Yeremia 5 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Yeremia 5:1-31

Hakuna Hata Mmoja Aliye Mkamilifu

15:1 Eze 22:30; Mwa 18:24; Mik 7:2; Yer 2:29; 2Nya 16:9; Za 45:10“Pandeni na kushuka katika mitaa ya Yerusalemu,

tazameni pande zote na mtafakari,

tafuteni katika viwanja vyake.

Kama mtaweza kumpata hata mtu mmoja tu

atendaye kwa uaminifu na kutafuta kweli,

nitausamehe mji huu.

25:2 Tit 1:16; Yer 4:2; Law 19:12Ingawa wanasema, ‘Kwa hakika kama Bwana aishivyo,’

bado wanaapa kwa uongo.”

35:3 2Nya 16:9; Yer 7:28; Isa 9:13; Sef 3:2; Zek 7:2; Eze 36:26; 3:8-9; Amo 4:6Ee Bwana, je, macho yako hayaitafuti kweli?

Uliwapiga, lakini hawakusikia maumivu,

uliwapondaponda, lakini walikataa maonyo.

Walifanya nyuso zao kuwa ngumu kuliko jiwe

nao walikataa kutubu.

45:4 Yer 8:7; Mit 10:21; Yer 4:22Ndipo nikasema, “Hawa ni maskini tu;

wao ni wapumbavu,

kwa maana hawaijui njia ya Bwana,

sheria ya Mungu wao.

55:5 Mik 3:1, 9; Za 2:3; Yer 2:20Kwa hiyo nitakwenda kwa viongozi

na kuzungumza nao,

hakika wao wanaijua njia ya Bwana,

sheria ya Mungu wao.”

Lakini kwa nia moja nao pia walikuwa wameivunja nira

na kuvivunja vifungo.

65:6 Hos 13:7; Yer 4:7; 30:14; Za 7:12; Law 26:22Kwa hiyo simba kutoka mwituni atawashambulia,

mbwa mwitu kutoka jangwani atawaangamiza,

chui atawavizia karibu na miji yao,

ili kumrarua vipande vipande yeyote atakayethubutu kutoka nje,

kwa maana maasi yao ni makubwa,

na kukengeuka kwao kumekuwa ni kwingi.

75:7 Yos 23:7; Yer 12:16; Gal 4:8; Amo 8:14; Kum 32:21; Hes 25:1; Yer 2:11; 13:27“Kwa nini niwasamehe?

Watoto wenu wameniacha na kuapa kwa miungu ambayo si miungu.

Niliwapatia mahitaji yao yote,

lakini bado wamefanya uzinzi na kusongana katika nyumba za makahaba.

85:8 Eze 22:11; 2Sam 11:2-4; Eze 33:26; Yer 29:23Wamelishwa vizuri, kama farasi waume wenye tamaa nyingi,

kila mmoja akimlilia mke wa mwanaume mwingine.

95:9 Yer 44:22; Eze 7:9; Isa 1:24; 57:6Je, nisiwaadhibu kwa ajili ya hili?”

asema Bwana.

“Je, nisijilipizie kisasi

juu ya taifa kama hili?

105:10 Yer 39:8; 4:27; Amo 9:8“Piteni katika mashamba yake ya mizabibu na kuyaharibu,

lakini msiangamize kabisa.

Pogoeni matawi yake,

kwa kuwa watu hawa sio wa Bwana.

115:11 1Fal 19:10; Yer 3:20; Za 73:27; Isa 24:16Nyumba ya Israeli na nyumba ya Yuda

wamekuwa si waaminifu kwangu kamwe,”

asema Bwana.

125:12 Yer 23:17; 2Nya 36:16; Yer 28:7; Isa 28:15; Yer 14:13Wamedanganya kuhusu Bwana.

Wamesema, “Yeye hatafanya jambo lolote!

Hakuna dhara litakalotupata;

kamwe hatutaona upanga wala njaa.

135:13 Yer 14:15; 2Nya 36:16; Ay 6:26Manabii ni upepo tu, wala neno halimo ndani yao,

kwa hiyo hayo wayasemayo na yatendeke kwao.”

145:14 Hos 6:5; Yer 1:9; 23:9; Za 39:3Kwa hiyo hili ndilo asemalo Bwana Mungu Mwenye Nguvu Zote:

“Kwa sababu watu hawa wamesema maneno haya,

nitayafanya maneno yangu vinywani mwenu kuwa moto,

na watu hawa wawe kuni

zinazoliwa na huo moto.

155:15 Kum 28:49; Isa 5:26; 2Fal 24:2; Isa 28:11; Mwa 11:7Ee nyumba ya Israeli,” asema Bwana,

“Ninaleta taifa toka mbali dhidi yako,

taifa la kale na linaloendelea kudumu,

taifa ambalo lugha yao huijui,

wala msemo wao huwezi kuuelewa.

165:16 Ay 39:23Podo zao ni kama kaburi lililo wazi,

wote ni mashujaa hodari wa vita.

175:17 Yer 30:16; Law 26:16; Yer 50:7-17; Kum 28:31-33; Yer 8:16; Hes 16:14; Hos 2:12Watayaangamiza mazao yenu na chakula chenu,

wataangamiza wana wenu na mabinti zenu;

wataangamiza makundi yenu ya kondoo na ya ngʼombe,

wataangamiza mizabibu yenu na mitini yenu.

Kwa upanga wataangamiza

miji yenye maboma mliyoitumainia.

18“Hata hivyo katika siku hizo, sitakuangamiza kabisa,” asema Bwana. 195:19 Kum 29:24-26; 4:28; Yer 15:4; 13:22; 1Fal 9; 9; Yer 16:13“Nao watu watakapouliza, ‘Kwa nini Bwana, Mungu wetu ametufanyia mambo haya yote?’ utawaambia, ‘Kama vile mlivyoniacha mimi na kutumikia miungu migeni katika nchi yenu wenyewe, ndivyo sasa mtakavyowatumikia wageni katika nchi ambayo si yenu.’

20“Itangazie nyumba ya Yakobo hili

na ulipigie mbiu katika Yuda:

215:21 Isa 6:10; Eze 12:2; Mdo 28:26; Isa 42:20; Mk 8:18; Kum 32:6; Yer 4:22; Hes 2:18Sikieni hili, enyi watu wapumbavu, msio na akili,

mlio na macho lakini hamwoni,

mlio na masikio lakini hamsikii:

225:22 Kum 28:58; Ay 4:14; Isa 64:2; Za 46:3Je, haiwapasi kuniogopa mimi?” asema Bwana.

“Je, haiwapasi kutetemeka mbele zangu?

Niliufanya mchanga kuwa mpaka wa bahari,

kizuizi cha milele ambacho haiwezi kupita.

Mawimbi yanaweza kuumuka, lakini hayawezi kuupita;

yanaweza kunguruma, lakini hayawezi kuuvuka.

235:23 Kum 21:18; Za 14:3Lakini watu hawa wana mioyo ya ukaidi na ya uasi,

wamegeukia mbali na kwenda zao.

245:24 Mt 5:45; Yoe 2:23; Mwa 8:22; Mdo 14:17; Kum 6:24; Yak 5:7Wao hawaambiani wenyewe,

‘Sisi na tumwogope Bwana Mungu wetu,

anayetupatia mvua za masika na za vuli kwa majira yake,

anayetuhakikishia majuma ya mavuno kwa utaratibu.’

25Matendo yenu mabaya yamezuia haya yote,

dhambi zenu zimewazuia msipate mema.

265:26 Za 10:8; Mit 1:11; Mt 7; 15; Mhu 9:12; Yer 9:8; Mik 7:2“Miongoni mwa watu wangu wamo walio waovu

wanaovizia kama watu wanaotega ndege,

na kama wale wanaoweka mitego

kuwakamata watu.

27Kama vitundu vilivyojaa ndege,

nyumba zao zimejaa udanganyifu;

wamekuwa matajiri na wenye nguvu,

285:28 Kum 32:15; Zek 7:10; Kut 22:21-24; Amo 5:12; Za 73:12; 82:3wamenenepa na kunawiri.

Matendo yao maovu hayana kikomo;

hawatetei mashauri ya yatima wapate kushinda,

hawatetei haki za maskini.

29Je, nisiwaadhibu kwa ajili ya hili?”

asema Bwana.

“Je, nisijilipizie kisasi

juu ya taifa kama hili?

305:30 Yer 18:13; Hos 6:10; Yer 23:14“Jambo la kutisha na kushtusha

limetokea katika nchi hii:

315:31 Eze 13:6; Isa 30:10; Mik 2:11; Mao 4:13; Hos 9:5Manabii wanatabiri uongo,

makuhani wanatawala kwa mamlaka yao wenyewe,

nao watu wangu wanapenda hivyo.

Lakini mtafanya nini mwisho wake?

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 5:1-31

Kò sí ọ̀kan tí o jẹ́ olóòtítọ́

1“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu

wò yíká, kí o sì mọ̀,

kí o sì wá kiri

Bí o bá le è rí ẹnìkan,

tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo,

n ó dáríjì ìlú yìí.

2Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’

síbẹ̀ wọ́n búra èké.”

3Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́

Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n.

Ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà.

Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ,

wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.

4Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí;

wọn jẹ́ aṣiwèrè,

nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa,

àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.

5Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ,

n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀;

ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa

àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.”

Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́,

wọ́n sì ti já ìdè.

6Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n,

ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run,

ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín

ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,

nítorí àìgbọ́ràn yín pọ,

ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.

7“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́?

Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀

àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra.

Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn,

síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà

wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.

8Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó,

tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.

9Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?”

ni Olúwa wí.

“Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi

lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?

10“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run,

ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá.

Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò,

nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.

11Ilé Israẹli àti ilé Juda

ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,”

ni Olúwa wí.

12Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa;

wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan!

Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá;

àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.

13Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́,

ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn.

Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”

14Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí:

“Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí;

Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná,

àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.

15Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí,

“Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín

Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì

àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀,

tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.

16Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí

gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.

17Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ,

àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin,

wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ,

wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ.

Pẹ̀lú idà ni wọn ó run

ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.

18“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá. 19Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’

20“Kéde èyí fún ilé Jakọbu,

kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.

215.21: Isa 6.9-10; Mt 13.10-15; Mk 8.17-18.Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn,

tí ó lójú ti kò fi ríran

tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.

22Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí.

“Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí?

Mo fi yanrìn pààlà Òkun,

èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé.

Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀;

wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.

23Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀,

wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.

24Wọn kò sọ fún ara wọn pé,

‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa,

ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀,

tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’

25Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò,

ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.

26“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà

tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ,

àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.

27Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ,

ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn.

Wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,

28Wọ́n sanra wọ́n sì ń dán.

Ìwà búburú wọn kò sì lópin;

wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀.

Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.

29Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?”

ni Olúwa wí.

“Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi

lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?

30“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara

ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.

31Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké,

àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn,

àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí,

kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?