1 Kọrinti 15 – YCB & CARSA

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Kọrinti 15:1-58

Àjíǹde Kristi

1Ǹjẹ́ ará, èmi ń sọ ìhìnrere náà dí mí mọ̀ fún un yín, tí mo ti wàásù fún un yín, èyí tí ẹ̀yin pẹ̀lú ti gbá, nínú èyí tí ẹ̀yin sì dúró. 2Nípasẹ̀ ìhìnrere yìí ni a fi ń gbà yín là pẹ̀lú, bí ẹ̀yin bá di ọ̀rọ̀ ti mo ti wàásù fún yín mú ṣinṣin. Bí bẹ́ẹ̀ kọ̀, ẹ̀yin kàn gbàgbọ́ lásán.

315.3: 1Kọ 11.23; 1Pt 2.24; Isa 53.5-12.Nítorí èyí tí mo rí gbà ṣáájú ohun gbogbo ní èmi pẹ̀lú ti fi lé e yín lọ́wọ́, bí Kristi ti kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìwé mímọ́ tí wí. 415.4: Mt 16.21; Sm 16.8-9.Àti pé a sìnkú rẹ̀, àti pé ó jíǹde ní ọjọ́ kẹta gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ tí wí; 515.5: Lk 24.34; Mt 28.17.Àti pé ó farahàn Peteru, lẹ́yìn èyí, àwọn méjìlá 6Lẹ́yìn èyí, ó farahàn àwọn ará tí o jú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta lọ lẹ́ẹ̀kan náà; ọ̀pọ̀ nínú wọn wà títí fi di ìsinsin yìí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn. 7Lẹ́yìn èyí ni ó farahan Jakọbu; lẹ́yìn náà fún gbogbo àwọn aposteli. 815.8: 1Kọ 9.1; Ga 1.16; Ap 9.3-6.Àti níkẹyìn gbogbo wọn ó farahàn mí pẹ̀lú, bí ẹni tí a bí ṣáájú àkókò rẹ̀.

915.9: Ap 8.3.Nítorí èmi ni ẹni tí ó kéré jùlọ nínú àwọn aposteli, èmi ẹni tí kò yẹ láti pè ní aposteli, nítorí tí mo ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run. 10Ṣùgbọ́n nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run mo rí bí mo ti rí: oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí a fi fún mi kò sì jẹ́ asán; ṣùgbọ́n mó ṣiṣẹ́ lọ́pọ̀lọpọ̀ jú gbogbo wọn lọ: ṣùgbọ́n kì í ṣe èmi, bí kò ṣe oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí ó wà pẹ̀lú mi. 11Nítorí náà ìbá à ṣe èmí tàbí àwọn ni, èyí ní àwa wàásù, èyí ní ẹ̀yin sì gbàgbọ́.

Àjíǹde òkú

12Ǹjẹ́ bí a bá wàásù Kristi pé ó tí jíǹde kúrò nínú òkú, èéha tí ṣe tí àwọn mìíràn nínú yín fi wí pé, àjíǹde òkú kò sí. 13Ṣùgbọ́n bí àjíǹde òkú kò sí, ǹjẹ́ Kristi kò jíǹde. 1415.14: 1Tẹ 4.14.Bí Kristi kò bá sì jíǹde, ǹjẹ́ asán ni ìwàásù wà, asán sì ni ìgbàgbọ́ yín pẹ̀lú. 15Ṣùgbọ́n jù bẹ́ẹ̀ lọ, a mú wa ni ẹlẹ́rìí èké fún Ọlọ́run; nítorí ti àwa jẹ́rìí Ọlọ́run pé ó jí Kristi dìde kúrò nínú òkú: ẹni tí òun kò jí dìde bí ó bá ṣe pé àwọn òkú kò jíǹde? 16Nítorí pé bi á kò bá jí àwọn òkú dìde, ǹjẹ́ a kò jí Kristi dìde, 17bí a kò bá sì jí Kristi dìde, asán ní ìgbàgbọ́ yín; ẹ̀yin wà nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín síbẹ̀. 1815.18: 1Tẹ 4.16.Ǹjẹ́ àwọn pẹ̀lú tí ó sùn nínú Kristi ṣègbé. 19Bí ó bá ṣe pé kìkì ayé yìí nìkan ní àwa ní ìrètí nínú Kristi, àwa jásí òtòṣì jùlọ nínú gbogbo ènìyàn.

20Ǹjẹ́ nísinsin yìí Kristi tí jíǹde kúrò nínú òkú, ó sì dí àkọ́bí nínú àwọn tí ó sùn. 2115.21: Ro 5.12.Nítorí ìgbà tí ó jẹ́ pé nípa ènìyàn ní ikú ti wá, nípa ènìyàn ní àjíǹde òkú sì ti wá pẹ̀lú. 2215.22: Ro 5.14-18.Nítorí bí gbogbo ènìyàn ti kú nínú Adamu, bẹ́ẹ̀ ní a ó sì sọ gbogbo ènìyàn dí alààyè nínú Kristi. 2315.23: 1Tẹ 2.19.Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ènìyàn ní ipá tirẹ̀: Kristi àkọ́bí; lẹ́yìn èyí àwọn tí ó jẹ́ tí Kristi ni wíwá rẹ̀. 24Nígbà náà ni òpin yóò dé, nígbà tí ó bá ti fi ìjọba fún Ọlọ́run Baba, nígbà tí ó bá pa gbogbo àṣẹ àti gbogbo ọlá àti agbára run. 2515.25: Sm 110.1.Nítorí ti òun gbọdọ̀ ti jẹ ọba kí òun to fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀. 26Ikú ní ọ̀tá ìkẹyìn tí a ó parun 2715.27: Sm 8.6; Ef 1.22.“Nítorí ó ti fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wí pé, “Ohun gbogbo ni á fi sí abẹ́ rẹ̀,” o dájú pé Ọlọ́run nìkan ṣoṣo ní kò sí ní abẹ́ rẹ̀, Òun ní ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ àkóso Kristi. 2815.28: Fp 3.21.Nígbà tí a bá sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀ tán, nígbà náà ni á ó fi ọmọ tìkára rẹ̀ pẹ̀lú sábẹ́ Ẹni tí ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jásí ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.

29Ní báyìí, bí kò bá sí àjíǹde, kín ní ète àwọn ènìyàn tí wọn ń tẹ bọ omi nítorí òkú? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde rárá, nítorí kín ni a ṣe ń bamitiisi wọn nítorí wọn? 30Nítorí kín ní àwa sì ṣe ń bẹ nínú ewu ni wákàtí gbogbo? 31Mo sọ nípa ayọ̀ tí mo ní lórí yín nínú Kristi Jesu Olúwa wá pé, èmi ń kú lójoojúmọ́. 3215.32: 2Kọ 8–9; Isa 22.13.Kí a wí bí ènìyàn, bí mo bá ẹranko jà ní Efesu, àǹfààní kín ni ó jẹ́ fún mi? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde,

“Ẹ jẹ́ kí a máa jẹ, kí á máa mú;

nítorí ní ọlá ni àwa ó kú.”

33Kí a má tàn yín jẹ́, “Ẹgbẹ́ búburú bá ìwà rere jẹ́.” 3415.34: Ro 13.11.Ẹ jí ìjí òdodo, kí ẹ má sì dẹ́ṣẹ̀; nítorí àwọn ẹlòmíràn kò ni imọ̀ Ọlọ́run, mo sọ èyí kí ojú ba à lè tiyín.

Àjíǹde ara

35Ṣùgbọ́n ẹnìkan yóò wí pé, “Báwo ni àwọn òkú yóò ṣe jíǹde? Irú ara wó ni wọn ó padà sí?” 3615.36: Jh 12.24.Ìwọ aláìmòye, ohun tí ìwọ fúnrúgbìn kì í yè bí kò ṣe pé ó ba kú: 37Àti èyí tí ìwọ fúnrúgbìn, kì í ṣe ara tí ń bọ̀ ni ìwọ fúnrúgbìn, ṣùgbọ́n èso lásán ni, ìbá à ṣe alikama, tàbí irú mìíràn. 3815.38: Gẹ 1.11.Ṣùgbọ́n Ọlọ́run fún ún ni ara bí o tí wù ú, àti fún olúkúlùkù irúgbìn ara tirẹ̀. 39Gbogbo ẹran-ara kì í ṣe ẹran-ara kan náà: ṣùgbọ́n ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ènìyàn, ọ̀tọ̀ ni ẹran-ara ti ẹranko, ọ̀tọ̀ ní ti ẹja, ọ̀tọ̀ sì ní tí ẹyẹ. 40Ará ti òkè ọ̀run ń bẹ, ara ti ayé pẹ̀lú sì ń bẹ: ṣùgbọ́n ògo ti òkè ọ̀run ọ̀tọ̀, àti ògo ti ayé ọ̀tọ̀. 41Ọ̀tọ̀ ni ògo ti oòrùn, ọ̀tọ̀ ni ògo ti òṣùpá, ọ̀tọ̀ sì ni ògo ti ìràwọ̀; ìràwọ̀ ṣá yàtọ̀ sí ìràwọ̀ ni ògo.

4215.42: Da 12.3.Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sí ni àjíǹde òkú. A gbìn ín ní ìdíbàjẹ́; a sí jì í dìde ni àìdíbàjẹ́: 43A gbìn ín ni àìní ọlá, a sí jí i dìde ni ògo; a gbìn ín ni àìlera, a sì jí í dìde ní agbára. 44A gbìn ín ni, ara ẹran a sì jí i dìde ni ara ti ẹ̀mí.

Bí ara ẹran bá ń bẹ, ara ẹ̀mí náà sì ń bẹ. 4515.45: Gẹ 2.7.Bẹ́ẹ̀ ní a si kọ ọ́ pé, “Adamu ọkùnrin ìṣáájú, alààyè ọkàn ni a dá a;” Adamu ìkẹyìn ẹ̀mí ìsọnidààyè. 46Ṣùgbọ́n èyí tí í ṣe tí ẹ̀mí kọ ní ó kọ́kọ́ ṣáájú, bí kò ṣe èyí tí í ṣe tí ara ọkàn, lẹ́yìn náà èyí ti í ṣe ti ẹ̀mí. 47Ọkùnrin ìṣáájú ti inú erùpẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ẹni erùpẹ̀: ọkùnrin èkejì láti ọ̀run wá ni. 48Bí ẹni erùpẹ̀ ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe erùpẹ̀: bí ẹni tí ọ̀run ti rí, irú bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn tí í ṣe tí ọ̀run. 49Bí àwa ti rú àwòrán ẹni erùpẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwa ó sì rú àwòrán ẹni ti ọ̀run.

50Ará, ǹjẹ́ èyí ní mo wí pé, ara àti ẹ̀jẹ̀ kò lè jogún ìjọba Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìdíbàjẹ́ kò lé jogún àìdíbàjẹ́. 51Kíyèsi í, ohun ìjìnlẹ̀ ni mo sọ fún un yín: gbogbo wá kì yóò sùn, ṣùgbọ́n gbogbo wá ní a ó paláradà, 52Lọ́gán, ni ìṣẹ́jú kan, nígbà ìpè ìkẹyìn: nítorí ìpè yóò dún, a ó sì jí àwọn òkú dìde ní àìdíbàjẹ́, a ó sì pa wá láradà. 53Nítorí pé ara ìdíbàjẹ́ yìí kò lè ṣàìgbé ìdíbàjẹ́ wọ̀, àti ara kíkú yìí kò lè ṣàìgbé ara àìkú wọ̀. 5415.54: Isa 25.8.Ṣùgbọ́n nígbà tí ará ìdíbàjẹ́ yìí bá ti gbé àìdíbàjẹ́ wọ̀, ti ara kíkú yìí bá sí ti gbé àìkú wọ̀ bẹ́ẹ̀ tan, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ ti a kọ yóò ṣẹ pé, “A gbé ikú mí ní ìṣẹ́gun.”

55“Ikú, oró rẹ dà?

Ikú, ìṣẹ́gun rẹ́ dà?”

56Oró ikú ni ẹ̀ṣẹ̀; àti agbára ẹ̀ṣẹ̀ ni òfin 57Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ní fún Ọlọ́run ẹni tí ó fì ìṣẹ́gun fún wá nípa Olúwa wá Jesu Kristi!

58Nítorí náà ẹ̀yin ará mi olùfẹ́ ẹ máa dúró ṣinṣin, láìyẹsẹ̀, kí ẹ máa pọ̀ si í ní iṣẹ́ Olúwa nígbà gbogbo, ní ìwọ̀n bí ẹ̀yin ti mọ̀ pé iṣẹ́ yin kì í ṣe asán nínú Olúwa.

Священное Писание (Восточный перевод), версия с «Аллахом»

1 Коринфянам 15:1-58

Воскресение Исы аль-Масиха

1Братья, хочу ещё раз напомнить вам Радостную Весть, которую я вам возвещал, которую вы приняли и в которой вы утвердились. 2Она спасительна для вас, если только твёрдо придерживаетесь того, что я вам возвещал, а иначе ваша вера напрасна.

3Самое важное, что я получил, я передал вам: аль-Масих умер за наши грехи согласно Писанию. 4Он был погребён, и был воскрешён на третий день согласно Писанию15:4 См. Мат. 12:40; Юнус 2:1; ср. также Ос. 6:2.. 5Он явился Кифе и потом двенадцати ученикам. 6После этого Он явился ещё более чем пятистам братьям одновременно. Большинство из них ещё живы, а некоторые уже умерли. 7Затем Он явился Якубу15:7 Скорее всего, это был единоутробный брат Исы аль-Масиха (см. Мат. 13:55), важнейший лидер общины верующих в Иерусалиме., потом также всем посланникам аль-Масиха, 8и последнему из всех явился мне, жалкому недоноску.

9Ведь я самый наименьший15:9 Наименьший – возможно, здесь наблюдается игра слов, так как имя Паул переводится как «маленький», «низкий». из посланников аль-Масиха и даже не заслуживаю чести называться посланником, потому что я преследовал святой народ Аллаха. 10Но по благодати Аллаха я есть тот, кто я есть, и Его благодать во мне была не напрасной: я трудился больше, чем все остальные, впрочем не я, а благодать Аллаха, которая со мной. 11Не имеет значения, кто возвещает: я или они. Главное – вы поверили в то, что мы возвещаем.

Воскресение мёртвых

12Скажите мне, если об аль-Масихе возвещается, что Он был воскрешён из мёртвых, то как это некоторые из вас могут утверждать, что нет воскресения мёртвых? 13Если воскресения мёртвых нет, то и аль-Масих не мог быть воскрешён. 14А если аль-Масих не воскрес, то и всё, что мы возвещаем, не имеет смысла, равно как и ваша вера. 15Мы сами в таком случае оказываемся лжесвидетелями об Аллахе, так как мы засвидетельствовали о том, что Аллах воскресил аль-Масиха, Которого Он не воскрешал, если, конечно, мёртвых вообще нельзя воскресить. 16Ведь если мёртвых нельзя воскресить, то и аль-Масих не был воскрешён. 17А если аль-Масих не был воскрешён, то и вера ваша напрасна и ваши грехи по-прежнему на вас. 18Тогда и те, кто умер с верой в аль-Масиха, погибли. 19Если мы надеемся на аль-Масиха лишь в этой жизни, то мы находимся в более жалком положении, чем все прочие люди.

20Но аль-Масих действительно воскрес из мёртвых! Он – первый плод будущего урожая, тех, кто воскреснет из мёртвых!15:20 Букв.: «Он – первый плод из умерших». Аллах через пророка Мусу повелел исраильтянам приносить Ему в жертву первые снопы (см. Лев. 23:9-14) и лепёшку, испечённую из муки от первого урожая (см. Чис. 15:17-21). Всё первое было своего рода залогом последующего. Таким же образом воскресение Исы служит залогом будущего воскресения всех верующих в Него. См. также сноску на Отк. 1:5. 21И как смерть пришла в этот мир через одного человека, так через одного Человека пришло и воскресение мёртвых. 22Как умирают все, кто связан с Адамом, так будут оживлены все, кто связан с аль-Масихом. 23Но каждый в своём порядке: вначале15:23 Букв.: «первый плод». аль-Масих, а затем, когда Он вернётся, будем воскрешены и мы, принадлежащие Ему. 24И потом наступит конец, когда Он, уничтожив всякое начальство, всякую власть и силу, передаст Царство Аллаху, Небесному Отцу! 25Аль-Масиху предназначено царствовать до тех пор, пока Аллах не повергнет всех врагов к Его ногам15:25 См. Заб. 109:1.. 26Последний враг, который будет уничтожен, – это смерть. 27Ведь Аллах «всё подчинил под ноги Его»15:27 Заб. 8:7.. Когда говорится, что «всё подчинил», то, конечно же, это «всё» не включает в себя Того, Кто и подчинил Ему всё. 28Когда же всё будет Ему подчинено, тогда и Сам Сын будет подчинён Тому, Кто всё подчинил Ему, чтобы Всевышний безраздельно царствовал над всем.

29Что же тогда делают те, кто принимает обряд погружения в воду15:29 Или: «обряд омовения». за мёртвых?15:29 Здесь Паул не поддерживает тех, кто принимал этот обряд за мёртвых, а просто приводит их в пример как один из аргументов, подтверждающих воскресение. Если мёртвых нельзя воскрешать, зачем люди принимают этот обряд за них? 30Зачем и нам ежечасно рисковать своей жизнью? 31Я каждый день стою перед лицом смерти. Это верно, братья, как и то, что я хвалюсь вами перед Исой аль-Масихом, нашим Повелителем! 32Если я только из человеческих побуждений боролся с дикими зверями15:32 Многие толкователи видят здесь метафору: Паул сравнивает с дикими зверями людей, противников пути Аллаха. в Эфесе, то что я этим приобрёл? Если мёртвые не могут быть воскрешены, тогда что же:

«Давайте будем пировать и напиваться,

потому что завтра умрём»?15:32 Ис. 22:13. См. также Ис. 56:12.

33Смотрите, чтобы вам не оказаться обманутыми: «Плохая компания развращает добрые нравы»15:33 Паул здесь приводит цитату из комедии «Таис» древнегреческого поэта Менандра (342–292 гг. до н. э.).. 34Отрезвитесь, как вам и должно, и перестаньте грешить, ведь некоторые из вас даже не знают Аллаха, – я говорю это к вашему стыду.

Земное и небесное тело

35Может, кто-то спросит: «Как это мёртвые могут воскреснуть? Какое у них тогда будет тело?» 36Спрашивать об этом неразумно. Ведь каждому семени для того, чтобы прорасти, надо сначала умереть! 37Когда ты сеешь, ты же сеешь не само растение, а лишь семя, пшеничное или какое-либо другое. 38А Аллах по Своему усмотрению даёт ему тело – каждому семени своё. 39Не все тела одинаковы: у людей не такое тело, как у зверей, у зверей не такое, как у птиц, а у птиц не такое, как у рыб. 40Есть тела небесные и тела земные. У небесных тел своя красота, и у земных тел своя. 41У солнца тоже своё сияние, у луны своё, у звёзд своё. Звёзды, в свою очередь, тоже отличаются по яркости друг от друга.

42Так же будет и при воскресении мёртвых. Предаётся земле тело тленное, а воскресает нетленное. 43Предаётся неприглядное, а воскресает великолепное! Предаётся в слабости, а воскресает в силе, 44предаётся физическое тело, а воскресает – духовное.

Если есть тело физическое, то есть и тело духовное. 45Писание говорит, что первый человек, Адам, стал живым существом, но последний Адам (Иса) – духом животворящим. 46Сначала приходит не духовное, а физическое, и лишь потом – духовное. 47Первый человек был сотворён из праха земного15:47 См. Нач. 2:7., а второй Человек – это Человек с небес. 48Земные люди подобны первому земному человеку, а небесные будут такими же, как Человек, пришедший с небес. 49И как сейчас мы носим образ земного человека, точно так же мы будем похожи на Человека небесного.

50Я говорю вам, братья, что плоть и кровь не могут стать наследниками Царства Аллаха; ничто тленное не может стать наследником нетленного. 51Послушайте, я открою вам тайну: мы не все умрём, но все будем изменены, 52внезапно, во мгновение ока, когда прозвучит последняя труба. По сигналу трубы мёртвые воскреснут нетленными, а мы будем изменены. 53Всё тленное должно превратиться в нетленное, и всё смертное – в бессмертное. 54Когда тленное облечётся в нетленное и смертное – в бессмертное, тогда исполнятся слова: «Смерть поглощена победой!»15:54 Ис. 25:8.

55«О смерть, где твоя победа?

О смерть, где твоё жало?»15:55 Ос. 13:14.

56Жало смерти – грех, а сила греха – Закон. 57Но благодарение Аллаху! Он даёт нам победу через Повелителя Ису аль-Масиха!

58Поэтому, мои любимые братья, стойте твёрдо. Ничто не должно вас поколебать. Всегда отдавайте себя полностью на служение Повелителю и знайте, что ваш труд для Повелителя не напрасен.