1Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa;
wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò,
ilé wa ti di ti àjèjì.
3Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba,
àwọn ìyá wa ti di opó.
4A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu;
igi wa di títà fún wa.
5Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa;
àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria
láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́,
àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa,
kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa
nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò,
ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni,
àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn;
kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta;
àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú;
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn
15Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa;
ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16Adé ti ṣí kúrò ní orí wa
ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa,
nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro
lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé;
ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà?
Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà;
mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì
22Àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá
tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
1-2ای خداوند، به ياد آور كه چه بر سر ما آمده است. ببين چگونه رسوا شدهايم. سرزمين ما به دست دشمنان افتاده است و خانههای ما را بيگانگان تصرف كردهاند. 3ما يتيميم؛ پدرانمان كشته و مادرانمان بيوه شدهاند. 4آب خود را میخريم و مینوشيم و هيزم ما به ما فروخته میشود. 5در زير فشار و آزار دشمنان به ستوه آمدهايم و آسايش نداريم. 6خود را تسليم مصر و آشور كردهايم تا نان به دست آوريم و از گرسنگی نميريم.
7پدرانمان گناه كردند و مردند، و اينک جور گناهانشان را ما میكشيم.
8نوكران ديروزمان، اربابان امروزمان شدهاند و كسی نيست كه ما را از دست آنها نجات دهد. 9برای يک لقمه نان، در بيابانها جانمان را به خطر میاندازيم. 10از شدت گرسنگی در تب میسوزيم و پوست بدنمان مثل تنور داغ شده است. 11زنان و دختران ما را در يهودا بیعصمت كردهاند. 12رهبرانمان را به دار كشيدهاند و ريشسفيدانمان را بیحرمت نمودهاند. 13جوانان ما را مانند غلامان، در آسياب به كارهای سخت وا میدارند و كودكان ما زير بارهای سنگين هيزم، افتان و خيزان راه میروند.
14پيران ما ديگر در كنار دروازههای شهر نمینشينند؛ جوانان ما ديگر نمیرقصند و آواز نمیخوانند. 15شادی دلهای ما رفته و رقص ما به ماتم تبديل شده است. 16وای بر ما كه گناه كردهايم و شكوه و جلال خود را از دست دادهايم. 17دلهايمان بیتاب و چشمانمان تار شدهاند، 18زيرا خانهٔ خدا ويران گشته و پناهگاه شغالها شده است.
19ای خداوند، تو تا ابد باقی هستی و تخت سلطنت تو بیزوال است. 20مدت مديدی است كه تو ما را ترک كردهای و ديگر ما را به ياد نمیآوری. 21-22ای خداوند، آيا تو ما را به کلی طرد كردهای و تا ابد بر ما غضبناک خواهی بود؟ اگر چنين نيست، پس ما را به سوی خود بازگردان و شكوه دوران گذشتهٔ ما را به ما باز ده.