1 Johanu 2 – YCB & CARS

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

1 Johanu 2:1-29

12.1: Jh 14.16.Ẹ̀yin ọmọ mi ọ̀wọ́n, mo kọ ìwé nǹkan wọ̀nyí sí yín, kí ẹ̀yin má bà á dẹ́ṣẹ̀. Ṣùgbọ́n bí ẹnikẹ́ni bá sì dẹ́ṣẹ̀, àwa ni alágbàwí lọ́dọ̀ Baba: Jesu Kristi, olódodo nìkan. 22.2: Jh 1.29; 3.14-16; 11.51-52; 1Jh 4.10.Òun sì ní ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ wa, kì í tilẹ̀ ṣe fún tiwa nìkan ṣùgbọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ gbogbo aráyé.

3Àwa mọ̀ pé àwa ti wá mọ̀ ọ́n, bí àwa bá ń pa òfin rẹ̀ mọ́. 42.4: Jh 15.10.Ẹni tí ó bá wí pé, “Èmi mọ̀ ọ́n,” tí kò sì pa òfin rẹ̀ mọ́, èké ni, òtítọ́ kò sì ṣí nínú rẹ̀. 52.5: Jh 14.21,23; 1Jh 5.3.Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá ń pa òfin rẹ̀ mọ́, lára rẹ̀ ni a gbé mú ìfẹ́ Ọlọ́run pé nítòótọ́. Nípa èyí ni àwa mọ̀ pé àwa ń wà nínú rẹ̀. 62.6: Jh 13.15.Ẹnikẹ́ni tí ó bá wí pé òun ń gbé inú rẹ̀, òun náà pẹ̀lú sì yẹ láti máa rìn gẹ́gẹ́ bí Jesu ti rìn.

72.7: Jh 13.34.Ẹ̀yin olùfẹ́ ọ̀wọ́n, kì í ṣe òfin tuntun ni mo ń kọ̀wé rẹ̀ sí yín ṣùgbọ́n òfin àtijọ́, èyí tí ẹ̀yin tí gbọ́ ní àtètèkọ́ṣe. Òfin àtijọ́ ni ọ̀rọ̀ náà tí ẹ̀yin tí gbọ́. 82.8: Jh 8.12.Pẹ̀lúpẹ̀lú, òfin tuntun ni mo ń kọ̀wé rẹ̀ sí yín; èyí tí í ṣe òtítọ́ nínú rẹ̀ àti nínú yin, nítorí òkùnkùn ń kọjá lọ, ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ sì tí ń tàn.

9Ẹni tí ó bá sì wí pé òun ń wà nínú ìmọ́lẹ̀, tí ó sì kórìíra arákùnrin rẹ̀ sì ń bẹ nínú òkùnkùn. 102.10-11: Jh 11.9-10; 1Jh 1.6.Ẹni tí ó ba fẹ́ràn arákùnrin rẹ̀, ó ń gbé inú ìmọ́lẹ̀, kò sì ṣí ohun ìkọ̀sẹ̀ kan nínú rẹ̀. 11Ṣùgbọ́n ẹni tí o bá kórìíra arákùnrin rẹ̀ ń gbé nínú òkùnkùn, ó sì ń rìn nínú òkùnkùn; kò sì mọ ibi tí òun ń lọ, nítorí tí òkùnkùn tí fọ́ ọ lójú.

12Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin ọmọ mi ọ̀wọ́n,

nítorí tí a darí ẹ̀ṣẹ̀ yín jì yín nítorí orúkọ rẹ̀.

132.13: Jh 1.1; 1Jh 1.1.Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin baba,

nítorí tí ẹ̀yin tí mọ ẹni tí ó wà ní àtètèkọ́ṣe,

Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọkùnrin,

nítorí tí ẹ̀yin ti ṣẹ́gun ẹni ibi náà.

14Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin ọmọdé mi ọ̀wọ́n,

nítorí ẹ̀yin ti mọ Baba.

Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin baba,

nítorí ti ẹ̀yin tí mọ ẹni tí o wà ni àtètèkọ́ṣe.

Èmi ń kọ̀wé sí yín, ẹ̀yin ọ̀dọ́mọkùnrin,

nítorí tí ẹ̀yin ni agbára,

tí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sì ń gbé nínú yín,

tí ẹ sì ṣẹ́gun ẹni ibi náà.

Ẹ má ṣe fẹ́ràn ayé

15Ẹ má ṣe fẹ́ràn ayé tàbí ohunkóhun tí ń bẹ nínú ayé. Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ràn ayé, ìfẹ́ tí Baba kò sí nínú rẹ̀. 16Nítorí ohun gbogbo tí ń bẹ nínú ayé: ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ti ara, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ti ojú, àti ìgbéraga ti ohun ti ó ní àti ohun tí ó ṣe: kò wá láti ọ̀dọ̀ Baba bí kò ṣe láti ọwọ́ ayé. 17Ayé sì ń kọjá lọ àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ó ba ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run ni yóò wà títí láéláé.

Ìkìlọ̀ nípa àwọn aṣòdì sí Kristi

182.18: 1Jh 4.3.Ẹ̀yin ọmọ mi ọ̀wọ́n, ìgbà ìkẹyìn ni èyí; bí ẹ̀yin sì tí gbọ́ pé aṣòdì sí Kristi ń bọ̀ wá, àní nísinsin yìí, púpọ̀ aṣòdì sí Kristi ló ń bẹ. Nípa èyí ni àwa fi mọ́ pé ìgbà ìkẹyìn ni èyí. 19Wọ́n ti ọ̀dọ̀ wá jáde, ṣùgbọ́n wọn kì í ṣe ara wa. Nítorí bí wọ́n bá jẹ́ ara wa, wọn ìbá bá wa dúró: ṣùgbọ́n jíjáde lọ wọn fihàn pé gbogbo wọn kì í ṣe ara wa.

20Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ní ìfòróróyàn láti ọ̀dọ̀ Ẹ̀mí Mímọ́ wá, gbogbo yín sì mọ òtítọ́. 21Èmi kò kọ̀wé sí yín nítorí pé ẹ̀yin kò mọ òtítọ́, ṣùgbọ́n nítorí tí ẹ̀yin mọ̀ ọ́n, àti pé kò sí èké nínú òtítọ́. 222.22: 2Jh 7.Ta ni èké? Ẹni tí ó sẹ́ pé Jesu kì í ṣe Kristi. Eléyìí ni Aṣòdì sí Kristi: ẹni tí ó sẹ́ Baba àti Ọmọ. 232.23: 1Jh 4.15; 2Jh 9.Ẹnikẹ́ni tí o ba sẹ́ Ọmọ, kò gba Baba; ṣùgbọ́n ẹni tí ó ba jẹ́wọ́ Ọmọ, ó gba Baba pẹ̀lú.

24Ẹ jẹ́ kí èyí tí ẹ tí gbọ́ ni àtètèkọ́ṣe máa gbé inú yín. Bí èyí tí ẹ̀yin tí gbọ́ ní àtètèkọ́ṣe bá ń gbé inú yín, ẹ̀yin ó sì dúró nínú Ọmọ àti nínú Baba. 25Èyí sì ni ìlérí náà tí ó tí ṣe fún wa, àní ìyè àìnípẹ̀kun.

26Nǹkan wọ̀nyí ni mo kọ̀wé sí yín ní ti àwọn tí wọ́n fẹ́ ẹ mún un yín ṣìnà. 272.27: Jh 14.26.Ṣùgbọ́n ní ti ìfóróróyàn tí ẹ̀yín gba lọ́wọ́ rẹ̀ ṣì ń gbé inú yín, ẹ̀yin kò tún nílò pé kí ẹnìkan kọ yín. Ṣùgbọ́n bí ìfòróróyàn náà ti ń kọ́ yín ní ohun gbogbo tí ó jẹ́ òtítọ́, tí kì í sì í ṣe èké, àní gẹ́gẹ́ bí ó sì ti kọ́ yín, ẹ máa gbé inú rẹ̀.

Àwọn ọmọ Ọlọ́run

282.28: 1Jh 4.17.Àti nísinsin yìí, ẹ̀yin ọmọ mi ọ̀wọ́n, ẹ máa gbé inú rẹ̀, pé nígbà tí òun ó bá farahàn, kí a lè ni ìgboyà níwájú rẹ̀, kí ojú má sì tì wá níwájú rẹ̀ ni ìgbà wíwá rẹ̀.

292.29: 1Jh 3.7-10; 4.7.Bí ẹ̀yin ba mọ̀ pé olódodo ni òun, ẹ mọ̀ pé a bí olúkúlùkù ẹni tí ń ṣe òdodo nípa rẹ̀.

Священное Писание

1 Иохана 2:1-29

1Дети мои, я пишу вам это, чтобы вы не согрешали. Но если кто из вас и согрешит, то у нас есть Праведник Иса Масих, Который свидетельствует перед Небесным Отцом в нашу защиту. 2Он – умилостивление за наши грехи, и не только за наши, но и за грехи всего мира.

Знающий Всевышнего исполняет Его повеления

3Мы можем быть уверены, что знаем Всевышнего, если соблюдаем Его повеления. 4Если кто-то говорит: «Я знаю Его», но не соблюдает Его повелений, тот лжец, и истины в нём нет. 5Но если человек послушен Его слову, тогда любовь Всевышнего действительно достигла в нём своей полноты; это и показывает, что мы пребываем в Нём. 6Кто заявляет, что живёт в единении со Всевышним, тот должен и поступать так, как поступал Иса.

7Дорогие, я не пишу вам какое-то новое повеление, повеление это известно уже давно, оно было у вас с самого начала. Это старое повеление и есть та весть, которую вы слышали. 8И всё-таки, то, что я пишу, – это и новое повеление, истинное в Исе и в вас, потому что мрак рассеивается, и уже светит истинный свет.

9Кто заявляет, что живёт во свете, но ненавидит своего брата, тот ещё во тьме. 10Но кто любит своего брата, тот живёт во свете, и в нём нет уже ничего, что ведёт ко греху. 11Кто ненавидит своего брата, тот находится во тьме и во тьме ходит, не зная, куда идёт, потому что тьма ослепила его.

12Я пишу вам, дети,

потому что ваши грехи уже прощены ради имени Исы.

13Я пишу вам, отцы,

потому что вы познали Того, Кто существует от начала.

Я пишу вам, юноши,

потому что вы победили дьявола.

Я написал вам, дети,

потому что вы познали Небесного Отца.

14Отцы, я написал вам,

потому что вы познали Того, Кто существует от начала.

Я написал вам, юноши,

потому что вы сильны,

в вас пребывает слово Всевышнего,

и вы победили дьявола.

Не любите мира

15Не любите ни этого мира2:15 Мир – здесь этот термин означает не мироздание, а мир людей, погрязший во зле и грехе, противящийся Всевышнему, мир, которым правит сатана, князь демонов., ни того, что в мире. Кто любит мир, в том нет любви к Небесному Отцу2:15 Или: «любви Небесного Отца»., 16потому что всё, что есть в этом мире, – греховные желания плоти, желания глаз и житейская гордость, – не от Небесного Отца, а от мира. 17Мир и мирские желания проходят, но тот, кто исполняет волю Всевышнего, живёт вечно.

Предостережение о врагах Исы Масиха

18Дети, это время – последнее. Вы слышали, что должен прийти враг Масиха2:18 Враг Масиха – вероятно, здесь говорится о противнике Всевышнего, который явится в конце времён и будет стоять во главе большого организованного движения против Масиха (см. 2 Фес. 2; Отк. 13). Эта личность известна также под именем Даджжал., и сейчас появилось много врагов Масиха, из чего мы узнаём, что время – последнее. 19Эти враги Масиха вышли из нашей среды, хоть они никогда к нам не принадлежали. Если бы они действительно принадлежали к нам, то остались бы с нами. Но то, что они от нас вышли, показывает, что они и не принадлежали к нам.

20Вы получили помазание2:20 Помазание – имеется в виду Святой Дух; также в ст. 27. от Святого2:20 Святого – вероятно, это Масих, но возможно – Всевышний., и у всех вас есть знание. 21Я пишу вам не потому, что вы не знаете истины, а наоборот, потому, что вы знаете её и то, что из неё не может произойти никакой лжи. 22Кто такой лжец? Лжец – тот, кто отвергает, что Иса – обещанный Масих. Такой человек – враг Масиха, он отвергает и Небесного Отца, и Сына. 23Тот, кто отвергает Сына, не имеет и Небесного Отца, а кто признаёт Сына, тот имеет и Небесного Отца.

24Храните слышанное вами от начала. Если то, что вы слышали от начала, будет постоянно в вас, то и вы сами будете в единении с Сыном и Небесным Отцом. 25Обещание, которое Сын дал нам, – вечная жизнь.

26Это я пишу вам относительно тех, кто пытается вас обмануть. 27Помазание, которое вы получили от Него, постоянно в вас, и поэтому вам не нужно, чтобы кто-либо учил вас. Его помазание само учит вас всему, оно говорит истину и никогда не лжёт. Поэтому, как оно научило вас, так и оставайтесь в Нём2:27 Или: «в нём»..

Дети Всевышнего

28И теперь, дети, оставайтесь в единении с Масихом, чтобы, когда Он вернётся, мы могли бы стоять перед Ним уверенно и не стыдясь.

29Если вы знаете, что Он праведен, то знаете и то, что каждый, кто живёт праведно, рождён от Всевышнего.