Àdúrà Hana
1Hana sì gbàdúrà pé:
“Ọkàn mi yọ̀ sí Olúwa;
Ìwo agbára mi ni a sì gbé sókè sí Olúwa.
Ẹnu mi sì gbòòrò lórí àwọn ọ̀tá mi,
nítorí ti èmi yọ̀ ni ìgbàlà rẹ̀.
2“Kò sí ẹni tí ó mọ́ bi Olúwa;
kò sí ẹlòmíràn bí kò ṣe ìwọ;
kò sì sí àpáta bi Ọlọ́run wa.
3“Má ṣe halẹ̀;
má ṣe jẹ́ kí ìgbéraga ti ẹnu yín jáde
nítorí pé Ọlọ́run olùmọ̀ ni Olúwa,
láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá ni a ti ń wọn ìwà.
4“Ọ̀run àwọn alágbára ti ṣẹ́,
àwọn tí ó ṣe aláìlera ni a fi agbára dì ní àmùrè.
5Àwọn tí ó yọ̀ fún oúnjẹ ti fi ara wọn ṣe alágbàṣe,
àwọn tí ebi ń pa kò sì ṣe aláìní.
Tó bẹ́ẹ̀ tí àgàn fi bí méje.
Ẹni tí ó bímọ púpọ̀ sì di aláìlágbára.
6“Olúwa pa ó sì sọ di ààyè;
ó mú sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú, ó sì gbé dìde.
7Olúwa sọ di tálákà; ó sì sọ di ọlọ́rọ̀;
ó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì gbé sókè.
8Ó gbé tálákà sókè láti inú erùpẹ̀ wá,
ó gbé alágbe sókè láti orí òkìtì eérú wá,
láti mú wọn jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé,
láti mu wọn jogún ìtẹ́ ògo:
“Nítorí pé ọ̀wọ́n ayé ti Olúwa ni,
ó sì ti gbé ayé ka orí wọn
9Yóò pa ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́,
àwọn ènìyàn búburú ni yóò dákẹ́ ní òkùnkùn.
“Nípa agbára kò sí ọkùnrin tí yóò borí.
10A ó fọ́ àwọn ọ̀tá Olúwa túútúú;
láti ọ̀run wá ni yóò sán àrá sí wọn;
Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ òpin ayé.
“Yóò fi agbára fún ọba rẹ̀,
yóò si gbé ìwo ẹni ààmì òróró rẹ̀ sókè.”
11Elkana sì lọ sí Rama sí ilé rẹ̀, Ọmọ náà sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Olúwa níwájú Eli àlùfáà.
Àwọn ọmọ Eli búburú
12Àwọn ọmọ Eli sì jẹ́ ọmọ Beliali; wọn kò mọ Olúwa. 13Iṣẹ́ àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ènìyàn ni pé nígbà tí ẹnìkan bá ṣe ìrúbọ, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, nígbà tí ẹran náà bá ń hó lórí iná, pẹ̀lú ọ̀pá-ẹran náà oníga mẹ́ta ní ọwọ́ rẹ̀. 14Òun a sì fi gún inú apẹ, tàbí àgé tàbí ọpọ́n, tàbí ìkòkò, gbogbo èyí tí ọ̀pá-ẹran oníga náà bá mú wá sí òkè, àlùfáà á mú un fún ara rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí gbogbo Israẹli tí ó wá sí ibẹ̀ ní Ṣilo. 15Pẹ̀lú, kí wọn tó sun ọ̀rá náà, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, á sì wí fún ọkùnrin tí ó ń ṣe ìrúbọ pé, “Fi ẹran fún mi láti sun fún àlùfáà; nítorí tí kì yóò gba ẹran sísè lọ́wọ́ rẹ, bí kò ṣe tútù.”
16Bí ọkùnrin náà bá sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí wọn ó sun ọ̀rá náà nísinsin yìí, kí o sì mú iyekíye tí ọkàn rẹ̀ bá fẹ́,” nígbà náà ni yóò dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó fi í fún mi nísinsin yìí, bí kó ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó fi agbára gbà á.”
17Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì tóbi gidigidi níwájú Olúwa: nítorí tí àwọn ènìyàn kórìíra ẹbọ Olúwa.
18Ṣùgbọ́n Samuẹli ń ṣe ìránṣẹ́ níwájú Olúwa, ọmọdé, ti a wọ̀ ní efodu ọ̀gbọ̀. 19Pẹ̀lúpẹ̀lú, ìyá rẹ̀ máa ń dá aṣọ ìlekè péńpé fún un, a sì máa mú wá fún un lọ́dọọdún, nígbà tí ó bá bá ọkọ rẹ̀ gòkè wá láti ṣe ìrúbọ ọdún. 20Eli súre fún Elkana àti aya rẹ̀ pé, “Kí Olúwa fún ọ ní irú-ọmọ láti ara obìnrin yìí wá, nítorí ẹ̀bùn tí ó béèrè tí ó sì tún fún Olúwa.” Wọ́n sì lọ sí ilé wọn. 21Olúwa si bojú wo Hana, ó sì lóyún, ó bí ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì. Samuẹli ọmọ náà sì ń dàgbà níwájú Olúwa.
22Eli sì di arúgbó gidigidi, ó sì gbọ́ gbogbo èyí ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe sí gbogbo Israẹli; àti bi wọ́n ti máa ń bá àwọn obìnrin sùn, tí wọ́n máa ń péjọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ. 23Ó sì wí fún wọn pé, kí ni ó ti ri “Èétirí tí èmi fi ń gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ sí yín? Nítorí tí èmi ń gbọ́ iṣẹ́ búburú yín láti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn. 24Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí kì ṣe ìròyìn rere èmi gbọ́; ẹ̀yin mú ènìyàn Ọlọ́run dẹ́ṣẹ̀. 25Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì, onídàájọ́ yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀: ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí Olúwa, ta ni yóò bẹ̀bẹ̀ fún un?” Wọn kò sì fi etí sí ohùn baba wọn, nítorí tí Olúwa ń fẹ́ pa wọ́n.
26Ọmọ náà Samuẹli ń dàgbà, ó sì rí ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa, àti ènìyàn pẹ̀lú.
Wòlíì sọtẹ́lẹ̀ nípa ilé Eli
27Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ Eli wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí, ‘Èmi fi ara mi hàn ní gbangba fún ilé baba rẹ, nígbà tí wọ́n ń bẹ ní Ejibiti nínú ilé Farao. 28Èmi sì yàn án kúrò láàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti jẹ́ àlùfáà mi, láti rú ẹbọ lórí pẹpẹ mi, láti fi tùràrí jóná, láti wọ efodu níwájú mi, èmi sì fi gbogbo ẹbọ tí ọmọ Israẹli máa ń fi iná sun fún ìdílé baba rẹ̀. 29Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi tàpá sí ẹbọ àti ọrẹ mi, tí mo pàṣẹ ní ibùjókòó mi: ìwọ sì bu ọlá fún àwọn ọmọ rẹ jù mí lọ, tí ẹ sì fi gbogbo àṣàyàn ẹbọ Israẹli àwọn ènìyàn mi mú ara yín sanra.’
30“Nítorí náà Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Èmi ti wí nítòótọ́ pé, ilé rẹ àti ilé baba rẹ, yóò máa rìn níwájú mi títí.’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa wí pé, ‘Kí á má rí i! Àwọn tí ó bú ọlá fún mi ni èmi yóò bu ọlá fún, àti àwọn tí kò kà mí sí ni a ó sì ṣe aláìkàsí. 31Kíyèsi i, àwọn ọjọ́ ń bọ̀ tí èmi ó gé agbára rẹ kúrò, àti agbára baba rẹ, tí kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ. 32Ìwọ yóò rí wàhálà ti Àgọ́, nínú gbogbo ọlá tí Ọlọ́run yóò fi fún Israẹli; kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ láéláé. 33Ọkùnrin tí ó jẹ́ tìrẹ, tí èmi kì yóò gé kúrò ní ibi pẹpẹ mi ni a ó dá sí láti sọkún yọ lójú àti láti banújẹ́: Ṣùgbọ́n gbogbo irú-ọmọ ilé rẹ̀ ni a ó fi idà pa ní ààbọ̀ ọjọ́ wọn.
34“ ‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ ọkùnrin rẹ̀ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, yóò jẹ́ ààmì fún ọ—àwọn méjèèjì yóò kú ní ọjọ́ kan náà. 35Èmi yóò dìde fún ara mi láti gbé àlùfáà olódodo dìde fún ara mi ẹni tí yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó wà ní ọkàn mi àti inú mi: Èmi yóò fi ẹsẹ̀ ilé rẹ̀ múlẹ̀ gbọningbọnin òun yóò sì ṣe òjíṣẹ́ níwájú ẹni òróró mi ní ọjọ́ gbogbo. 36Nígbà náà olúkúlùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá kù ní ìdílé yín, yóò jáde wá yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀ nítorí ẹyọ fàdákà àti nítorí èépá àkàrà àti ẹ̀bẹ̀ pé, “Jọ̀wọ́ yàn mí sí ọ̀kan nínú iṣẹ́ àwọn àlùfáà, kí èmi kí ó le máa rí oúnjẹ jẹ.” ’ ”
دعای حنا
1حنا اينطور دعا كرد:
«خداوند قلب مرا از شادی لبريز ساخته است،
او به من قدرت بخشيده و مرا تقويت نموده است.
بر دشمنانم میخندم و خوشحالم،
چون خداوند مرا ياری كرده است!
2«هيچكس مثل خداوند مقدس نيست،
غير از او خدايی نيست،
مثل خدای ما پناهگاهی نيست.
3«از سخنان و رفتار متكبرانه دست برداريد،
زيرا خداوند همه چيز را میداند؛
اوست كه كارهای مردم را داوری میكند.
4كمان جنگاوران شكسته شد،
اما افتادگان قوت يافتند.
5آنانی كه سير بودند برای نان، خود را اجير كردند،
ولی كسانی كه گرسنه بودند سير و راحت شدند.
زن نازا هفت فرزند زاييده است،
اما آنكه فرزندان زياد داشت، بیاولاد شده است.
6«خداوند میميراند و زنده میكند،
به گور فرو میبرد و بر میخيزاند.
7خداوند فقير میكند و غنی میسازد،
پست میكند و بلند میگرداند.
8فقير را از خاک بر میافرازد،
محتاج را از بدبختی بيرون میكشد،
و ايشان را چون شاهزادگان بر تخت عزت مینشاند.
ستونهای زمين از آن خداوند است،
او بر آنها زمين را استوار كرده است.
9«خدا مقدسين خود را حفظ میكند،
اما بدكاران در تاريكی محو میشوند؛
انسان با قدرت خود نيست كه موفق میشود.
10كسانی كه با خداوند مخالفت كنند نابود میگردند.
خدا بر آنها از آسمان صاعقه خواهد فرستاد؛
خداوند بر تمام دنيا داوری خواهد كرد.
او به پادشاه خود قدرت میبخشد،
و برگزيدهٔ خود را پيروز میگرداند.»
11آنگاه القانه به خانهٔ خود در رامه برگشت، ولی سموئيل در شيلوه ماند و زير نظر عيلی به خدمت خداوند مشغول شد.
پسران فاسد عيلی
12اما پسران خود عيلی بسيار فاسد بودند و برای خداوند احترامی قايل نبودند. 13-14وقتی كسی قربانی میكرد و گوشت قربانی را در ديگ میگذاشت تا بپزد، آنها يكی از نوكران خود را با چنگال سه دندانهای میفرستادند تا آن را به داخل ديگ فرو برد و از گوشتی كه در حال پختن بود هر قدر بيرون میآمد برای ايشان ببرد. پسران عيلی به همين طريق با تمام بنیاسرائيل كه برای عبادت به شيلوه میآمدند، رفتار میكردند. 15گاهی نوكر ايشان پيش كسانی كه میخواستند قربانی كنند میآمد و پيش از سوزاندن پيه قربانی، از آنها گوشت مطالبه میكرد؛ او به جای گوشت پخته، گوشت خام میخواست تا برای پسران عيلی كباب كند. 16اگر كسی اعتراض مینمود و میگفت: «اول بگذار پيه آن بر قربانگاه سوزانده شود، بعد هر قدر گوشت میخواهی بردار.»2:16 مطابق شريعت، پيهِ قربانی میبايست بر قربانگاه سوزانده شود. آن نوكر میگفت: «نه، گوشت را حالا به من بده، و گرنه خودم به زور میگيرم.»
17گناه پسران عيلی در نظر خداوند بسيار عظيم بود، زيرا به قربانیهایی كه مردم به خداوند تقديم میكردند، بیاحترامی مینمودند.
18سموئيل هر چند بچهای بيش نبود، ولی جليقهٔ مخصوص كاهنان را میپوشيد و خداوند را خدمت مینمود. 19مادرش هر سال يک ردای كوچک برای سموئيل میدوخت و هنگامی كه با شوهرش برای قربانی كردن میآمد، آن را به سموئيل میداد. 20پيش از مراجعت، عيلی كاهن، پدر و مادر سموئيل را بركت میداد و برای ايشان دعا میكرد كه خداوند فرزندان ديگر نيز به آنها بدهد تا جای سموئيل را كه در خدمت خداوند بود، بگيرند. 21پس خداوند سه پسر و دو دختر ديگر به حنا بخشيد. در ضمن، سموئيل در خدمت خداوند رشد میكرد.
22عيلی خيلی پير شده بود. او از رفتار پسرانش با قوم اسرائيل اطلاع داشت و میدانست كه پسرانش با زنانی كه كنار در ورودی خيمهٔ عبادت خدمت میكنند همخواب میشوند. 23پس به پسرانش گفت: «چرا چنين میكنيد؟ دربارهٔ كارهای بد شما از تمام قوم میشنوم. 24ای پسرانم، از اين كارها دست برداريد. آنچه از قوم خداوند دربارهٔ شما میشنوم، وحشتناک است! 25اگر كسی نسبت به همنوع خود گناه ورزد، خدا ممكن است برای او شفاعت كند، اما برای شما كه بر ضد خود خداوند گناه ورزيدهايد، كيست كه بتواند شفاعت نمايد؟» ولی آنها به سخنان پدر خود گوش ندادند، زيرا خداوند میخواست آنها را هلاک كند.
26اما سموئيل كوچک رشد میكرد و خداوند و مردم او را دوست میداشتند.
پيشگويی بر ضد خاندان عيلی
27روزی يک نبی نزد عيلی آمد و از طرف خداوند برای او اين پيغام را آورد: «آيا زمانی كه اجداد تو در مصر بردهٔ فرعون بودند، قدرت خود را به آنها نشان ندادم؟ 28آيا جد تو لاوی را از ميان برادرانش انتخاب نكردم تا كاهن من باشد و بر قربانگاه من قربانی كند و بخور بسوزاند و لباس كاهنی را در حضورم بپوشد؟ آيا تمام هدايايی را كه قوم اسرائيل بر آتش تقديم میكنند، برای شما كاهنان تعيين نكردم؟ 29پس چرا اينقدر حريص هستيد و میخواهيد قربانیها و هدايايی را نيز كه برای من میآورند، تصاحب نماييد؟ چرا پسران خود را بيش از من احترام میكنی؟ تو و پسرانت با خوردن بهترين قسمتِ هدايای قوم من، خود را چاق و فربه ساختهايد. 30بنابراين، من كه خداوند، خدای اسرائيل هستم اعلان میكنم كه اگرچه گفتم كه خاندان تو و خاندان پدرت برای هميشه كاهنان من خواهند بود، اما شما را از اين خدمت بركنار میكنم. هر كه مرا احترام كند، او را احترام خواهم نمود و هر كه مرا تحقير كند او را تحقير خواهم كرد. 31زمانی میرسد كه خاندان تو را برخواهم انداخت به طوری كه افراد خانهات همه جوانمرگ شده، به سن پيری نخواهند رسيد 32و چشمان تو مصيبتی را كه دامنگير عبادتگاه من میشود خواهد ديد. من به بنیاسرائيل بركت خواهم داد، اما در خاندان تو هيچكس به سن پيری نخواهد رسيد. 33آنانی نيز كه از خاندان تو باقی بمانند، باعث غم و رنج تو خواهند شد و تمام نسل تو در جوانی خواهند مرد. 34برای اينكه ثابت شود هر آنچه به تو گفتم واقع خواهد شد، بدان كه دو پسرت حُفنی و فينحاس در يک روز خواهند مرد!
35«سپس كاهن امينی روی كار خواهم آورد كه مطابق ميل من خدمت كند و هر آنچه را كه به او دستور دهم انجام دهد. به او فرزندان خواهم بخشيد و آنها برای پادشاه برگزيدهٔ من تا ابد كاهن خواهند شد. 36آنگاه هر كه از خاندان تو باقی مانده باشد برای پول و نان در برابر او زانو زده، تعظيم خواهد كرد و خواهد گفت: التماس میكنم در میان كاهنان خود به من كاری بدهيد تا شكم خود را سير كنم.»