Òwe 31 – YCB & OL

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 31:1-31

1Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba,

ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ.

2“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!

Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.

3Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,

okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.

4“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli

kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì

kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle

5Kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí

kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n

6Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé

wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora;

7Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn

kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.

8“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnrawọn

fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun

9Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè

jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”

10Ta ni ó le rí aya oníwà rere?

Ó níye lórí ju iyùn lọ

11Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀

kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.

12Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀

Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.

14Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;

ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn

15Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;

ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀

àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.

16Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;

nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀

17Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára

apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́

18Ó rí i pé òwò òun pé

fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru

19Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú

20O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.

21Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀

nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.

22Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;

ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀

23A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú

níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú

24Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n

ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò

25Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ

ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.

26A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n

ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀

27Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀

kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́

28Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún

ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un

29“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá

ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”

30Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán

nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn

31Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i

kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.

O Livro

Provérbios 31:1-31

Provérbios do rei Lemuel

1Palavras do rei Lemuel, que a sua mãe lhe transmitiu e ensinou:

2Ó meu filho, filho das minhas entranhas,

tu, a quem eu consagrei a Deus,

3não gastes as tuas energias com mulheres,

não entregues o teu destino

às que até são capazes de levar reis à ruína.

4Não convém que os reis, ó Lemuel,

se deixem vencer pelo vinho e outras bebidas alcoólicas.

5Porque se se derem à bebida,

virão a esquecer os seus deveres

e não saberão fazer justiça aos oprimidos.

6As bebidas alcoólicas podem ajudar doentes,

que estão para morrer, ou os que vivem deprimidos.

7Bebendo, não se lembram mais da sua pobreza e miséria.

8Não feches a boca, se puderes contribuir para ajudar os que não sabem se defender,

e por todos os desamparados.

9Não te cales, pois deves intervir sempre a favor dos necessitados,

exigindo que se lhes faça justiça.

A esposa de carácter nobre

10Não é fácil encontrar uma mulher virtuosa;

o seu valor ultrapassa em muito o das mais finas joias.

11O seu marido tem confiança nela

e os recursos materiais nunca lhe faltarão.

12Nunca se tornará um empecilho para o seu esposo;

pelo contrário, sempre o ajudará a vida toda.

13Escolhe lã e linho,

e vai costurando e trabalhando, com gosto, com as suas mãos.

14Tal como um navio mercante,

ela traz de longe os alimentos necessários à sua casa.

15Levanta-se cedo, escuro ainda,

para preparar as refeições para a família

e distribuir o trabalho pelas suas empregadas.

16Se é preciso comprar um terreno,

vai pessoalmente examiná-lo com cuidado;

ela própria cultiva a sua vinha com o produto do trabalho.

17Concentra as energias

e procura ganhar forças para o trabalho que lhe compete.

18É cuidadosa em tudo o que compra;

durante a noite há sempre uma luz acesa na casa.

19Pega, de boa vontade, nas suas costuras, nas suas malhas.

20Confeciona roupa para os necessitados,

a quem as oferece com generosidade.

21Também não tem receio do inverno, para a família,

porque tem roupa quente suficiente para todos.

22Prepara cobertores, lençóis, toalhas e cortinas com tecidos escolhidos;

a roupa com que se veste é fina e de boa qualidade.

23O seu marido é conhecido pela sua dignidade

e pela sua participação honesta na vida cívica da localidade.

24Ela própria também faz roupas de linho fino

que vende aos negociantes.

25É uma mulher com energia e dignidade

e não tem medo da velhice.

26Quando fala é com graça e sabedoria;

há bondade em tudo quanto diz.

27Zela pelo governo da casa;

para ela não há preguiça.

28Os seus filhos bendizem-na;

e o marido louva-a, dizendo:

29“Há muita mulher virtuosa neste mundo,

mas tu és superior a todas!”

30Os encantos femininos podem enganar;

a beleza não dura sempre.

Mas uma mulher que ama e teme o Senhor,

essa merece todos os elogios.

31Louvem-na por tudo o que faz

e os seus atos virtuosos serão reconhecidos publicamente.