1 Kọrinti 16 – YCB & NIRV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Kọrinti 16:1-24

Ìkójọpọ̀ fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run

116.1: Ap 24.17.Ǹjẹ́ ní ti ìdáwó fún àwọn ènìyàn mímọ́, bí mo tí wí fún àwọn ìjọ Galatia, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní kí ẹ ṣe. 216.2: Ap 20.7; 2Kọ 9.4-5.Ní ọjọ́ kìn-ín-ní ọ̀sẹ̀, kí olúkúlùkù yín fi sínú ìṣúra lọ́dọ̀ ara rẹ̀ ni apá kan, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti ṣe rere fún ún, ki ó má ṣe si ìkójọ nígbà tí mo bá dé. 316.3: 2Kọ 8.18-19.Àti nígbà ti mo bá dé, àwọn ẹni tí ẹ bá yàn, àwọn ni èmi ó rán láti mú ẹ̀bùn yín gòkè lọ si Jerusalẹmu. 4Bí ó bá sì yẹ kí èmí lọ pẹ̀lú, wọn ó sì bá mi lọ.

Ìbéèrè ti ara ẹni

516.5: Ro 15.26; Ap 19.21.Ṣùgbọ́n èmi yóò tọ̀ yin wá, nígbà tí èmí bá ti kọjá láàrín Makedonia: nítorí èmi yóò kọjá láàrín Makedonia. 6Bóyá èmi ó sì dúró pẹ̀lú yín, tàbí kí n tilẹ̀ lo àkókò òtútù, ki ẹ̀yin lé sìn mí ni ọ̀nà àjò mí, níbikíbi tí mo bá ń lọ. 716.7: Ap 18.21.Nítorí èmi kò fẹ́ kan ri yín kí èmi sì ṣe bẹ́ẹ̀ kọjá lọ; nítorí èmi ń retí àti dúró lọ́dọ̀ yín díẹ̀, bí Olúwa bá fẹ́ 816.8: Ap 18.19.Ṣùgbọ́n èmi yóò dúró ni Efesu títí dí Pentikosti. 916.9: Ap 19.9.Nítorí pé ìlẹ̀kùn ńlá láti ṣe iṣẹ́ gidi ṣí sílẹ̀ fún mí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ sì ni àwọn ọ̀tá tí ń bẹ.

1016.10: Ap 16.1.Ǹjẹ́ bí Timotiu bá dé, ẹ jẹ́ kí ó wà lọ́dọ̀ yín láìbẹ̀rù: nítorí òun ń ṣé iṣẹ́ Olúwa, bí èmi pẹ̀lú ti ń ṣe. 11Nítorí náà kí ẹnikẹ́ni má ṣe kẹ́gàn rẹ̀. Ṣùgbọ́n ẹ sín ín jáde lọ́nà àjò ni àlàáfíà, kí òun lè tọ̀ mí wá; nítorí tí èmí ń fi ojú sí ọ̀nà fún wíwá rẹ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin.

1216.12: Ap 18.24.Ṣùgbọ́n ní ti Apollo arákùnrin wa, mo bẹ̀ ẹ́ púpọ̀ láti tọ̀ yín wá pẹ̀lú àwọn arákùnrin: Ṣùgbọ́n kì í ṣe ìfẹ́ rẹ̀ rárá láti wà nísinsin yìí, ṣùgbọ́n òun yóò wá nígbà tí ààyè bá ṣí sílẹ̀ fún un.

1316.13: Sm 31.24; Ef 6.10.Ẹ máa ṣọ́ra, ẹ dúró ṣinṣin nínú ìgbàgbọ́, ẹ ṣe bi ọkùnrin tí ó ní ìgboyà, ẹ jẹ́ alágbára. 14Ẹ máa ṣe ohun gbogbo nínú ìfẹ́.

15Ǹjẹ́ mo bẹ̀ yín ará, ẹ ṣá mọ ilé Stefana pé, àwọn ni ẹni àkọ́kọ́ tó gba Jesu ní Akaia, àti pé, wọn sì tí fi ará wọn fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ àwọn ènìyàn mímọ́. 16Kí ẹ̀yin tẹríba fún irú àwọn báwọ̀nyí, àti fún olúkúlùkù olùbáṣiṣẹ́ pọ̀ pẹ̀lú wa tí ó sì ń ṣe làálàá. 17Mo láyọ̀ fún wíwá Stefana àti Fortunatu àti Akaiku: nítorí èyí tí ó kù nípá tí yín wọ́n ti fi kún un. 18Nítorí tí wọ́n tu ẹ̀mí mí lára àti tiyín: nítorí náà, ẹ máa gba irú àwọn ti ó rí bẹ́ẹ̀.

Ìkíni ìkẹyìn

1916.19: Ap 18.2; Ro 16.5.Àwọn ìjọ ni Asia kí í yín.

Akuila àti Priskilla kí í yín púpọ̀ nínú Olúwa, pẹ̀lú ìjọ tí ó wà ni ilé wọn.

2016.20: Ro 16.16.Gbogbo àwọn arákùnrin kí í yín.

Ẹ fi ìfẹnukonu mímọ́ kí ara yín.

2116.21: Kl 4.18; Ga 6.11; 2Tẹ 3.17.Ìkíni ti èmi Paulu, láti ọwọ́ èmi tìkára mi wá.

2216.22: Ro 9.3.Bí ẹnikẹ́ni kò bá ní ìfẹ́ Jesu Kristi Olúwa, jẹ́ kí ó dì ẹni ìfibú. Máa bọ Olúwa wa!

2316.23: Ro 16.20.Oore-ọ̀fẹ́ Jesu Kristi Olúwa kí ó wà pẹ̀lú yín!

24Ìfẹ́ mi wá pẹ̀lú gbogbo yín nínú Kristi Jesu. Àmín.

New International Reader’s Version

1 Corinthians 16:1-24

The Offering for the Lord’s People

1Now I want to deal with the offering of money for the Lord’s people. Do what I told the churches in Galatia to do. 2On the first day of every week, each of you should put some money away. The amount should be in keeping with how much money you make. Save the money so that you won’t have to take up an offering when I come. 3When I arrive, I will send some people with your gift to Jerusalem. They will be people you consider to be good. And I will give them letters that explain who they are. 4If it seems good for me to go also, they will go with me.

What Paul Asks for Himself

5After I go through Macedonia, I will come to you. I will only be passing through Macedonia. 6But I might stay with you for a while. I might even spend the winter. Then you can help me on my journey everywhere I go. 7I don’t want to see you now while I am just passing through. Instead, I hope to spend some time with you, if the Lord allows it. 8But I will stay at Ephesus until the day of Pentecost. 9A door has opened wide for me to do some good work here. There are many people who oppose me.

10Timothy will visit you. Make sure he has nothing to worry about while he is with you. He is doing the work of the Lord, just as I am. 11No one should treat him badly. Send him safely on his way so he can return to me. I’m expecting him to come back along with the others.

12I want to say something about our brother Apollos. I tried my best to get him to go to you with the others. But he didn’t want to go right now. He will go when he can.

13Be on your guard. Remain strong in the faith. Be brave. 14Be loving in everything you do.

15You know that the first believers in Achaia were from the family of Stephanas. They have spent all their time serving the Lord’s people. Brothers and sisters, I am asking you 16to follow the lead of people like them. Follow everyone who joins in the task and works hard at it. 17I was glad when Stephanas, Fortunatus and Achaicus arrived. They have supplied me with what you couldn’t give me. 18They renewed my spirit, and yours also. People like them are worthy of honor.

Final Greetings

19The churches in Asia Minor send you greetings.

Aquila and Priscilla greet you warmly because of the Lord’s love. So does the church that meets in their house.

20All the brothers and sisters here send you greetings.

Greet one another with a holy kiss.

21I, Paul, am writing this greeting with my own hand.

22If anyone does not love the Lord, let a curse be on that person! Come, Lord!

23May the grace of the Lord Jesus be with you.

24I give my love to all of you who belong to Christ Jesus. Amen.