1 Tẹsalonika 5 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Tẹsalonika 5:1-28

15.1: Ap 1.7.Nísinsin yìí, ará, a kò nílò láti kọ ìwé sí i yín mọ́ nípa àkókò àti ìgbà, 25.2: 1Kọ 1.8.nítorí ẹ̀yin pàápàá mọ̀ wí pé ọjọ́ Olúwa yóò wá bí olè lóru. 35.3: 2Tẹ 1.9.Ní àkókò gan an tí àwọn ènìyàn yóò máa wí pé, “Àlàáfíà àti ààbò,” nígbà náà ni ìparun òjijì yóò dé sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ìrọbí obìnrin tí ó lóyún, wọn kò sí ni rí ibi ààbò láti sá sí.

45.4: 1Jh 2.8; Ap 26.18.Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ará, kò sí nínú òkùnkùn nípa nǹkan wọ̀nyí tí ọjọ́ Olúwa yóò fi dé bá yín bí olè. 55.5: Lk 16.8.Nítorí gbogbo yín ni ọmọ ìmọ́lẹ̀ àti ọmọ ọ̀sán gangan. Ẹ kì í ṣe tí òru tàbí tí òkùnkùn mọ́. 65.6: Ro 13.11; 1Pt 1.13.Nítorí náà, ẹ kíyèsára yín kí ẹ má ṣe sùn bí àwọn ẹlòmíràn. Ẹ máa ṣọ́nà kí ẹ sì máa pa ara yín mọ́. 75.7: Ap 2.15; 2Pt 2.13.Nítorí àwọn tí wọ́n ń sùn, a máa sùn ní òru, àwọn ẹni tí ń mu àmupara, a máa mú un ní òru. 85.8: Ef 6.17; Ro 8.24.Ṣùgbọ́n àwa jẹ́ ti ìmọ́lẹ̀, ẹ jẹ́ kí a pa ara wa mọ́, ní gbígbé ìgbàgbọ́ wọ̀ àti ìfẹ́ bí ìgbàyà ni òru àti ìrètí ìgbàlà bí àṣíborí. 95.9: 1Tẹ 1.10; 2Tẹ 2.13; Ro 14.9.Nítorí pé, Ọlọ́run kò yàn wa láti da ìbínú rẹ̀ gbígbóná sí orí wa, ṣùgbọ́n ó yàn láti gbà wá là nípasẹ̀ Olúwa wa, Jesu Kristi. 10Jesu kú fún wa kí a lè ba à gbé títí láéláé. Èyí yóò rí bẹ́ẹ̀ yálà a sùn tàbí a wà láààyè pẹ̀lú rẹ̀. 11Nítorí náà, ẹ máa gba ara yín níyànjú, kí ẹ sì máa gbé ara yín ró, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe.

Ọ̀rọ̀ ìkẹyìn

125.12: 1Kọ 16.18; 1Tm 5.17; 1Kọ 16.16; Ro 16.6,12; 1Kọ 15.10; Hb 13.17.Ẹ̀yin ará, ẹ fi ọlá fún àwọn olórí tí ń ṣe iṣẹ́ àṣekára láàrín yín tí wọn ń kìlọ̀ fún yín nínú Olúwa. 135.13: Mk 9.50.Ẹ bu ọlá fún wọn gidigidi nínú ìfẹ́, nítorí iṣẹ́ wọn. Ẹ sì máa wà ní àlàáfíà láàrín ara yín. 145.14: Isa 35.4; Ro 14.1; 1Kọ 8.7; 2Tẹ 3.6,7,11.Ẹ̀yin ará mi, ẹ kìlọ̀ fún àwọn ọ̀lẹ ti ó wà láàrín yín, ẹ gba àwọn tí ẹ̀rù ń bà ní ìyànjú, ẹ tọ́jú àwọn aláìlera pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, kí ẹ sì ní sùúrù pẹ̀lú gbogbo ènìyàn. 155.15: Ro 12.17; 1Pt 3.9.Ẹ rí i pé kò sí ẹni tí ó fi búburú san búburú, ṣùgbọ́n ẹ máa lépa èyí tí í ṣe rere láàrín ara yín àti sí ènìyàn gbogbo.

165.16: Fp 4.4.Ẹ máa yọ̀ nígbà gbogbo 175.17: Ef 6.18.Ẹ máa gbàdúrà nígbà gbogbo 185.18: Ef 5.20.Ẹ máa dúpẹ́ nígbà gbogbo nínú ipòkípò tí o wù kí ẹ wà; nítorí pé, èyí ni ìfẹ́ Ọlọ́run fún yin nínú Kristi Jesu nítòótọ́.

195.19: Ef 4.30.Ẹ má ṣe pa iná Ẹ̀mí Mímọ́. 205.20: 1Kọ 14.31.Ẹ má ṣe kẹ́gàn àwọn ti ń sọtẹ́lẹ̀. 215.21: 1Kọ 14.29; 1Jh 4.1.Ṣùgbọ́n ẹ dán gbogbo nǹkan wò. Ẹ di èyí tí ṣe òtítọ́ mú. 22Ẹ yẹra fún ohunkóhun tí í ṣe ibi.

235.23: Ro 15.33.Kí Ọlọ́run fúnra rẹ̀, Ọlọ́run àlàáfíà, sọ yín di mímọ́ pátápátá. Kí Ọlọ́run pa ẹ̀mí àti ọkàn pẹ̀lú ara yín mọ́ pátápátá ní àìlábùkù, títí di ìgbà wíwá Jesu Kristi Olúwa wa. 24Olóòtítọ́ ni ẹni tí ó pè yín, yóò sì ṣe.

25Ẹ̀yin ará, ẹ gbàdúrà fún wa.

265.26: Ro 16.16.Ẹ fi ìfẹ́nukonu mímọ́ ki ara yin.

275.27: Kl 4.16.Mo pàṣẹ fún yín níwájú Olúwa pé, kí ẹ ka lẹ́tà yìí fún gbogbo àwọn ará.

285.28: Ro 16.20; 2Tẹ 3.18.Ki oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa wa, wà pẹ̀lú yín.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

1 Фессалоникийцам 5:1-28

День возвращения Исы аль-Масиха

1Братья, нам нет нужды писать вам о временах и сроках. 2Вы и сами хорошо знаете, что день возвращения Вечного Повелителя придёт неожиданно, как вор ночью. 3Люди будут говорить «мир и безопасность», но внезапно их постигнет гибель, как родовые схватки неожиданно застигают беременную женщину, и тогда никто не убежит.

4Но вы, братья, не во тьме, чтобы день этот застиг вас внезапно, как вор. 5Вы все сыны света и дня. У нас нет ничего общего с ночью или с тьмой, 6поэтому не будем спать, как другие, но будем бодрствовать и оставаться трезвыми. 7Те, кто спит, – спят ночью, и те, кто пьянствует, – напиваются ночью. 8Но раз мы принадлежим дню, то давайте же оставаться трезвыми, одевшись, как в броню, в веру и любовь и, как шлем, надев на голову надежду на спасение5:8 См. Ис. 59:17.. 9Ведь Аллах предназначил нас не для гнева, а для спасения, которое мы получаем через Повелителя нашего Ису аль-Масиха. 10Он умер за нас, чтобы нам, окажемся ли мы к тому дню среди умерших или среди живых, жить вместе с Ним. 11Поэтому ободряйте и укрепляйте друг друга, что вы и делаете.

Заключительные наставления

12Мы обращаемся к вам, братья, с просьбой: оказывайте почёт тем, кто так усердно трудится среди вас, кто руководит вашей общиной и наставляет вас в следовании Повелителю. 13Проявляйте к ним большое уважение и любовь за ту работу, которую они совершают. Будьте в мире друг с другом. 14Мы умоляем вас, братья, убеждайте тех, кто не хочет работать; ободряйте боязливых; помогайте слабым духом; будьте терпеливы со всеми. 15Никто пусть не платит никому злом за зло, но будьте всегда добры друг к другу и ко всем.

16Всегда радуйтесь, 17постоянно молитесь 18и при любых обстоятельствах будьте благодарны Аллаху, потому что в этом воля Аллаха для вас, принадлежащих Исе аль-Масиху.

19Не угашайте Духа, 20пророчеством не пренебрегайте, 21но всё проверяйте и держитесь добра. 22Избегайте всякого рода зла.

Благословение и приветствия

23Итак, пусть Сам Аллах, дающий мир, освятит вас всецело, чтобы ваш дух, душа и тело сохранились непорочными до тех пор, когда придёт Повелитель наш Иса аль-Масих. 24Тот, Кто вас призывает, верен, и Он выполнит то, что обещал.

25Братья, молитесь о нас. 26Приветствуйте всех братьев святым поцелуем5:26 Поцелуем приветствовали и приветствуют доныне друг друга жители Ближнего Востока. Подобное можно наблюдать и в Центральной Азии.. 27Я заклинаю вас перед Повелителем, прочитайте это послание всем братьям!

28Пусть с вами будет благодать Повелителя нашего Исы аль-Масиха.