Ìṣe àwọn Aposteli 2 – YCB & NUB

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ìṣe àwọn Aposteli 2:1-47

Ẹ̀mí Mímọ́ wá ní Pentikosti

1Nígbà tí ọjọ́ Pentikosti sì dé, gbogbo wọn fi ọkàn kan wà ní ibìkan. 2Lójijì ìró sì ti ọ̀run wá, gẹ́gẹ́ bí ìró ẹ̀fúùfù líle, ó sì kún gbogbo ilé níbi tí wọ́n gbé jókòó. 3Ẹ̀là ahọ́n bí i iná sì yọ sí wọn, ó pín, ó sì bà lé olúkúlùkù wọn. 4Gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í fi èdè mìíràn sọ̀rọ̀, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ti fi fún wọn ni ohùn.

5Àwọn Júù olùfọkànsìn láti orílẹ̀-èdè gbogbo lábẹ́ ọ̀run sì ń gbé Jerusalẹmu. 6Nígbà tí wọn sì gbọ́ ìró yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ pẹ̀lú ìyàlẹ́nu, nítorí tí olúkúlùkù gbọ́ tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè rẹ̀. 7Ẹnu sì yà wọ́n, wọn ń wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ ara Galili kọ́ ni gbogbo àwọn tí ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí jẹ́? 8Èéha sì tí ṣe ti olúkúlùkù wa fi ń gbọ́ bí wọ́n tí ń fi èdè sọ̀rọ̀? 9Àwọn ará Partia, àti Media, àti Elamu; àti àwọn tí ń gbé Mesopotamia, Judea, àti Kappadokia, Pọntu àti Asia. 10Frigia, àti pamfilia, Ejibiti, àti agbègbè Libia níhà Kirene; àti àwọn àtìpó Romu, àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe Júù 11(àti àwọn Júù àti àwọn tí a ti ipa ẹ̀sìn sọ di Júù); àwọn ará Krete àti Arabia; àwa gbọ́ tí wọ́n sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu ńlá Ọlọ́run ni èdè wa.” 12Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì wárìrì. Wọn wí fún ara wọn pé, “Kí ni èyí túmọ̀ sí?”

13Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, wọn sí wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kún fún wáìnì tuntun”.

Peteru wàásù sí ọ̀pọ̀ ènìyàn

14Nígbà náà ni Peteru dìde dúró pẹ̀lú àwọn mọ́kànlá yòókù, ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin Júù ènìyàn mi àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé Jerusalẹmu, ẹ jẹ́ kí èyí kí ó yé yin; kí ẹ sì fetísí ọ̀rọ̀ mi. 15Àwọn wọ̀nyí kò mu ọtí yó, bí ẹ̀yin tí rò ó; wákàtí kẹta ọjọ́ sá à ni èyí. 16Bẹ́ẹ̀ kọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ ti a ti sọ láti ẹnu wòlíì Joeli wá pé:

172.17-21: Jl 2.28-32.“Ọlọ́run wí pé, ‘Ní ìkẹyìn ọjọ́,

Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí jáde sára ènìyàn gbogbo,

àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀

àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò sì máa ríran,

àwọn arúgbó yín yóò sì máa lá àlá;

18Àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi ọkùnrin àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi obìnrin,

ni Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mi jáde ni ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì:

wọn yóò sì máa sọtẹ́lẹ̀;

19Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn lójú ọ̀run,

àti àwọn ààmì nísàlẹ̀ ilẹ̀;

ẹ̀jẹ̀ àti iná àti rírú èéfín;

20A ó sọ oòrùn di òkùnkùn,

àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,

kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ológo Olúwa tó dé.

21Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó bá ké pe

orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.’

22“Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Jesu tí Nasareti, ọkùnrin tí a mọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípa iṣẹ́ agbára àti tí ìyanu, àti ààmì ti Ọlọ́run ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe láàrín yín, bí ẹ̀yin tìkára yín ti mọ̀ pẹ̀lú. 23Ẹni tí a ti fi lé yín lọ́wọ́ nípa ìpinnu ìmọ̀ àti ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run; àti ẹ̀yin pẹ̀lú, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú kàn mọ́ àgbélébùú, tí a sì pa á. 24Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, gbà á kúrò nínú ìrora ikú: nítorí tí kò ṣe é ṣe fún ikú láti dìímú. 252.25-28: Sm 16.8-11.Dafidi tí wí nípa tirẹ̀ pé:

“ ‘Mo rí Olúwa nígbà gbogbo níwájú mí,

nítorí tí ó ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún mi,

a kì ó ṣí mi ní ipò.

26Nítorí náà inú mi dùn, ahọ́n mi sì yọ̀:

pẹ̀lúpẹ̀lú ara mi yóò sì sinmi ní ìrètí.

27Nítorí tí ìwọ kí yóò fi ọkàn mi sílẹ̀ ni isà òkú,

bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́.

28Ìwọ mú mi mọ ọ̀nà ìyè,

ìwọ yóò mú mi kún fún ayọ̀ ni iwájú rẹ.’

29“Ará, èmí lè sọ fún yín pẹ̀lú ìgboyà pé Dafidi baba ńlá kú, a sì sin ín, ibojì rẹ̀ sì ń bẹ lọ́dọ̀ wa títí di òní yìí. 302.30: Sm 132.11.Ṣùgbọ́n ó jẹ́ wòlíì, àti bí ó mọ́ pé, Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún òun nínú ìbúra pé nínú irú-ọmọ inú rẹ̀, òun yóò mú ọ̀kan jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. 312.31: Sm 16.10.Ní rí rí èyí tẹ́lẹ̀, ó sọ ti àjíǹde Kristi, pé a kò fi ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́. 32Jesu náà yìí ni Ọlọ́run ti jí dìde sí ìyè, àwa pẹ̀lú sì jẹ́rìí sí èyí. 33A ti gbéga sí ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, ó ti gba ìlérí Ẹ̀mí Mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba, ó tu èyí tí ẹ̀yin rí àti gbọ́ nísinsin yìí síta. 342.34-35: Sm 110.1.Nítorí Dafidi kò gòkè lọ sí ọ̀run ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wí pé,

“ ‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé:

“Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi

35títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ

dí àpótí ìtìsẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ.” ’

36“Ǹjẹ́ kí gbogbo ilé Israẹli mọ̀ dájúdájú pé: Ọlọ́run ti fi Jesu náà, ti ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, ṣe Olúwa àti Kristi.”

37Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, ọkàn wọn gbọgbẹ́, wọn sì wí fún Peteru àti àwọn aposteli yòókù pé, “Ará, kín ni àwa yóò ṣe?”

38Peteru sì wí fún wọn pé, “Ẹ ronúpìwàdà, kí a sì bamitiisi olúkúlùkù yín ní orúkọ Jesu Kristi fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yín. Ẹ̀yin yóò sì gba ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ 392.39: Isa 57.19; Jl 2.32.Nítorí fún yín ni ìlérí náà, àti fún àwọn ọmọ yín, àti fún gbogbo àwọn tí ó jìnnà réré, àní gbogbo àwọn tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò pè.”

40Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ mìíràn ni ó fi ń kìlọ̀ tí ó sì ń fi ń rọ̀ wọ́n wí pé, “Ẹ gba ara yín là lọ́wọ́ ìran àrékérekè yìí.” 41Nítorí náà àwọn tí ó fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ a bamitiisi wọn, lọ́jọ́ náà a sì kà ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkàn kún wọn.

Ìsọ̀kan àwọn ará tí o gbàgbọ́

42Wọ́n sì dúró ṣinṣin nínú ẹ̀kọ́ àwọn aposteli, àti ní ìdàpọ̀, ní bíbu àkàrà àti nínú àdúrà. 43Ẹ̀rù sí ba gbogbo ọkàn; iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ ààmì púpọ̀ ni a ti ọwọ́ àwọn aposteli ṣe. 442.44-45: Ap 4.32-35.Gbogbo àwọn tí ó sì gbàgbọ́ wà ni ibìkan, wọn ní ohun gbogbo sọ́kàn; 45Wọn si ń ta ohun ìní àti ẹrù wọn, wọn sì ń pín wọn fún olúkúlùkù, gẹ́gẹ́ bí ẹnikẹ́ni tí í ṣe aláìní sí. 46Wọ́n fi ọkàn kan dúró lójoojúmọ́ nínú tẹmpili. Wọ́n ń bu àkàrà ní ilé wọn, wọn ń fi inú dídùn àti ọkàn òtítọ́ jẹ oúnjẹ wọn. 47Wọ́n yín Ọlọ́run, wọn sì rí ojúrere lọ́dọ̀ ènìyàn gbogbo, Olúwa sí ń yàn kún wọn lójoojúmọ́, àwọn tí à ń gbàlà.

Swedish Contemporary Bible

Apostlagärningarna 2:1-47

1När pingstdagen2:1 Pingsten firades sju veckor efter påsk och var från början en skördefest. kom, var de troende alla samlade. 2Då hördes plötsligt ett dån från himlen som en väldig storm och det fyllde hela huset där de satt. 3Sedan såg de något som såg ut som eldslågor och de delade på sig och stannade över var och en av dem. 4Och alla blev fyllda av den heliga Anden och började tala andra språk som Anden gav dem.

5Många hängivna judar från olika länder var i Jerusalem 6och när de hörde dånet, samlades en stor mängd människor. Förvånade fick de då höra sina egna språk talas. 7De var helt förbluffade och sa: ”Hur kan det komma sig? De här människorna är ju alla från Galileen 8och ändå hör vi dem tala på våra egna språk. 9Vi är parther, meder och elamiter. Vi kommer från Mesopotamien, Judeen, Kappadokien, Pontos, Asien, 10Frygien, Pamfylien,2:10 Kappadokien, Pontos, provinsen Asien, Frygien och Pamfylien var alla romerska provinser i nuvarande Turkiet. Egypten och från trakten kring Kyrene i Libyen. Vi är besökare från Rom, 11både judar och proselyter, vi är kretensare och araber. Och ändå hör vi dessa människor tala om Guds mäktiga gärningar på våra egna språk!” 12De var förvirrade och visste inte vad de skulle tro och de frågade varandra: ”Vad kan det här betyda?” 13Men andra sa hånfullt: ”De är väl bara fulla av sött vin!”

Petrus tal på pingstdagen

14Då steg Petrus fram tillsammans med de elva andra och började tala högt och tydligt till folket: ”Hör på mig ni judar och alla som bor i Jerusalem! Detta ska ni veta! 15De här männen är inte fulla som ni menar. Klockan är ju bara nio på morgonen. 16Nej, detta är vad som sagts genom profeten Joel:

17’Det ska ske i den sista tiden, säger Gud,

att jag ska utgjuta min Ande över alla människor.

Era söner och döttrar ska profetera,

era unga män ska se syner,

och era gamla män ska ha drömmar.

18Också över mina tjänare och tjänarinnor

ska jag på den tiden utgjuta min Ande,

och de ska profetera.

19Jag ska låta tecken visa sig uppe på himlen

och nere på jorden: blod och eld och rökmoln.

20Solen ska vändas i mörker

och månen i blod innan Herrens stora och underbara dag kommer.

21Men var och en som åkallar Herrens namn

ska bli räddad.’2:21 Se Joel 2:28-32. I citatet här finns små skillnader med texten i Joel.

22Lyssna på vad jag säger ni israeliter! Gud bekräftade Jesus från Nasarets uppdrag genom kraftgärningar, under och tecken. Det vet ni själva. 23Han utlämnades efter den plan som Gud hade bestämt och gjort upp och ni lät laglösa2:23 Att vara laglös är detsamma som att vara icke-jude. Här syftar det på de romerska myndigheterna. människor spika fast honom och döda honom. 24Men Gud befriade honom från dödens fasor och lät honom uppstå, eftersom det var omöjligt för döden att hålla honom i sitt grepp.

25David sa ju om honom:

’Jag har alltid Herren inför mig,

eftersom han står vid min sida vacklar jag inte.

26Därför är mitt hjärta fyllt av glädje och jag ropar ut mitt jubel,

också min kropp vilar i det hoppet,

27att du inte ska lämna mig kvar i dödsriket,

eller låta din Helige förmultna.

28Du visar mig vägen till livet,

du fyller mig med glädje inför dig.’2:28 Se Ps 16:8-11.

29Mina syskon! Jag kan tryggt säga till er att vår stamfar David dog och blev begravd och att hans grav fortfarande finns här ibland oss. 30Men han var en profet och visste att Gud med ed hade lovat att en av hans ättlingar skulle få sitta på hans tron. 31Han förutsade därför Messias uppståndelse: ’Han ska inte lämnas kvar i dödsriket och hans kropp ska inte förmultna.’ 32Gud har låtit Jesus uppstå och vi alla kan vittna om det.

33Gud har upphöjt Jesus och satt honom på sin högra sida.2:33 Att sitta på Guds högra sida innebär att dela hans makt och regera tillsammans med honom. Han har av Fadern fått ta emot den utlovade heliga Anden, som han nu har låtit komma över oss. Det är det ni har sett och hört här idag. 34David steg ju heller aldrig upp till himlen. Men han säger:

’Herren sa till min Herre:

”Sätt dig på min högra sida,

35tills jag har lagt dina fiender

som en pall under dina fötter.” ’2:35 Se Ps 110:1.

36Hela Israels folk måste alltså klart förstå att Gud har gjort Jesus till Herre och Messias, denna Jesus som ni korsfäste.”

37När folket hörde det här gick det rakt in i deras hjärtan och de frågade Petrus och de andra apostlarna: ”Bröder, vad ska vi göra?”

38Petrus svarade: ”Omvänd er och låt er alla döpas i Jesus Kristus namn, så ska ni få förlåtelse för era synder. Ni ska då också få den heliga Anden som gåva. 39För detta löfte gäller er och era barn och alla dem långt borta som Herren vår Gud kallar.”

40Sedan fortsatte Petrus att vittna och vädja till dem med många andra ord och han uppmanade dem: ”Se till att ni blir räddade undan detta vilsegångna släkte!” 41De som trodde på vad Petrus sa lät sedan döpa sig. Och den dagen ökade antalet troende med omkring 3 000 personer.

De troende samlas

42De troende höll sig till apostlarnas undervisning och de hade gemenskap med varandra och bröt bröd2:42 De firade minnet av Jesus död, nattvard; se Luk 22:19. tillsammans och bad. 43Människorna hade en djup respekt för dem och apostlarna utförde många under och tecken. 44Alla de troende var ständigt tillsammans och hade allting gemensamt. 45De sålde allt vad de ägde och delade med sig till varandra, allt efter vars och ens behov. 46Varje dag möttes de i templet, och i hemmen samlades de för att bryta bröd och äta tillsammans i glädje och uppriktig hjärtlighet, 47de prisade Gud och var omtyckta av hela folket. Varje dag lät Herren deras grupp växa, genom att fler och fler blev räddade.