон.

4Тогда астрологи ответили царю по-арамейски:

– О царь, живи вечно! Расскажи нам, твоим рабам, этот сон, и мы истолкуем его.

5Царь ответил астрологам:

– Вот что я решил: если вы сами не расскажете мне содержание сна и его истолкование, то вас разрубят на куски, а ваши дома разрушат до основания. 6Но если вы расскажете мне этот сон и истолкуете его, то получите от меня подарки, награды и великие почести. Итак, расскажите мне этот сон и истолкуйте его.

7Они ответили ещё раз:

– Пусть царь расскажет своим рабам сон, а мы истолкуем его.

8Тогда царь сказал:

– Я точно знаю, что вы стараетесь выиграть время, так как знаете, что я твёрдо решил 9наказать вас, если не расскажете мне мой сон. Поэтому вы и сговорились лгать и обманывать меня в надежде, что дело изменится. Итак, расскажите мне сон, и я узнаю, что вы можете мне его и истолковать.

10Астрологи ответили царю:

– На земле нет человека, который мог бы сделать то, чего просит царь! Никакой царь, как бы он ни был велик и могуществен, никогда не просил такого ни у одного чародея, волшебника или астролога. 11То, о чём просит царь, слишком трудно. Никто не может открыть этого царю, кроме богов, а они среди людей не живут.

12Это так разгневало и разъярило царя Вавилона, что он приказал казнить всех мудрецов Вавилона. 13Был издан указ предать смерти всех мудрецов. Искали и Данияла с его друзьями, чтобы предать их смерти.

14Когда Ариох, начальник царских стражей, вышел предать смерти вавилонских мудрецов, Даниял заговорил с ним с мудростью и рассудительностью. 15Он спросил царского сановника:

– Почему царь издал такой суровый указ?

И Ариох рассказал обо всём Даниялу. 16Тогда Даниял пошёл к царю и попросил дать ему время, чтобы истолковать его сон.

17Даниял вернулся домой и рассказал об этом своим друзьям – Ханании, Мисаилу и Азарии. 18Он велел им просить у Бога2:18 Бог – на языке оригинала: «Элах» – слово, родственное арабскому «Аллах». Это имя Всевышнего часто встречается в этой книге. См. приложение V. небесного милости, чтобы Он открыл им эту тайну, и они не были казнены вместе с остальными вавилонскими мудрецами. 19Ночью эта тайна была открыта Даниялу в видении.

Даниял восславил Бога небесного 20такими словами:

– Слава имени Твоему, Аллах, вовеки;

у Тебя мудрость и сила.

21Ты сменяешь времена и эпохи;

Ты возводишь и низлагаешь царей.

Ты даёшь мудрость мудрым

и знание – разумным.

22Ты открываешь глубокое и сокровенное;

Ты знаешь, что таится во тьме,

и свет обитает с Тобой.

23Благодарю и славлю Тебя, Бог моих предков,

потому что Ты дал мне мудрость и силу;

Ты открыл мне то, о чём мы Тебя молили,

Ты открыл нам царский сон!

Даниял толкует сон

24Даниял пошёл к Ариоху, которому царь велел казнить вавилонских мудрецов, и сказал ему:

– Не казни вавилонских мудрецов. Отведи меня к царю, и я истолкую ему его сон.

25Ариох тотчас же отвёл Данияла к царю и сказал:

– Я нашёл среди пленников из Иудеи человека, который может рассказать царю, что означает его сон.

26Царь спросил Данияла (называемого также Валтасисаром):

– Ты можешь рассказать мне о том, что я видел во сне, и истолковать это?

27Даниял ответил:

– Ни один мудрец, волшебник, чародей или колдун не мог открыть царю тайны, о которой он спрашивал, 28но на небе есть Бог, открывающий тайны. Он показал царю Навуходоносору то, что должно произойти в последние дни. Вот сон и видения, которые ты видел, лёжа в постели.

29Когда ты лежал в постели, о царь, ты размышлял о будущем, и Открывающий тайны показал тебе то, что должно произойти. 30А мне эта тайна была открыта не потому, что у меня больше мудрости, чем у прочих людей, но для того, чтобы ты, царь, мог узнать истолкование и понять то, о чём размышлял.

31Ты увидел, о царь, стоявшую перед тобой большую статую – огромную, сияющую ослепительным блеском, ужасную на вид. 32Голова статуи была из чистого золота, грудь и руки из серебра, живот и бёдра из бронзы, 33ноги из железа, а ступни частью из железа, частью из обожжённой глины. 34Пока ты смотрел, от горы откололся камень без помощи человеческих рук. Он ударил статую по ступням из железа и обожжённой глины и раздробил их. 35И в тот же миг железо, обожжённая глина, бронза, серебро и золото разбились на куски и стали как мякина на току летом. Ветер унёс их, не оставив и следа. Но камень, который ударил в статую, превратился в огромную гору и заполнил всю землю.

36Таков был сон, а теперь истолкуем его царю. 37Ты, о царь, есть царь царей. Бог небесный дал тебе владычество и силу, могущество и славу; 38Он отдал в твои руки человеческий род, полевых зверей и небесных птиц. Где бы они ни жили, Он сделал тебя правителем над всеми ними. Ты и есть та золотая голова.

39После тебя поднимется другое царство, уступающее твоему. После него – третье царство, бронзовое, которое будет править всей землёй. 40Наконец, явится четвёртое царство, крепкое, как железо, – ведь железо всё разбивает и всё крушит, – и как всесокрушающее железо, оно раздробит и сокрушит все остальные. 41И как ты видел то, что ступни и пальцы ступней были частью из обожжённой глины и частью из железа, так и царство это будет разделённым; но будет в нём и от крепости железа, ведь ты видел, что железо смешано с обожжённой глиной. 42Так как пальцы ступней были частью из железа и частью из глины, то и царство это будет частью крепким, частью хрупким. 43И как ты видел железо, смешанным с обожжённой глиной, так и его народ будет смешанным2:43 Букв.: «они смешаются через человеческое семя»., но не пребудет в единстве, как невозможно смешать железо и глину2:31-43 Золотая голова статуи символизирует Навуходоносора, точнее всю вавилонскую монархию, грудь и руки – Мидо-Персидскую империю, живот и бёдра – Греческую, а ноги и ступни – Римскую империи. Согласно другой трактовке видения второе царство – это Мидия, а третье и четвёртое – это Персия и Греция..

44В дни тех царей Бог небесный установит царство, которое никогда не погибнет и не перейдёт к другому народу. Оно сокрушит все эти царства и положит им конец, но само пребудет вовеки. 45Таково значение камня, отколовшегося от горы без помощи человеческих рук – камня, что разбил железо, бронзу, обожжённую глину, серебро и золото на куски2:44-45 Пятое царство – это вечное Царство Аллаха, которое распространяется во всём мире (см. ст. 35; Мат. 13:31-32; Лк. 16:16; Отк. 11:15)..

Великий Бог показал царю то, что произойдёт в будущем. Истинен сон и верно истолкование.

46Тогда царь Навуходоносор пал на колени перед Даниялом и повелел почтить его приношениями и возжиганием благовоний.

47Царь сказал Даниялу:

– Несомненно, ваш Бог есть Бог богов и Владыка царей, открывающий тайны, раз ты смог открыть эту тайну.

48Затем царь возвысил Данияла и дал ему множество ценных подарков. Он сделал его правителем всей провинции Вавилон и главой всех её мудрецов. 49Даниял попросил царя, и царь поставил Шадраха, Мисаха и Аведнего над делами провинции Вавилон. Сам же Даниял остался при царском дворе.