Ìṣe àwọn Aposteli 2 – YCB & GKY

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Ìṣe àwọn Aposteli 2:1-47

Ẹ̀mí Mímọ́ wá ní Pentikosti

1Nígbà tí ọjọ́ Pentikosti sì dé, gbogbo wọn fi ọkàn kan wà ní ibìkan. 2Lójijì ìró sì ti ọ̀run wá, gẹ́gẹ́ bí ìró ẹ̀fúùfù líle, ó sì kún gbogbo ilé níbi tí wọ́n gbé jókòó. 3Ẹ̀là ahọ́n bí i iná sì yọ sí wọn, ó pín, ó sì bà lé olúkúlùkù wọn. 4Gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í fi èdè mìíràn sọ̀rọ̀, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ti fi fún wọn ni ohùn.

5Àwọn Júù olùfọkànsìn láti orílẹ̀-èdè gbogbo lábẹ́ ọ̀run sì ń gbé Jerusalẹmu. 6Nígbà tí wọn sì gbọ́ ìró yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ pẹ̀lú ìyàlẹ́nu, nítorí tí olúkúlùkù gbọ́ tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè rẹ̀. 7Ẹnu sì yà wọ́n, wọn ń wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ ara Galili kọ́ ni gbogbo àwọn tí ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí jẹ́? 8Èéha sì tí ṣe ti olúkúlùkù wa fi ń gbọ́ bí wọ́n tí ń fi èdè sọ̀rọ̀? 9Àwọn ará Partia, àti Media, àti Elamu; àti àwọn tí ń gbé Mesopotamia, Judea, àti Kappadokia, Pọntu àti Asia. 10Frigia, àti pamfilia, Ejibiti, àti agbègbè Libia níhà Kirene; àti àwọn àtìpó Romu, àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe Júù 11(àti àwọn Júù àti àwọn tí a ti ipa ẹ̀sìn sọ di Júù); àwọn ará Krete àti Arabia; àwa gbọ́ tí wọ́n sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu ńlá Ọlọ́run ni èdè wa.” 12Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì wárìrì. Wọn wí fún ara wọn pé, “Kí ni èyí túmọ̀ sí?”

13Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, wọn sí wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kún fún wáìnì tuntun”.

Peteru wàásù sí ọ̀pọ̀ ènìyàn

14Nígbà náà ni Peteru dìde dúró pẹ̀lú àwọn mọ́kànlá yòókù, ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin Júù ènìyàn mi àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé Jerusalẹmu, ẹ jẹ́ kí èyí kí ó yé yin; kí ẹ sì fetísí ọ̀rọ̀ mi. 15Àwọn wọ̀nyí kò mu ọtí yó, bí ẹ̀yin tí rò ó; wákàtí kẹta ọjọ́ sá à ni èyí. 16Bẹ́ẹ̀ kọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ ti a ti sọ láti ẹnu wòlíì Joeli wá pé:

172.17-21: Jl 2.28-32.“Ọlọ́run wí pé, ‘Ní ìkẹyìn ọjọ́,

Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí jáde sára ènìyàn gbogbo,

àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀

àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò sì máa ríran,

àwọn arúgbó yín yóò sì máa lá àlá;

18Àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi ọkùnrin àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi obìnrin,

ni Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mi jáde ni ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì:

wọn yóò sì máa sọtẹ́lẹ̀;

19Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn lójú ọ̀run,

àti àwọn ààmì nísàlẹ̀ ilẹ̀;

ẹ̀jẹ̀ àti iná àti rírú èéfín;

20A ó sọ oòrùn di òkùnkùn,

àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀,

kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ológo Olúwa tó dé.

21Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó bá ké pe

orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.’

22“Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Jesu tí Nasareti, ọkùnrin tí a mọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípa iṣẹ́ agbára àti tí ìyanu, àti ààmì ti Ọlọ́run ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe láàrín yín, bí ẹ̀yin tìkára yín ti mọ̀ pẹ̀lú. 23Ẹni tí a ti fi lé yín lọ́wọ́ nípa ìpinnu ìmọ̀ àti ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run; àti ẹ̀yin pẹ̀lú, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú kàn mọ́ àgbélébùú, tí a sì pa á. 24Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, gbà á kúrò nínú ìrora ikú: nítorí tí kò ṣe é ṣe fún ikú láti dìímú. 252.25-28: Sm 16.8-11.Dafidi tí wí nípa tirẹ̀ pé:

“ ‘Mo rí Olúwa nígbà gbogbo níwájú mí,

nítorí tí ó ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún mi,

a kì ó ṣí mi ní ipò.

26Nítorí náà inú mi dùn, ahọ́n mi sì yọ̀:

pẹ̀lúpẹ̀lú ara mi yóò sì sinmi ní ìrètí.

27Nítorí tí ìwọ kí yóò fi ọkàn mi sílẹ̀ ni isà òkú,

bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́.

28Ìwọ mú mi mọ ọ̀nà ìyè,

ìwọ yóò mú mi kún fún ayọ̀ ni iwájú rẹ.’

29“Ará, èmí lè sọ fún yín pẹ̀lú ìgboyà pé Dafidi baba ńlá kú, a sì sin ín, ibojì rẹ̀ sì ń bẹ lọ́dọ̀ wa títí di òní yìí. 302.30: Sm 132.11.Ṣùgbọ́n ó jẹ́ wòlíì, àti bí ó mọ́ pé, Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún òun nínú ìbúra pé nínú irú-ọmọ inú rẹ̀, òun yóò mú ọ̀kan jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀. 312.31: Sm 16.10.Ní rí rí èyí tẹ́lẹ̀, ó sọ ti àjíǹde Kristi, pé a kò fi ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́. 32Jesu náà yìí ni Ọlọ́run ti jí dìde sí ìyè, àwa pẹ̀lú sì jẹ́rìí sí èyí. 33A ti gbéga sí ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, ó ti gba ìlérí Ẹ̀mí Mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba, ó tu èyí tí ẹ̀yin rí àti gbọ́ nísinsin yìí síta. 342.34-35: Sm 110.1.Nítorí Dafidi kò gòkè lọ sí ọ̀run ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wí pé,

“ ‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé:

“Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi

35títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ

dí àpótí ìtìsẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ.” ’

36“Ǹjẹ́ kí gbogbo ilé Israẹli mọ̀ dájúdájú pé: Ọlọ́run ti fi Jesu náà, ti ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, ṣe Olúwa àti Kristi.”

37Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, ọkàn wọn gbọgbẹ́, wọn sì wí fún Peteru àti àwọn aposteli yòókù pé, “Ará, kín ni àwa yóò ṣe?”

38Peteru sì wí fún wọn pé, “Ẹ ronúpìwàdà, kí a sì bamitiisi olúkúlùkù yín ní orúkọ Jesu Kristi fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yín. Ẹ̀yin yóò sì gba ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ 392.39: Isa 57.19; Jl 2.32.Nítorí fún yín ni ìlérí náà, àti fún àwọn ọmọ yín, àti fún gbogbo àwọn tí ó jìnnà réré, àní gbogbo àwọn tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò pè.”

40Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ mìíràn ni ó fi ń kìlọ̀ tí ó sì ń fi ń rọ̀ wọ́n wí pé, “Ẹ gba ara yín là lọ́wọ́ ìran àrékérekè yìí.” 41Nítorí náà àwọn tí ó fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ a bamitiisi wọn, lọ́jọ́ náà a sì kà ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkàn kún wọn.

Ìsọ̀kan àwọn ará tí o gbàgbọ́

42Wọ́n sì dúró ṣinṣin nínú ẹ̀kọ́ àwọn aposteli, àti ní ìdàpọ̀, ní bíbu àkàrà àti nínú àdúrà. 43Ẹ̀rù sí ba gbogbo ọkàn; iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ ààmì púpọ̀ ni a ti ọwọ́ àwọn aposteli ṣe. 442.44-45: Ap 4.32-35.Gbogbo àwọn tí ó sì gbàgbọ́ wà ni ibìkan, wọn ní ohun gbogbo sọ́kàn; 45Wọn si ń ta ohun ìní àti ẹrù wọn, wọn sì ń pín wọn fún olúkúlùkù, gẹ́gẹ́ bí ẹnikẹ́ni tí í ṣe aláìní sí. 46Wọ́n fi ọkàn kan dúró lójoojúmọ́ nínú tẹmpili. Wọ́n ń bu àkàrà ní ilé wọn, wọn ń fi inú dídùn àti ọkàn òtítọ́ jẹ oúnjẹ wọn. 47Wọ́n yín Ọlọ́run, wọn sì rí ojúrere lọ́dọ̀ ènìyàn gbogbo, Olúwa sí ń yàn kún wọn lójoojúmọ́, àwọn tí à ń gbàlà.

Holy Bible in Gĩkũyũ

Atũmwo 2:1-47

Roho Mũtheru Gũũka Hĩndĩ ya Bendegothito

12:1 Alaw 23:15, 16; Atũm 1:14Hĩndĩ ĩrĩa mũthenya wa Bendegothito2:1 Bendegothito nĩ kuuga “mĩrongo ĩtano” (Alaw 23:16) tondũ gĩathĩ kĩu gĩokaga mũthenya wa mĩrongo ĩtano kuuma kiumia kĩa Bathaka. wakinyire-rĩ, acio othe magĩkorwo maarĩ handũ hamwe. 22:2 Atũm 4:31Na o rĩmwe mũgambo ta wa rũhuho rũnene rũkũhurutana na hinya ũgĩũka kuuma igũrũ, ũkĩiyũra nyũmba yothe ĩrĩa maaikarĩte. 3Makĩona kĩndũ gĩatariĩ ta nĩnĩmbĩ cia mwaki iria ciagayũkanĩte igĩikara igũrũ rĩa mũndũ o mũndũ. 42:4 Luk 1:15; Mar 16:17Othe makĩiyũrio Roho Mũtheru na makĩambĩrĩria kwaria na thiomi ingĩ o ta ũrĩa Roho aamahotithirie.

52:5 Luk 2:25Na rĩrĩ, kũu Jerusalemu nĩ gwaikaraga Ayahudi etigĩri Ngai kuuma ndũrĩrĩ-inĩ ciothe cia thĩ. 6Rĩrĩa maiguire mũgambo ũcio, gĩkundi kĩa andũ gĩgĩcookanĩrĩra kĩgegete, tondũ o mũndũ aamaiguaga makĩaria na rũthiomi rwake kĩũmbe. 72:7 Atũm 1:11Nao makĩgega mũno, makĩũrania atĩrĩ, “Githĩ andũ aya othe maraaria ti andũ a Galili? 8Nĩ kĩĩ kĩratũma mũndũ o mũndũ witũ amaigue makĩaria na rũthiomi rwa kũrĩa aaciarĩirwo? 92:9 1Pet 1:1; Atũm 16:6Andũ a Parithi, na a Media, na a Elamu; o na andũ arĩa matũũraga Mesopotamia, na Judea, na Kapadokia, na Ponto, na Asia, 102:10 Atũm 16:6; Math 27:32na Firigia, na Pamufilia, na Misiri, na mĩena ya Libia ĩrĩa ĩrĩ gũkuhĩ na Kurene, na ageni a kuuma Roma, 11(Ayahudi hamwe na andũ arĩa meegarũrĩte magatuĩka Ayahudi); na andũ a Kirete, na a Arabia, tũramaigua makĩaria na thiomi ciitũ ũhoro wa magegania ma Ngai!” 12Mamakĩte na makagega makĩũrania atĩrĩ, “Ũũ nĩ kuuga atĩa?”

13Amwe ao, o na kũrĩ ũguo, nĩmamathirĩkirie, makiuga atĩrĩ, “Aya nĩkũrĩĩo marĩĩtwo nĩ ndibei.”

Petero Kwarĩria Gĩkundi kĩa Andũ

14Hĩndĩ ĩyo Petero akĩrũgama hamwe na arĩa ikũmi na ũmwe, akĩanĩrĩra na akĩarĩria gĩkundi kĩu kĩa andũ akĩmeera atĩrĩ, “Inyuĩ andũ aitũ Ayahudi o na inyuĩ inyuothe mũtũũraga Jerusalemu, rekei ndĩmũtaarĩrie ũhoro ũyũ; thikĩrĩriai wega ũrĩa nguuga. 152:15 1Athe 5:7Andũ aya ti arĩĩu, ta ũrĩa mũreciiria. Rĩu nĩ thaa ithatũ tu cia rũciinĩ! 16Aca gũtitariĩ ta ũguo, ũhoro ũyũ nĩguo warĩtio nĩ mũnabii Joeli, akiuga atĩrĩ:

17“ ‘Ngai ekuuga atĩrĩ, matukũ-inĩ ma kũrigĩrĩria

nĩngaitĩrĩria andũ othe Roho wakwa.

Ariũ na aarĩ anyu nĩmakarathaga mohoro,

Aanake anyu nĩmakonaga cioneki,

nao athuuri anyu marootage irooto.

182:18 Atũm 21:9-12O na ningĩ nĩngaitĩrĩria ndungata ciakwa

cia arũme na cia andũ-a-nja Roho wakwa matukũ-inĩ macio,

nacio nĩikarathaga mohoro.

19Nĩngonania morirũ kũu igũrũ matu-inĩ,

na nyonanie ciama gũkũ thĩ,

cia thakame, na cia mwaki, na cia ndogo ĩkwambata.

202:20 Math 24:29Riũa nĩrĩkagarũrwo rĩtuĩke nduma,

naguo mweri ũtuĩke ta thakame,

mbere ya mũthenya ũcio mũnene wa Mwathani ũrĩa ũrĩ riiri gũkinya.

212:21 Kĩam 3:18; Arom 10:13Na nĩgũgakinya atĩrĩ, atĩ mũndũ wothe ũgaakaĩra

rĩĩtwa rĩa Mwathani nĩakahonokio.’

222:22 Joh 4:48; Joh 3:2“Inyuĩ andũ aya a Isiraeli, thikĩrĩriai ũhoro ũyũ: Jesũ wa Nazarethi aarĩ mũndũ waheanĩtwo nĩ Ngai kũrĩ inyuĩ na ũndũ wa ciama, na morirũ, na cionereria, iria Ngai aaringire gatagatĩ-inĩ kanyu agereire harĩ we, o ta ũrĩa inyuĩ ene mũũĩ. 232:23 Atũm 3:18Mũndũ ũyũ aaneanirwo moko-inĩ manyu, kũringana na ũrĩa Ngai aatuĩte na ũrĩa aamenyete o mbere; na inyuĩ, mũteithĩrĩirio nĩ andũ arĩa aaganu, mũkĩmũũraga na njĩra ya kũmwambithia mũtharaba-inĩ. 242:24 Aef 1:20; Akol 2:12; Ahib 13:20No Ngai akĩmũriũkia kuuma kũrĩ arĩa akuũ, akĩmuohora ruo-inĩ rwa gĩkuũ, tondũ gũtingĩahotekire atũũre anyiitĩtwo nĩkĩo. 25Tondũ Daudi oigire atĩrĩ ũhoro wake:

“ ‘Nĩndonaga Mwathani arĩ mbere yakwa hĩndĩ ciothe.

Tondũ arĩ guoko-inĩ gwakwa kwa ũrĩo-rĩ,

ndingĩenyenyeka.

26Nĩ ũndũ ũcio ngoro yakwa nĩnjanjamũku, naruo rũrĩmĩ rwakwa rũgakena;

o naguo mwĩrĩ wakwa nĩũgũtũũra ũrĩ na mwĩhoko,

272:27 Atũm 13:35tondũ ndũkandiganĩria mbĩrĩra-inĩ,

o na kana ũreke ũrĩa waku Mũtheru abuthe.

282:28 Thab 16:8-11Nĩũũmenyithĩtie njĩra cia muoyo;

nĩũkanjiyũria gĩkeno ndĩ harĩa ũrĩ.’

292:29 Atũm 13:36; 2Athe 2:10; Neh 2:16“Ariũ na aarĩ a Ithe witũ, no ndĩmwĩre ndĩ na ũũmĩrĩru atĩ ithe witũ Daudi nĩakuire na agĩthikwo, na mbĩrĩra yake ĩrĩ o gũkũ nginya ũmũthĩ ũyũ. 30Nowe aarĩ mũnabii na nĩamenyete atĩ Ngai nĩamwĩrire na mwĩhĩtwa atĩ nĩagaikarĩria ũmwe wa rũciaro rwake gĩtĩ gĩake kĩa ũnene. 312:31 Thab 16:10Nĩ ũndũ nĩamenyete ũhoro ũcio mbere, nĩaririe ũhoro wa kũriũka gwa Kristũ, atĩ ndaatiganĩirio mbĩrĩra-inĩ, o na kana mwĩrĩ wake ũkĩbutha. 322:32 Atũm 2:24; Luk 24:48Ngai nĩariũkĩtie Jesũ ũcio, na ithuĩ ithuothe tũrĩ aira a ũhoro ũcio. 332:33 Atũm 10:45Kuona atĩ nĩatũũgĩrĩtio guoko-inĩ kwa ũrĩo kwa Ngai, na nĩamũkĩrire kĩĩranĩro kĩa Roho Mũtheru kuuma kũrĩ Ithe, nake nĩatũitĩrĩirie Roho ta ũrĩa mũrona rĩu na mũkaigua. 34Nĩgũkorwo Daudi ndaambatire agĩthiĩ igũrũ, no nĩoigire atĩrĩ,

“ ‘Mwathani nĩeerire Mwathani wakwa atĩrĩ:

“Ikara guoko-inĩ gwakwa kwa ũrĩo,

352:35 Thab 110:1o nginya rĩrĩa ngaatua thũ ciaku

gaturwa ka makinya maku.” ’

362:36 Math 28:18; Luk 2:11“Nĩ ũndũ ũcio andũ othe a Isiraeli nĩmamenye atĩrĩ: Ngai nĩ atuĩte Jesũ, o ũcio mwambire, Mwathani na Kristũ.”

372:37 Luk 3:10, 12, 14; Atũm 16:30Rĩrĩa andũ maiguire ũhoro ũcio, ũkĩmatheeca ngoro, makĩũria Petero na atũmwo acio angĩ atĩrĩ, “Ariũ a Baba, twagĩrĩirwo nĩ gwĩka atĩa?”

382:38 Jer 36:30; Luk 24:47; Atũm 3:19Nake Petero akĩmacookeria atĩrĩ, “Mwĩrirei na mũbatithio mũndũ o mũndũ thĩinĩ wa rĩĩtwa rĩa Jesũ Kristũ, nĩguo mũrekerwo mehia manyu. Na inyuĩ nĩ mũkwamũkĩra kĩheo kĩa Roho Mũtheru. 392:39 Isa 40:2; Aef 2:13Kĩĩranĩro gĩkĩ nĩ kĩanyu na ciana cianyu, na andũ arĩa othe marĩ kũraya, na andũ arĩa othe Mwathani Ngai witũ ageeta moke harĩ we.”

402:40 Gũcook 32:5; Afil 2:15Akĩmataara na ciugo ingĩ nyingĩ, akĩmakaanagia; na akĩmathaitha, akĩmeera atĩrĩ, “Mwĩhonokiei kuuma kũrĩ rũciaro rũrũ ruogomu.” 41Andũ arĩa meetĩkĩrire ndũmĩrĩri yake makĩbatithio, na mũthenya ũcio makĩongerereka andũ ta ngiri ithatũ.

Ngwatanĩro ya Andũ arĩa Metĩkĩtie

422:42 Math 28:20; Atũm 1:14Nao nĩmerutĩire kũgwatĩria ũrutani wa atũmwo, na ngwatanĩro-inĩ, na ũhoro-inĩ wa kwenyũrana mũgate, na kũhooya. 43Andũ othe makĩiyũrwo nĩ guoya, nao atũmwo magĩĩka morirũ maingĩ, na makĩringa ciama. 442:44 Atũm 4:32Andũ arĩa othe meetĩkĩtie maarĩ hamwe, na nĩmagwatanagĩra indo ciothe. 45Makĩendia ithaka ciao na indo ciao, makaheaga mũndũ o wothe kũringana na bata wake. 462:46 Luk 24:53; Math 14:19O mũthenya nĩmagomanaga hekarũ-inĩ. Nĩmenyũraga mũgate marĩ mĩciĩ-inĩ yao, na makarĩĩanĩra marĩ na gĩkeno, na marĩ na ngoro theru, 47makagoocaga Ngai, na magetĩkĩrĩka kũrĩ andũ othe. Nake Mwathani nĩongagĩrĩra thiritũ-inĩ yao andũ arĩa maahonokaga o mũthenya.