Sefania 3 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Sefania 3:1-20

Hatima Ya Yerusalemu

13:1 Yer 6:6; Kum 21:18; Eze 23:30Ole mji wa wadhalimu,

waasi na waliotiwa unajisi!

23:2 Yer 5:3; 7:28; 22:21; Kum 1:32; Law 26:33; Za 78:23Hautii mtu yeyote,

haukubali maonyo.

Haumtumaini Bwana,

haukaribii karibu na Mungu wake.

33:3 Za 22:13; Mwa 49:27; Mik 3:3Maafisa wake ni simba wangurumao,

watawala wake ni mbwa mwitu wa jioni,

ambao hawabakizi chochote

kwa ajili ya asubuhi.

43:4 Za 25:3; Isa 48:8; Yer 3:20; 9:4; 23:11; Mal 2:10; Eze 22:26Manabii wake ni wenye kiburi,

ni wadanganyifu.

Makuhani wake hunajisi patakatifu

na kuihalifu sheria.

53:5 Ezr 9:15; Kum 32:4; Za 5:3; 99:3, 4; Mao 3:23; Yer 3:3; Eze 18:25Bwana aliye ndani yake ni mwenye haki,

hafanyi kosa.

Asubuhi kwa asubuhi hutoa haki yake,

kila kukipambazuka huitimiza,

bali mtu dhalimu hana aibu.

63:6 Law 26:31“Nimeyafutilia mbali mataifa,

ngome zao zimebomolewa.

Nimeziacha barabara ukiwa,

hakuna anayepita humo.

Miji yao imeharibiwa;

hakuna mmoja atakayeachwa:

hakuna hata mmoja.

73:7 Yer 7:28; Mwa 6:12; Hos 9:9Niliuambia huo mji,

‘Hakika utaniogopa na kukubali maonyo!’

Ndipo makao yake hayatafutiliwa mbali,

wala adhabu zangu zote hazitakuja juu yake.

Lakini walikuwa bado na shauku

kutenda kwa upotovu katika yote waliyofanya.”

83:8 Za 27:14; 79:6; Yoe 3:2; 3:11; Isa 2:3; Mit 20:22; Ufu 16:1; Yer 10:25; Mao 4:11; Sef 1:18Bwana anasema,

“Kwa hiyo ningojee mimi,

siku nitakayosimama kuteka nyara.

Nimeamua kukusanya mataifa,

kukusanya falme

na kumimina ghadhabu yangu juu yao,

hasira yangu kali yote.

Dunia yote itateketezwa

kwa moto wa wivu wa hasira yangu.

93:9 Sef 2:11; Mwa 4:26; Isa 19:18“Ndipo nitatakasa midomo ya mataifa,

kwamba wote waweze kuliitia jina la Bwana

na kumtumikia kwa pamoja.

103:10 Mwa 10:6; Za 68:31; Mal 1:11; Isa 60:7; Mdo 8:27; 2Nya 32:23Kutoka ngʼambo ya mito ya Kushi

watu wangu wanaoniabudu,

watu wangu waliotawanyika,

wataniletea sadaka.

113:11 Isa 29:22; Yoe 2:26-27; Mwa 50:15; Kut 15:17; Za 59:12; Mt 3:9; Law 26:19Siku hiyo hutaaibishwa

kwa ajili ya makosa yote ulionitendea,

kwa sababu nitawaondoa kutoka mji huu

wale wote wanaoshangilia

katika kiburi chao.

Kamwe hutajivuna tena

katika kilima changu kitakatifu.

123:12 Isa 14:32; Mt 5:3; Lk 6:20; Isa 57:15; Yer 29:12; Nah 1:7Lakini nitakuachia ndani yako

wapole na wanyenyekevu,

ambao wanatumaini jina la Bwana.

133:13 Isa 4:3; 10:21; Za 119:3; Yer 33:16; Ufu 14:5; Ay 16:17; Eze 34:25-28Mabaki ya Israeli hayatafanya kosa;

hawatasema uongo,

wala udanganyifu hautakuwa

katika vinywa vyao.

Watakula na kulala

wala hakuna yeyote

atakayewaogopesha.”

143:14 Za 9:14; 14:7; Zek 2:10; Isa 12:6; 51:11Imba, ee Binti Sayuni;

paza sauti, ee Israeli!

Furahi na kushangilia kwa moyo wako wote,

ee Binti Yerusalemu!

153:15 Yn 1:49; Eze 37:26-28; 48:35; Ufu 21:3; Isa 54:14; Zek 9:9Bwana amekuondolea adhabu yako,

amewarudisha nyuma adui zako.

Bwana, Mfalme wa Israeli, yu pamoja nawe;

kamwe hutaogopa tena madhara yoyote.

163:16 2Fal 19:26; Ebr 12:12; Ay 4:3; Isa 35:3-4Katika siku hiyo watauambia Yerusalemu,

“Usiogope, ee Sayuni;

usiiache mikono yako ilegee.

173:17 Isa 40:1; 62:4; 63:1; Yoe 2:21; Kum 28:63; Hos 14:4Bwana Mungu wako yu pamoja nawe,

yeye ni mwenye nguvu kuokoa.

Atakufurahia kwa furaha kubwa,

atakutuliza kwa pendo lake,

atakufurahia kwa kuimba.”

183:18 Mao 2:6“Huzuni katika sikukuu zilizoamriwa

nitaziondoa kwenu;

hizo ni mzigo na fedheha kwenu.

193:19 Isa 14:2; 60:18; Eze 34:16; Mik 4:6Wakati huo nitawashughulikia

wote waliokudhulumu;

nitaokoa vilema na kukusanya

wale ambao wametawanywa.

Nitawapa sifa na heshima

katika kila nchi ambayo waliaibishwa.

203:20 Yer 29:14; Eze 37:12; Za 22:27; Isa 56:5; 60:18; 66:22; Kum 26:19Wakati huo nitawakusanya;

wakati huo nitawaleta nyumbani.

Nitawapa sifa na heshima

miongoni mwa mataifa yote ya dunia

wakati nitakapowarudishia mateka yenu

mbele ya macho yenu hasa,”

asema Bwana.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Sefaniah 3:1-20

Ọjọ́ iwájú Jerusalẹmu

1Ègbé ni fún ìlú aninilára,

ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.

2Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni,

òun kò gba ìtọ́ni,

òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa,

bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.

3Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù,

àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn,

wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.

4Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga,

wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn.

Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́,

wọ́n sì rú òfin.

5Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo;

kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà.

Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀,

kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun,

síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.

6“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò,

ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́.

Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo

tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀.

Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí

ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù,

kò sì ní sí ẹnìkan rárá.

7Èmi wí fún ìlú náà wí pé

‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi,

ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’

Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò

bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó.

Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara

láti ṣe ìbàjẹ́.

8Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí,

“títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin;

nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ

kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ

àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn,

àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi.

Nítorí, gbogbo ayé

ni a ó fi iná owú mi jẹ run.

9“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,

nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,

láti fi ọkàn kan sìn ín.

10Láti òkè odò Etiopia,

àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,

yóò mú ọrẹ wá fún mi.

11Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì

nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi,

nígbà náà ni èmi yóò mu

kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.

Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́

ní òkè mímọ́ mi.

12Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù

àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀,

wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.

13Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà

ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké,

bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní

ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀,

bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”

14Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,

kígbe sókè, ìwọ Israẹli!

Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn,

ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.

15Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì

kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn.

Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ,

Ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.

16Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé,

“Má ṣe bẹ̀rù Sioni;

má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.

17Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ,

Ó ní agbára láti gbà ọ là.

Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀;

Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀,

Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”

18“Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ,

àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀;

àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.

19Ní àkókò náà

ni èmi yóò dojúkọ àwọn

tí ń ni yín lára,

èmi yóò gba àtiro là,

èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ,

èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní

gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.

20Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ;

Nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé.

Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín

láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé,

nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín

padà bọ sípò ní ojú ara yín,”

ni Olúwa wí.