Òwe 31 – YCB & CCB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 31:1-31

1Àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ ti Lemueli ọba,

ọ̀rọ̀ ẹ̀kọ́ tí ìyá rẹ̀ kọ́ ọ.

2“Gbọ́ ìwọ ọmọ mi, gbọ́ ìwọ ọmọ inú mi!

Gbọ́ ìwọ ọmọ ẹ̀jẹ́ mi.

3Má ṣe lo agbára rẹ lórí obìnrin,

okun rẹ lórí àwọn tí ó pa àwọn ọba run.

4“Kì í ṣe fún àwọn ọba, ìwọ Lemueli

kì í ṣe fún ọba láti mu ọtí wáìnì

kì í ṣe fún alákòóso láti máa wá ọtí líle

5Kí wọn má ba à mu ọtí yó kí wọn sì gbàgbé ohun tí òfin wí

kí wọn sì fi ẹ̀tọ́ àwọn tí ara ń ni dù wọ́n

6Fi ọtí líle fún àwọn tí ń ṣègbé

wáìnì fún àwọn tí ó wà nínú ìrora;

7Jẹ́ kí wọn mu ọtí kí wọn sì gbàgbé òsì wọn

kí wọn má sì rántí òsì wọn mọ́.

8“Sọ̀rọ̀ lórúkọ àwọn tí kò le sọ̀rọ̀ fúnrawọn

fún ẹ̀tọ́ àwọn ẹni tí ń parun

9Sọ̀rọ̀ kí o sì ṣe ìdájọ́ àìṣègbè

jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà àti aláìní.”

10Ta ni ó le rí aya oníwà rere?

Ó níye lórí ju iyùn lọ

11Ọkọ rẹ̀ ní ìgbẹ́kẹ̀lé púpọ̀ nínú rẹ̀

kò sì ṣí ìwà rere tí kò pé lọ́wọ́ rẹ̀.

12Ire ní ó ń ṣe fún un, kì í ṣe ibi

ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.

13Ó sa aṣọ irun àgùntàn olówùú àti ọ̀gbọ̀

Ó sì ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìyárí.

14Ó dàbí ọkọ̀ ojú omi tí àwọn oníṣòwò;

ó ń gbé oúnjẹ rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn

15Ó dìde nígbà tí òkùnkùn sì kùn;

ó ṣe oúnjẹ fún ìdílé rẹ̀

àti ìpín oúnjẹ fún àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀.

16Ó kíyèsi oko kan, ó sì rà á;

nínú ohun tí ó ń wọlé fún un ó gbin ọgbà àjàrà rẹ̀

17Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rẹ̀ tagbára tagbára

apá rẹ̀ le koko fún iṣẹ́

18Ó rí i pé òwò òun pé

fìtílà rẹ̀ kì í sì í kú ní òru

19Ní ọwọ́ rẹ̀, ó di kẹ̀kẹ́ òwú mú

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ di ìrànwú mú

20O la ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn tálákà

ó sì na ọwọ́ rẹ̀ sí àwọn aláìní.

21Nígbà tí òjò-dídì rọ̀, kò bẹ̀rù nítorí ìdílé rẹ̀

nítorí gbogbo wọn ni ó wọ aṣọ tí ó nípọn.

22Ó ṣe aṣọ títẹ́ fún ibùsùn rẹ̀;

ẹ̀wù dáradára àti elése àlùkò ni aṣọ rẹ̀

23A bọ̀wọ̀ fún ọkọ rẹ̀ ní ẹnu ibodè ìlú

níbi tí ó ń jókòó láàrín àwọn àgbàgbà ìlú

24Ó ń ṣe àwọn aṣọ dáradára ó sì ń tà wọ́n

ó sì ń kó ọjà fún àwọn oníṣòwò

25Agbára àti ọlá ni ó wò ọ́ láṣọ

ó le fi ọjọ́ iwájú rẹ́rìn-ín.

26A sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọgbọ́n

ìkọ́ni òtítọ́ sì ń bẹ létè e rẹ̀

27Ó ń bojútó gbogbo ètò ilé rẹ̀

kì í sì í jẹ oúnjẹ ìmẹ́lẹ́

28Àwọn ọmọ rẹ̀ dìde wọ́n sì pè é ní alábùkún

ọkọ rẹ̀ pẹ̀lú ń gbóríyìn fún un

29“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ obìnrin ní ń ṣe nǹkan ọlọ́lá

ṣùgbọ́n ìwọ ju gbogbo wọn lọ”

30Ojú dáradára a máa tan ni, ẹwà sì jẹ́ asán

nítorí obìnrin tí ó bẹ̀rù Olúwa yẹ kí ó gba oríyìn

31Sì fún un ní èrè tí ó tọ́ sí i

kí o sì jẹ́ kí iṣẹ́ rẹ̀ fún un ní ìyìn ní ẹnu ibodè ìlú.

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

箴言 31:1-31

利慕伊勒王的箴言

1以下是利慕伊勒王的箴言,

是他母亲给他的教诲:

2我儿,我亲生的骨肉,

我许愿得来的孩子啊,

我该怎样教导你呢?

3不要在女人身上耗废精力,

不要迷恋那些能毁灭王的人。

4利慕伊勒啊,

君王不可喝酒,

不可喝酒,

首领不宜喝烈酒,

5免得喝酒后忘记律例,

不为困苦人伸张正义。

6把烈酒给灭亡的人,

把淡酒给忧伤的人,

7让他们喝了忘掉贫穷,

不再记得自己的痛苦。

8要为不能自辩者说话,

为一切不幸的人申冤。

9你要发言,秉公审判,

为贫穷困苦者主持公道。

贤德的妻子

10谁能找到贤德之妻?

她的价值远胜过珠宝。

11她丈夫信赖她,

什么也不缺乏。

12她一生对丈夫有益无损。

13她寻找羊毛和细麻,

愉快地亲手做衣。

14她好像商船,

从远方运来粮食。

15天未亮她就起床,

为全家预备食物,

分派女仆做家事。

16她选中田地便买下来,

亲手赚钱栽种葡萄园。

17她精力充沛,

双臂有力。

18她深谙经营之道,

她的灯彻夜不熄。

19她手拿卷线杆,

手握纺线锤。

20她乐于周济穷人,

伸手帮助困苦者。

21她不因下雪而为家人担心,

因为全家都穿着朱红暖衣。

22她为自己缝制绣花毯,

用细麻和紫布做衣服。

23她丈夫在城门口与当地长老同坐,

受人尊重。

24她缝制细麻衣裳出售,

又制作腰带卖给商人。

25她充满力量和尊荣,

她以笑颜迎接未来。

26她说的话带着智慧,

她的训言充满慈爱。

27她料理一切家务,

从不偷懒吃闲饭。

28她的儿女肃立,

为她祝福,

她的丈夫也称赞她,

29说:“世上贤德的女子很多,

唯有你无与伦比。”

30艳丽是虚假的,

美貌是短暂的,

唯有敬畏耶和华的女子配得称赞。

31愿她享受自己的劳动成果,

愿她的事迹使她在城门口受称赞。