Ọbadiah 1 – YCB & NASV

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ọbadiah 1:1-21

1Ìran ti Ọbadiah.

1-21: Isa 34; 63.1-6; Jr 49.7-22; El 25.12-14; 35; Am 1.11-12; Ml 1.2-5.Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí nípa Edomu.

Àwa ti gbọ́ ohùn kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá:

A sì ti rán ikọ̀ kan sí gbogbo kèfèrí láti sọ pé,

“Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a dìde ogun sí i.”

2“Kíyèsi i, Èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín àwọn kèfèrí;

ìwọ yóò sì di gígàn lọ́pọ̀lọpọ̀,

3Ìgbéraga àyà rẹ ti tàn ọ́ jẹ,

ìwọ tí ń gbé inú pálapàla àpáta,

tí o sì kọ́ ibùgbé rẹ sí ibi gíga,

ìwọ wí nínú ọkàn rẹ pé,

‘ta ni yóò mú mi sọ̀kalẹ̀?’

4Bí ìwọ tilẹ̀ gbé ara rẹ ga bí ẹyẹ idì,

bí ìwọ tilẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ rẹ sí àárín àwọn ìràwọ̀,

láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti sọ̀ ọ kalẹ̀,”

ni Olúwa wí.

5“Bí àwọn olè tọ̀ ọ́ wá,

bí àwọn ọlọ́ṣà ní òru,

Háà! Irú ìparun wo ló dúró dè ọ́:

wọn kò ha jalè tó bí wọ́n ti fẹ́?

Bí àwọn tí ń ká èso àjàrà tọ̀ ọ́ wá,

wọn kò ha ni fi èso àjàrà díẹ̀ sílẹ̀?

6Báwo ni a ṣe ṣe àwárí nǹkan Esau,

tí a sì wá ohun ìní ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ jáde.

7Gbogbo àwọn ẹni ìmùlẹ̀ rẹ

ti mú ọ dé ìpẹ̀kun ilẹ̀ rẹ:

Àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti tàn ọ́ jẹ, wọ́n sì ti borí rẹ;

àwọn tó jẹ oúnjẹ rẹ dẹ pàkúté dè ọ́,

ṣùgbọ́n ìwọ kò ní ní òye rẹ̀.”

8Olúwa wí pé, “Ní ọjọ́ náà,

Èmi kì yóò ha pa àwọn ọlọ́gbọ́n Edomu run,

àti àwọn amòye run kúrò ní òkè Esau?

9A ó ṣe ẹ̀rù ba àwọn jagunjagun rẹ, Ìwọ Temani,

gbogbo àwọn tó wà ní orí òkè Esau

ní a ó gé kúrò nínú ìpànìyàn náà.

10Nítorí ìwà ipá sí Jakọbu arákùnrin rẹ,

ìtìjú yóò bò ọ,

a ó sì pa ọ run títí láé.

11Ní ọjọ́ tí ìwọ dúró ní apá kan,

ní ọjọ́ tí àlejò kó ogún rẹ lọ,

tí àwọn àjèjì sì wọ ibodè rẹ

tí wọ́n sì sẹ́ kèké lórí Jerusalẹmu,

ìwọ náà wà bí ọ̀kan nínú wọn.

12Ìwọ kì bá tí fi ojú kéré arákùnrin rẹ,

ní àkókò ìbànújẹ́ rẹ̀

ìwọ kì bá tí yọ̀ lórí àwọn ọmọ Juda,

ní ọjọ́ ìparun wọn

ìwọ kì bá tí gbéraga púpọ̀

ní ọjọ́ wàhálà wọn.

13Ìwọ kì bá tí wọ inú ibodè àwọn ènìyàn mi lọ,

ní ọjọ́ àjálù wọn.

Ìwọ kì bá tí fojú kó wọn mọ́lẹ̀

nínú ìdààmú wọn, ní ọjọ́ àjálù wọn.

Ìwọ kì bá tí jí ẹrù wọn kó,

ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.

14Ìwọ kì bá tí dúró ní ìkóríta ọ̀nà

láti ké àwọn tirẹ̀ tó ti sálà kúrò.

Ìwọ kì bá tí fa àwọn tó ṣẹ́kù nínú

wọn lélẹ̀ ní ọjọ́ wàhálà wọn.

15“Nítorí ọjọ́ Olúwa súnmọ́ etílé

lórí gbogbo àwọn kèfèrí.

Bí ìwọ ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni a ó ṣe sí ìwọ náà;

ẹ̀san rẹ yóò sì yípadà sí orí ara rẹ.

16Gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀ ṣe mu lórí òkè mímọ́ mi

bẹ́ẹ̀ ni gbogbo kèfèrí yóò máa mu títí

Wọn yóò mu wọn yóò sì mu àmutẹ́rùn

wọn yóò sì wà bí ẹni pé wọn kò wà rí

17Ṣùgbọ́n ìgbàlà yóò wà lórí òkè Sioni

Wọn yóò sì jẹ́ mímọ́

àti ilé Jakọbu yóò sì ní ìní wọn

18Ilé Jakọbu yóò sì jẹ́ iná

àti ilé Josẹfu ọwọ́ iná

ilé Esau yóò jẹ àgékù koríko

wọn yóò fi iná sí i,

wọn yóò jo run.

Kì yóò sí ẹni tí yóò kù ní ilé Esau.”

Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.

19Àwọn ará gúúsù yóò ni òkè Esau,

àwọn ará ẹsẹ̀ òkè yóò ni

ilẹ̀ àwọn ará Filistini ní ìní.

Wọn yóò sì ni oko Efraimu àti Samaria;

Benjamini yóò ní Gileadi ní ìní.

20Àwọn ìgbèkùn Israẹli tí ó wà ní Kenaani

yóò ni ilẹ̀ títí dé Sarefati;

àwọn ìgbèkùn láti Jerusalẹmu tí ó wà ní Sefaredi

yóò ni àwọn ìlú gúúsù ní ìní

21Àwọn tó ń gba ni là yóò sì gòkè Sioni wá

láti jẹ ọba lé orí àwọn òkè Esau.

Ìjọba náà yóò sì jẹ́ ti Olúwa.

New Amharic Standard Version

አብድዩ 1:1-21

የአብድዩ ራእይ

1ጌታ እግዚአብሔር ስለ ኤዶም እንዲህ ይላል፤

ከእግዚአብሔር ዘንድ መልእክት ሰምተናል፤

መልእክተኛውም ወደ አሕዛብ ተልኮ እንዲህ

ብሏል፤

“ተነሡ፤ እርሷን ለመውጋት እንውጣ።”

2“እነሆ፤ በአሕዛብ መካከል ታናሽ አደርግሃለሁ፤

እጅግ የተናቅህ ትሆናለህ።

3አንተ በሰንጣቃ1፥3 ወይም በሴላ ዐለት ውስጥ

የምትኖር፣

መኖሪያህንም በከፍታ ስፍራ ያደረግህ፣

ለራስህም፣

‘ማን ወደ ምድር ሊያወርደኝ ይችላል?’ የምትል፣

የልብህ ትዕቢት አታልሎሃል።

4እንደ ንስር መጥቀህ ወደ ላይ ብትወጣ፣

ጐጆህንም በከዋክብት መካከል ብታደርግ፣

ከዚያ አወርድሃለሁ”

ይላል እግዚአብሔር

5“ሌቦች ወደ አንተ ቢመጡ፣

ዘራፊዎችም በሌሊት ቢገቡ፣

የሚሰርቁት የሚፈልጉትን ያህል ብቻ አይደለምን?

ወይን ለቃሚዎች ወደ አንተ ቢመጡ፣

ጥቂት ቃርሚያ አይተዉምን?

አንተ ግን ምንኛ ጥፋት ይጠብቅሃል!

6ዔሳው ግን እንዴት ተዘረፈ?

የሸሸገውስ ሀብት ምንኛ ተመዘበረ!

7ወዳጆችህ ሁሉ ወደ ድንበር ይገፉሃል፤

ጓደኞችህ ያታልሉሃል፤ ያሸንፉህማል፤

እንጀራህን የበሉ ወጥመድ ይዘረጉብሃል፤1፥7 የዚህ ሐረግ የዕብራይስጡ ትርጓሜ በርግጠኝነት አይታወቅም።

አንተ ግን አታውቀውም።

8“በዚያ ቀን ጥበበኛ ሰዎችን ከኤዶም፣

አስተዋዮችንም ከዔሳው ተራሮች አልደመስስምን?”

ይላል እግዚአብሔር

9“ቴማን ሆይ፤ ተዋጊዎችህ ይደነግጣሉ፤

በዔሳውም ተራሮች ያለ ሁሉ፣

ተገድሎ ይጠፋል።

10በወንድምህ በያዕቆብ ላይ ስላደረግኸው ግፍ፣

በዕፍረት ትሸፈናለህ፤

ለዘላለምም ትጠፋለህ።

11እንግዶች ሀብቱን ዘርፈው ሲሄዱ፣

ባዕዳንም በበሮቹ ሲገቡ፣

በኢየሩሳሌምም ላይ ዕጣ ሲጣጣሉ፣

በዚያ ቀን ገለልተኛ ሆነህ ተመለከትህ፣

አንተም ከእነርሱ እንደ አንዱ ሆንህ።

12ክፉ ቀን በገጠመው ጊዜ፤

በወንድምህ ሥቃይ መደሰት አልነበረብህም፤

በጥፋታቸው ቀን፣ የይሁዳ ሕዝብ ሲያዝኑ

ሐሤት ማድረግ አልነበረብህም፤

በጭንቀታቸውም ቀን፣

በትዕቢት ልትናገር አይገባህም ነበር።

13በጥፋታቸው ቀን፣

በሕዝቤ በር መግባት የለብህም ነበር፤

በጥፋታቸው ቀን፣

በጭንቀታቸው መደሰት አልነበረብህም፤

በጥፋታቸው ቀን፣

ሀብታቸውን መዝረፍ አይገባህም ነበር።

14ስደተኞቻቸውን ለመግደል፣

በመንታ መንገድ መጠባበቅ አይገባህም ነበር፣

በጭንቀታቸው ቀን፣

የተረፉትን አሳልፈህ መስጠት አልነበረብህም።

15“በአሕዛብ ሁሉ ላይ፣

የእግዚአብሔር ቀን ደርሷል፤

አንተ እንዳደረግኸው፣ በአንተም ላይ ይደረጋል፤

ክፉ ሥራህም በራስህ ላይ ይመለሳል።

16እናንተ በቅዱሱ ተራራዬ እንደ ጠጣችሁ፣

አሕዛብ ሁሉ ዘወትር ይጠጣሉ፤

ይጠጣሉ፤ አብዝተውም ይጠጣሉ፤

ከዚህም በፊት እንዳልሆኑት ይሆናሉ።

17ነገር ግን በጽዮን ተራራ ነጻ መውጣት ይሆናል፤

የያዕቆብ ቤትም እርሷ የተቀደሰች ትሆናለች፤

ርስታቸውን ይወርሳሉ።

18የያዕቆብ ቤት እሳት፣

የዮሴፍም ቤት ነበልባል ይሆናል፤

የዔሳው ቤት ገለባ ይሆናል፤

ያቃጥሉታል፤ ይበሉትማል፤

ከዔሳው ቤት የሚተርፍ አይኖርም።”

እግዚአብሔር ተናግሯል።

19የኔጌብ ሰዎች፣

የዔሳውን ተራራ ይይዛሉ፤

ከተራራው ግርጌ ያሉ ሰዎችም፣

የፍልስጥኤማውያንን ምድር ይወርሳሉ፤

የኤፍሬምንና የሰማርያንም ዕርሻ ይይዛሉ፤

ብንያምም ገለዓድን ይወርሳል።

20በከነዓን ያለው ይህ የእስራኤል ስደተኞች ወገን፣

እስከ ሰራጵታ ያለውን ምድር ይወርሳል፤

በሰፋራድም ያሉ የኢየሩሳሌም ስደተኞች፣

የኔጌብን ከተሞች ይወርሳሉ።

21የዔሳውን ተራሮች ለመግዛት፣

ነጻ አውጪዎች ወደ ጽዮን ተራራ ይወጣሉ፤

መንግሥቱም የእግዚአብሔር ይሆናል።