1 Peteru 1 – YCB & SZ-PL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Peteru 1:1-25

1Peteru, aposteli Jesu Kristi,

Sí àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run, ti wọ́n ń ṣe àtìpó ní àgbáyé, tiwọn tú káàkiri sí Pọntu, Galatia, Kappadokia, Asia, àti Bitinia, 2àwọn ẹni tí a ti yàn gẹ́gẹ́ bí ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run Baba, nípa ìsọdimímọ́ Ẹ̀mí, sí ìgbọ́ràn àti ìbùwọ́n ẹ̀jẹ̀ Jesu Kristi:

Kí oore-ọ̀fẹ́ àti àlàáfíà máa bí sì fún yín.

Ìyìn sí Ọlọ́run fún ìrètí tó wà láààyè

3Ìyìn yẹ Ọlọ́run àti Baba Jesu Kristi Olúwa wa! Ẹni tí ó tún wa bí gẹ́gẹ́ bí àánú ńlá rẹ̀ sínú ìrètí ààyè nípa àjíǹde Jesu Kristi kúrò nínú òkú, 4àti sínú ogún àìdíbàjẹ́, àti àìlábàwọ́n, àti èyí tí kì í ṣá, tí a ti fi pamọ́ ni ọ̀run dè yin, 5ẹyin tí a ń pamọ́ nípa agbára Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ si ìgbàlà, tí a múra láti fihàn ní ìgbà ìkẹyìn. 6Ẹ yọ̀ nínú èyí púpọ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pe nísinsin yìí fún ìgbà díẹ̀, níwọ̀n bí ó ti yẹ, a ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdánwò bá yín nínú jẹ́: 7Àwọn wọ̀nyí sì wáyé ki ìdánwò ìgbàgbọ́ yín tí ó ni iye lórí ju wúrà, ti ń ṣègbé lọ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé iná ni a fi ń dán an wò, lè yọrísí ìyìn àti ògo àti ọlá ni ìgbà ìfarahàn Jesu Kristi. 8Ẹni tí ẹ̀yin fẹ́ láìrí, ẹni tí ẹ̀yin gbàgbọ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ kò rí i nísinsin yìí ẹ̀yin sì ń yọ ayọ̀ tí a kò lè fi ẹnu sọ, tí ó sì kún fún ògo; 9ẹyin sì ń gba ìlépa ìgbàgbọ́ yín, àní ìgbàlà ọkàn yín.

10Ní ti ìgbàlà yìí, àwọn wòlíì tí wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa oore-ọ̀fẹ́ tí ó mú tọ̀ yín wá, wọ́n wádìí jinlẹ̀ lẹ́sọ̀ lẹ́sọ̀. 11Wọ́n ń wádìí ìgbà wo tàbí irú sá à wo ni Ẹ̀mí Kristi tí ó wà nínú wọ́n ń tọ́ka sí, nígbà tí ó jẹ́rìí ìyà Kristi àti ògo tí yóò tẹ̀lé e. 12Àwọn ẹni tí a fihàn fún, pé kì í ṣe fún àwọn tìkára wọn, bí kò ṣe fún àwa ni wọ́n ṣe ìránṣẹ́ ohun wọ̀n-ọn-nì, tí a ti ròyìn fún yin nísinsin yìí, láti ọ̀dọ̀ àwọn tó ti ń wàásù ìhìnrere náà fún yín nípasẹ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ tí a rán wá láti ọ̀run; ohun tí àwọn angẹli ń fẹ́ láti wò.

Ẹ jẹ́ mímọ́

13Nítorí náà, ẹ múra ọkàn yín sílẹ̀, ẹ kó ara yín ní ìjánu, kí ẹ sì fi ìrètí yín ní kíkún sí oore-ọ̀fẹ́, èyí tí a ń mu bọ̀ fún yin ni ìgbà ìfarahàn Jesu Kristi. 14Bí àwọn ọmọ tí ń gbọ́rọ̀, ẹ ma ṣe da ara yín pọ̀ mọ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àìmọ́ yín ti àtijọ́. 15Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹni tí o pè yin ti jẹ mímọ́; bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà jẹ mímọ́. 161.16: Le 11.44-45.Nítorí a ti kọ ọ pé, “Ẹ jẹ́ mímọ́: nítorí tí Èmi jẹ mímọ́!”

17Níwọ́n bí ẹ̀yin ti ń ké pe Baba, ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ olúkúlùkù láìṣe ojúsàájú, ẹ máa lo ìgbà àtìpó yin ni ìbẹ̀rù. 18Níwọ̀n bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé a kò fi ohun ìdíbàjẹ́ rà yín padà, bí fàdákà tàbí wúrà kúrò nínú ìwà asán yín, tí ẹ̀yin ti jogún láti ọ̀dọ̀ àwọn baba yín. 19Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ iyebíye, bí i ti ọ̀dọ́-àgùntàn ti kò lábùkù, tí kò sì lábàwọ́n, àní, ẹ̀jẹ̀ Kristi. 20Ẹni tí a ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ nítòótọ́ ṣáájú ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé, ṣùgbọ́n tí a fihàn ní ìgbà ìkẹyìn wọ̀nyí nítorí yín, 21Àní ẹ̀yin tí o tipasẹ̀ rẹ̀ gba Ọlọ́run gbọ́, ẹni ti ó jí i dìde kúrò nínú òkú, tí ó sì fi ògo fún un; kí ìgbàgbọ́ àti ìrètí yín lè wà lọ́dọ̀ Ọlọ́run.

22Níwọ́n bí ẹ̀yin ti wẹ ọkàn yin mọ́ nípa ìgbọ́ràn yín sí òtítọ́ sí ìfẹ́ ará ti kò ní ẹ̀tàn, ẹ fẹ́ ọmọnìkejì yín gidigidi láti ọkàn wá. 23Bí a ti tún yín bí, kì í ṣe láti inú ìdíbàjẹ́ wá, bí kò ṣe èyí ti kì í díbàjẹ́ nípa ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí ń bẹ láààyè tí ó sì dúró. 241.24-25: Isa 40.6-9.Nítorí pé,

“Gbogbo ènìyàn dàbí koríko,

àti gbogbo ògo rẹ̀ bi ìtànná koríko.

Koríko á máa gbẹ ìtànná a sì máa rẹ̀ dànù,

25Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Olúwa dúró títí láé.”

Ọ̀rọ̀ náà yìí sì ni ìhìnrere tí a wàásù fún yín.

Słowo Życia

1 Piotra 1:1-25

Pozdrowienie

1Ja Piotr, apostoł Jezusa Chrystusa, piszę do wybranych, którzy jako cudzoziemcy mieszkają na obczyźnie: w Poncie, Galicji, Kapadocji, Azji i Bitynii.

2Bóg Ojciec, zgodnie ze swoim odwiecznym postanowieniem, wybrał was i przeznaczył do świętego życia w Duchu oraz do posłuszeństwa. On również, dzięki krwi przelanej przez Jezusa Chrystusa, oczyścił was z grzechów. Niech Jego łaska i pokój wydają wśród was coraz większy owoc!

Nowe życie

3Chwała niech będzie Bogu—Ojcu naszego Pana, Jezusa Chrystusa—który w swojej ogromnej miłości zrodził nas do nowego życia. On, dzięki zmartwychwstaniu Chrystusa, dał nam żywą nadzieję na przyszłość 4i przygotował dla was bezcenny dar w niebie—niezniszczalny, nieskażony i nietracący blasku!

5Uwierzyliście Bogu, dlatego On będzie was chronił swoją potężną mocą—do czasu, w którym objawi wszystkim wasze zbawienie. 6Cieszcie się więc, mimo że teraz różne chwilowe trudności sprawiają wam smutek. 7Dzięki nim jednak wasza wiara oczyszcza się i staje się cenniejsza od nietrwałego złota, które również oczyszcza się w ogniu. Gdy więc Jezus Chrystus powtórnie się objawi, wasza wiara zostanie doceniona i otoczona chwałą. 8Wiem, że chociaż nie widzieliście Pana, to bardzo Go kochacie. Teraz nadal Go nie widzicie, ale wierzycie Mu i doznajecie niezmiernej, cudownej radości 9z powodu waszego zbawienia. Ono jest celem waszej wiary!

10Właśnie to zbawienie było przedmiotem poszukiwań i dociekań proroków. Oni to zapowiadali, że Bóg okaże wam swoją łaskę. 11Zastanawiali się jednak, kiedy nadejdą cierpienia Chrystusa, zapowiedziane przez Jego Ducha, i kiedy objawi się Jego chwała. 12Bóg zaś powiedział im, że oni tego nie doczekają, ale wy—tak. I właśnie o tym—z pomocą zesłanego z nieba Ducha Świętego—powiedzieli wam ci, którzy przekazali wam dobrą nowinę. Są to rzeczy, które pragnęliby poznać nawet aniołowie.

Bądźcie święci

13Dlatego zachowujcie czujność oraz trzeźwość umysłu. Całą zaś waszą nadzieję złóżcie w Bożej łasce—w dniu powrotu Jezusa Chrystusa doświadczycie jej bowiem w całej pełni! 14Dawniej, gdy nie znaliście Pana, waszym życiem kierowały grzeszne pragnienia. Teraz jednak nie poddawajcie się im i zachowujcie się jak posłuszne dzieci. 15Naśladujcie Boga, który jest święty, i w każdej sytuacji również wy bądźcie święci. 16Pismo bowiem mówi: „Bądźcie święci, bo Ja jestem święty”.

Jezus złożył za nas okup

17Jeśli Boga, który jest bezstronnym sędzią ludzkich czynów, nazywacie swoim Ojcem, okazujcie Mu respekt do końca waszego życia na ziemi. 18Pamiętajcie też, że z powodu złego postępowania, odziedziczonego po waszych przodkach, byliście niewolnikami zła, ale zostaliście wykupieni przez Boga! I to nie marnym srebrem lub złotem, 19ale bezcenną krwią Chrystusa. On został bowiem zabity jak niewinny i czysty ofiarny baranek! 20Bóg przeznaczył Go do tego jeszcze przed powstaniem świata, ale—ze względu na was—Chrystus przyszedł na świat dopiero teraz, w czasach ostatecznych. 21To dzięki Niemu uwierzyliście Bogu, który wzbudził Go z martwych i otoczył chwałą. Od Niego pochodzi więc wasza wiara i nadzieja, którą złożyliście w Bogu.

22Okazaliście posłuszeństwo prawdzie i oczyściliście swoje dusze. Teraz więc bez obłudy, zupełnie szczerze, okazujcie miłość innym wierzącym. 23Narodziliście się bowiem na nowo dzięki słowu Bożemu, które jest jak niezniszczalne ziarno na zasiew—jest żywe i trwa na wieki. 24Pismo mówi:

„Ludzie są jak trawa,

a ich piękno jest jak kwiat.

Trawa usycha, kwiat opada,

25ale słowo Pana trwa na wieki”.

Dobra nowina, którą usłyszeliście, jest właśnie słowem Pana!