1 Timotiu 2 – YCB & NIVUK

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Timotiu 2:1-15

Àwọn ẹ̀kọ́ lórí ìsìn

1Nítorí náà mo gbà yín níyànjú ṣáájú ohun gbogbo, pé kí a máa bẹ̀bẹ̀, kí a máa gbàdúrà, kí a máa ṣìpẹ̀, àti kí a máa dúpẹ́ nítorí gbogbo ènìyàn. 2Fún àwọn ọba, àti gbogbo àwọn tí ó wà ni ipò àṣẹ, kí a lè máa lo ayé wa ní àlàáfíà àti ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ pẹ̀lú nínú gbogbo ìwà-bí-Ọlọ́run àti ìwà mímọ́. 3Nítorí èyí dára, ó sì ṣe ìtẹ́wọ́gbà níwájú Ọlọ́run Olùgbàlà wa; 4Ẹni tí ó fẹ́ kí gbogbo ènìyàn ní ìgbàlà kí wọ́n sì wá sínú ìmọ̀ òtítọ́. 5Nítorí Ọlọ́run kan ní ń bẹ, onílàjà kan pẹ̀lú láàrín Ọlọ́run àti ènìyàn, àní Kristi Jesu ọkùnrin náà. 6Ẹni ti ó fi ara rẹ̀ ṣe ìràpadà fún gbogbo ènìyàn—ẹ̀rí tí a fi fún ni ní àkókò tó yẹ. 7Nítorí èyí tí a yàn mi ṣe oníwàásù, aposteli òtítọ́ ni èmi ń sọ, èmi kò ṣèké olùkọ́ àwọn aláìkọlà nínú ìgbàgbọ́ àti òtítọ́.

8Mo fẹ́ kí àwọn ọkùnrin máa gbàdúrà níbi gbogbo, kí wọ́n máa gbé ọwọ́ mímọ́ sókè, ní àìbínú àti àìjiyàn. 9Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni kí àwọn obìnrin fi aṣọ ìwọ̀ntúnwọ̀nsì ṣe ara wọn ní ọ̀ṣọ́, ní ìwọ̀ntúnwọ̀nsì àti pẹ̀lú ìwà àìrékọjá; kì í ṣe pẹ̀lú irun dídì, tàbí wúrà, tàbí peali, tàbí aṣọ olówó iyebíye, 10bí kò ṣe pẹ̀lú iṣẹ́ rere, èyí tí ó yẹ fún àwọn obìnrin tó jẹ́wọ́ pé wọ́n sin Ọlọ́run.

11Jẹ́ kí obìnrin máa fi ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìtẹríba gbogbo kọ́ ẹ̀kọ́. 12Ṣùgbọ́n èmi kò fi àṣẹ fún obìnrin láti máa kọ́ni, tàbí láti pàṣẹ lórí ọkùnrin, bí kò ṣe kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́. 132.13: Gẹ 2.7,21-22.Nítorí Adamu ni a kọ́ dá, lẹ́yìn náà, Efa. 142.14: Gẹ 3.1-6.Adamu kọ́ ni a tànjẹ, ṣùgbọ́n obìnrin náà ni a tàn tí ó sì di ẹlẹ́ṣẹ̀. 15Ṣùgbọ́n a ó gbà àwọn obìnrin là nípa ìbímọ wọn, bí wọ́n bá dúró nínú ìgbàgbọ́, ìfẹ́, àti ìwà mímọ́ pẹ̀lú ìwà àìrékọjá.

New International Version – UK

1 Timothy 2:1-15

Instructions on worship

1I urge, then, first of all, that petitions, prayers, intercession and thanksgiving be made for all people – 2for kings and all those in authority, that we may live peaceful and quiet lives in all godliness and holiness. 3This is good, and pleases God our Saviour, 4who wants all people to be saved and to come to a knowledge of the truth. 5For there is one God and one mediator between God and mankind, the man Christ Jesus, 6who gave himself as a ransom for all people. This has now been witnessed to at the proper time. 7And for this purpose I was appointed a herald and an apostle – I am telling the truth, I am not lying – and a true and faithful teacher of the Gentiles.

8Therefore I want the men everywhere to pray, lifting up holy hands without anger or disputing. 9I also want the women to dress modestly, with decency and propriety, adorning themselves, not with elaborate hairstyles or gold or pearls or expensive clothes, 10but with good deeds, appropriate for women who profess to worship God.

11A woman2:11 Or wife; also in verse 12 should learn in quietness and full submission. 12I do not permit a woman to teach or to assume authority over a man;2:12 Or over her husband she must be quiet. 13For Adam was formed first, then Eve. 14And Adam was not the one deceived; it was the woman who was deceived and became a sinner. 15But women2:15 Greek she will be saved through childbearing – if they continue in faith, love and holiness with propriety.