Òwe 1 – YCB & NTLR

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 1:1-33

Èròǹgbà àti kókó-ọ̀rọ̀

1Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.

2Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́,

Láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.

3Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo,

àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;

4láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀,

ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.

5Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀,

sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.

6Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe,

àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.

7Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀,

ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.

Ọ̀rọ̀ ìyànjú láti ṣàfẹ́rí ọgbọ́n

8Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ,

má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.

9Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ

àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.

10Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́,

má ṣe gbà fún wọn.

11Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa;

jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan,

jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;

12Jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú,

àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò;

13A ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí

a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa;

14Da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa,

a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà”

15Ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ,

má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn;

16Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀,

wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.

17Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀,

ní ojú ẹyẹ!

18Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn.

Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà

19Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́;

yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.

Ìkìlọ̀ láti má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀

201.20,21: Òw 8.1-3.Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó

ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;

21Láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde

Ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:

22“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó?

Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó?

Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?

23Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni,

Ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín

kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.

24Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè

kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,

25Níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi,

tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,

26Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín;

èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.

27Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle,

Nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà,

nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.

28“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn;

wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.

29Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀

tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.

30Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi

tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,

31Wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn

wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún

32Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n

ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;

33Ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu

yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

Nouă Traducere În Limba Română

Proverbe 1:1-33

Prolog: scopul și tema cărții

1Proverbele lui Solomon, fiul lui David, regele lui Israel,

2pentru a cunoaște înțelepciunea și îndrumarea,

pentru a înțelege cuvintele cunoașterii,

3pentru a primi îndrumare în ce privește înțelepciunea,

dreptatea, judecata și nepărtinirea,

4pentru a da prudență celui neștiutor4 Sau: celui nesăbuit. Termenul ebraic se referă la o anumită naivitate sau lipsă de experiență.,

iar tânărului – cunoștință și discernământ.

5Să asculte cel înțelept și el își va spori învățătura,

iar cel priceput să primească îndrumări,

6pentru a înțelege un proverb sau o pildă,

cuvintele înțelepților și ghicitorile lor.

7Teama de Domnul este începutul cunoașterii,

dar nebunii7 Termenul ebraic tradus cu nebun denotă, aici și aproape peste tot în VT, o persoană care alege să rămână deficientă din punct de vedere moral. disprețuiesc înțelepciunea și îndrumarea.

Îndemnuri pentru căutarea înțelepciunii

Avertizare împotriva ispitirii

8Ascultă, fiule, îndrumarea tatălui tău

și nu părăsi învățătura mamei tale.

9Căci ele vor fi o cunună plăcută pe capul tău

și un colier în jurul gâtului tău.

10Fiule, dacă niște păcătoși vor să te ademenească

nu accepta.

11Dacă vor spune: „Vino cu noi!

Să stăm la pândă ca să vărsăm sânge,

să întindem fără motiv curse celui nevinovat!

12Să‑i înghițim de vii ca Locuința Morților12 Ebr.: Șeol [peste tot în carte].

și întregi ca pe cei ce se coboară în groapă!

13Vom găsi tot felul de lucruri scumpe

și ne vom umple casele cu pradă.

14Pune partea ta cu noi14 Lit.: Aruncă sorțul tău între noi.

și vom avea un sac împreună!“

15Fiule, să nu mergi pe același drum cu ei,

abate‑ți piciorul de pe cărarea lor,

16căci picioarele lor aleargă spre rău

și se grăbesc să verse sânge.

17În zadar se aruncă lațul

înaintea ochilor tuturor păsărilor!

18Aceștia își pândesc însăși sângele lor,

își întind curse înseși sufletelor lor.

19Astfel sunt căile tuturor celor ce obțin câștig nedrept;

el va lua viața stăpânilor lui.

Chemarea înțelepciunii și consecințele respingerii ei

20Înțelepciunea strigă pe stradă,

își înalță glasul în piețe,

21cheamă de la capătul locurilor aglomerate,

își rostește cuvintele în fața porților cetății:

22„Naivilor, până când veți iubi naivitatea?

Până când le va plăcea batjocoritorilor batjocura

și vor urî nesăbuiții cunoașterea?

23Dacă v‑ați întoarce la mustrarea mea,

aș revărsa duhul meu peste voi

și v‑aș dezvălui cuvintele mele.

24Dar pentru că mă respingeți când vă chem,

iar când îmi întind mâna, nimeni nu ia seama,

25pentru că ignorați toate sfaturile mele

și nu acceptați mustrarea mea,

26de aceea și eu voi râde de nenorocirea voastră,

îmi voi bate joc de voi când groaza vă va ajunge,

27când groaza voastră va veni ca o distrugere,

și nenorocirea voastră va veni ca o vijelie,

când necazul și suferința vor veni peste voi.

28Atunci mă vor chema, dar nu voi răspunde;

mă vor căuta, dar nu mă vor găsi.

29Pentru că au urât cunoștința

și n‑au ales teama de Domnul,

30pentru că n‑au acceptat sfatul meu

și au disprețuit toate mustrările mele,

31de aceea se vor hrăni cu rodul căii lor

și se vor sătura cu roada planurilor lor.

32Căci necredincioșia îi ucide pe cei naivi

și mulțumirea de sine îi distruge pe cei nesăbuiți;

33dar cel ce mă ascultă va locui în siguranță,

va trăi liniștit, fără să‑l cuprindă groaza de vreun rău.“