1Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan,
nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn!
Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
tí ó wà ní ipò opó,
Ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú
ni ó padà di ẹrú.
2Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò
pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀
kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún.
Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀
wọ́n ti di alátakò rẹ̀.
3Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú,
Juda lọ sí àjò
Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi.
Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́
ibi tí kò ti le sá àsálà.
4Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀,
nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn.
Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro,
àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn,
àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú,
òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.
5Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀,
nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀,
Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́
nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú,
ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.
6Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé
kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni.
Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín
tí kò rí ewé tútù jẹ;
nínú àárẹ̀ wọ́n sáré
níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.
7Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni
Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀
tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.
Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá,
kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó
wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.
8Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀
ó sì ti di aláìmọ́.
Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀,
nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀;
ó kérora fúnrarẹ̀,
ó sì lọ kúrò.
9Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,
bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,
Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;
olùtùnú kò sì ṣí fún un.
“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,
nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”
10Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé
gbogbo ìní rẹ;
o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè
tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—
àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀
láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.
11Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora
bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;
wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ
láti mú wọn wà láààyè.
“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,
nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”
12“Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín?
Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá,
Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà
tí a fi fún mi, ti
Olúwa mú wá fún mi
ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.
13“Ó rán iná láti òkè
sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi.
Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi,
ó sì yí mi padà.
Ó ti pa mí lára
mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.
14“Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà;
ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀.
Wọ́n ti yí ọrùn mi ká
Olúwa sì ti dín agbára mi kù.
Ó sì ti fi mí lé
àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.
15“Olúwa kọ
àwọn akọni mi sílẹ̀,
ó rán àwọn ológun lòdì sí mi
kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run.
Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́
àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.
16“Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún
tí omijé sì ń dà lójú mi,
Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi,
kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà.
Àwọn ọmọ mi di aláìní
nítorí ọ̀tá ti borí.”
17Sioni na ọwọ́ jáde,
ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un.
Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu
pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un
Jerusalẹmu ti di
ohun aláìmọ́ láàrín wọn.
18“Olóòtítọ́ ni Olúwa,
ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn;
ẹ wò mí wò ìyà mi.
Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi
ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.
19“Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi
ṣùgbọ́n wọ́n dà mí.
Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi
ṣègbé sínú ìlú
nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ
tí yóò mú wọn wà láààyè.
20“Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira!
Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi,
ìdààmú dé bá ọkàn mi
nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi.
Ní gbangba ni idà ń parun;
ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.
21“Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi,
ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi.
Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi;
wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe.
Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde,
kí wọ́n le dàbí tèmi.
22“Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ;
jẹ wọ́n ní yà
bí o ṣe jẹ mí ní yà
nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Ìrora mi pọ̀
ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”
Ierusalimul pustiit
11 Acest capitol este în acrostih (fiecare verset începe cu o literă a alfabetului ebraic, în ordinea literelor).Cum stă singură cetatea
care odinioară era plină de oameni!
Cum a ajuns asemenea văduvei,
ea, care era mare între neamuri!
Ea, care era prințesa ținuturilor,
a devenit o sclavă.
2Plânge amarnic în noapte
și lacrimile‑i curg pe obraz.
Dintre toți iubiții ei,
nu mai există niciunul care s‑o aline.
Toți prietenii au trădat‑o,
devenindu‑i dușmani.
3După multă suferință și muncă grea,
Iuda s‑a dus în captivitate.
Locuiește printre neamuri
și nu găsește un loc de odihnă.
Toți prigonitorii lui l‑au ajuns
chiar în toiul strâmtorării lui.
4Drumurile Sionului bocesc,
căci nimeni nu mai vine la sărbători.
Toate porțile lui sunt distruse,
iar preoții săi suspină.
Fecioarele lui sunt mâhnite
și el însuși este plin de amărăciune.
5Vrăjmașii lui au devenit stăpâni
și dușmanii lui au parte de bine,
căci Domnul l‑a făcut să sufere
din cauza mulțimii fărădelegilor sale.
Copiii lui au mers în exil,
captivi înaintea vrăjmașului.
6S‑a dus de la fiica Sionului6 Ierusalimul; [peste tot în carte].
toată măreția ei!
Prinții săi au ajuns ca niște cerbi
care nu găsesc pășune,
care fug, dar fără putere,
dinaintea urmăritorului.
7În zilele necazului și ale rătăcirii lui,
Ierusalimul își aduce aminte
de toate bogățiile
pe care le‑a avut în zilele de odinioară.
Când poporul lui a căzut în mâna vrăjmașului,
nimeni nu i‑a sărit în ajutor!
Vrăjmașii l‑au privit și au râs
pe seama prăbușirii lui.
8Cetatea Ierusalimului a păcătuit mult
și de aceea a ajuns murdară8-9 Se referă la necurăția, din punct de vedere ritualic, a unei femei în timpul menstruației..
Toți aceia care o cinsteau, acum o disprețuiesc,
fiindcă i‑au văzut goliciunea8 Eufemism ebraic cu sensul de a avea relații sexuale..
Ea însăși suspină
și își întoarce fața.
9Necurăția era pe rochia ei;
nu s‑a gândit la sfârșitul său.
Căderea ei a fost de neînțeles;
n‑a avut niciun mângâietor.
„Privește‑mi, Doamne, durerea,
căci dușmanul a triumfat!“
10Vrăjmașul a întins mâna
peste toate bogățiile ei.
Mai mult, ea a văzut neamurile
intrând în Sfântul ei Lăcaș,
cărora Tu le porunciseși
să nu intre în adunarea Ta.
11Tot poporul suspină,
căutând pâine.
Ei și‑au dat bogățiile pentru mâncare,
ca să‑și păstreze viața.
Privește, Doamne, și ia aminte
la cât sunt de disprețuită!
12Nu înseamnă nimic pentru voi,
cei care treceți pe lângă mine?
Priviți și vedeți
dacă există vreo durere asemenea durerii mele,
cu care Domnul m‑a făcut să sufăr
în ziua aprigei Lui mânii!
13Din înălțimi a trimis un foc
care mi‑a pătruns în oase.
A întins un laț sub picioarele mele
și m‑a răsturnat.
M‑a pustiit
și m‑a ostenit toată ziua.
14Fărădelegile mele au fost prinse14 Sensul termenului ebraic este nesigur. într‑un jug
și împletite de mâna Sa.
Ele apasă asupra gâtului meu,
frângându‑mi puterea.
Stăpânul m‑a dat în mâinile dușmanilor,
fără ca eu să mă pot împotrivi.
15Stăpânul i‑a lepădat
pe toți vitejii din mijlocul meu.
El a proclamat o vreme împotriva mea,
ca să‑mi zdrobească tinerii.
Stăpânul a călcat‑o ca în teasc
pe fiica fecioară a lui Iuda15 Ierusalimul; [peste tot în carte]..
16De aceea îmi plâng ochii;
din ochi îmi coboară lacrimi.
Căci Mângâietorul S‑a îndepărtat de mine,
El, Cel Ce îmi înviora sufletul.
Fiii mei sunt îngroziți,
căci dușmanul a învins.
17Sionul își întinde mâinile rugător,
dar nu este nimeni să‑l mângâie.
Domnul a poruncit pentru Iacov
ca vecinii lui să‑i fie vrăjmași,
iar Ierusalimul a ajuns
ca o necurăție printre ei.
18Domnul este drept,
căci m‑am răzvrătit împotriva Poruncii Lui.
Ascultați‑mă, vă rog, toate popoarele!
Priviți la durerea mea!
Fecioarele și tinerii mei
au mers în captivitate.
19Mi‑am chemat iubiții,
însă ei m‑au trădat.
Preoții și bătrânii mei
și‑au dat suflarea în cetate,
în timp ce căutau mâncare
ca să‑și păstreze viața.
20Privește, Doamne, cât sunt de nenorocit!
Măruntaiele‑mi fierb;
inima mi se zvârcolește înăuntrul meu,
căci am fost foarte răzvrătit!
Afară, sabia m‑a lăsat fără copii,
iar în casă, ea este precum moartea.
21Oamenii m‑au auzit suspinând,
dar nimeni nu m‑a mângâiat.
Toți dușmanii mei au aflat de nenorocirea mea
și s‑au bucurat de ce ai făcut.
Adu ziua pe care ai vestit‑o!
Să fie și ei ca mine!
22Să vină toată răutatea lor înaintea Ta;
și poartă‑Te cu ei
la fel cum Te‑ai purtat cu mine
din cauza tuturor fărădelegilor mele.
Căci suspinele mele sunt multe,
iar inima‑mi este sleită!