Isaya 60 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Isaya 60:1-22

Utukufu Wa Sayuni

160:1 Isa 52:2; Yn 8:12; Mal 4:2; Za 36:9; Efe 5:14; Za 118:27; Ufu 21:11; Kut 16:7“Ondoka, angaza, kwa kuwa nuru yako imekuja

na utukufu wa Bwana umezuka juu yako.

260:2 Yer 13:16; Kol 1:13; 1Sam 2:9; Za 82:5; Isa 8:20; Za 107:14Tazama, giza litaifunika dunia

na giza kuu litayafunika mataifa,

lakini Bwana atazuka juu yako

na utukufu wake utaonekana juu yako.

360:3 Mt 2:1-11; Isa 49:23; Ufu 21:24; Isa 44:5; 45:14; 42:6Mataifa watakuja kwenye nuru yako

na wafalme kwa mwanga wa mapambazuko yako.

460:4 Isa 11:12; 43:6; 49:20-22; Yer 30:10; Isa 43:6“Inua macho yako na utazame pande zote:

Wote wanakusanyika na kukujia,

wana wako wanakuja toka mbali,

nao binti zako wanabebwa mikononi.

560:5 Rum 11:25; Kut 34:29; Isa 35:2; 65:13; 66:14; Zek 10:7; Kum 33:19; Amu 3:15; Ufu 21; 6Ndipo utatazama na kutiwa nuru,

moyo wako utasisimka na kujaa furaha,

mali zilizo baharini zitaletwa kwako,

utajiri wa mataifa utakujilia.

660:6 Mwa 25:2-4; Yer 6:20; Za 72:10; Mt 2:11; Amu 6:5; Isa 42:10Makundi ya ngamia yatajaa katika nchi yako,

ngamia vijana wa Midiani na Efa.

Nao wote watokao Sheba watakuja,

wakichukua dhahabu na uvumba

na kutangaza sifa za Bwana.

760:7 Mwa 25:13; Hag 2:3-9; Isa 18:7; Sef 3:10; Eze 20:40; 43:27; Isa 19:21Makundi yote ya Kedari yatakusanyika kwako,

kondoo dume wa Nebayothi watakutumikia,

watakubalika kama sadaka juu ya madhabahu yangu,

nami nitalipamba Hekalu langu tukufu.

860:8 Isa 49:21; 19:1“Ni nani hawa warukao kama mawingu,

kama hua kuelekea kwenye viota vyao?

960:9 Mwa 10:4; Isa 2:16; 14:2; Yer 30:19; Isa 43:6; Gal 4:26; 1Fal 10:22Hakika visiwa vinanitazama,

merikebu za Tarshishi60:9 Au: za biashara (ona pia 1Fal 10:22; 22:48; 2Nya 9:21; 20:36; Isa 2:16). ndizo zinazotangulia,

zikiwaleta wana wenu kutoka mbali,

wakiwa na fedha na dhahabu zao,

kwa heshima ya Bwana, Mungu wenu,

yeye Aliye Mtakatifu wa Israeli,

kwa maana amekujalia utukufu.

1060:10 Ezr 1:2; Ufu 21:24; Za 102:13; Isa 54:8; Kut 1:11; Isa 14:1-2; 56:6“Wageni watazijenga upya kuta zako,

na wafalme wao watakutumikia.

Ingawa katika hasira nilikupiga,

lakini katika upendeleo wangu

nitakuonyesha huruma.

1160:11 Mik 2:13; Ufu 21:25-26; Isa 2:12; 61:6; Za 24:7Malango yako yatakuwa wazi siku zote,

kamwe hayatafungwa, mchana wala usiku,

ili watu wapate kukuletea utajiri wa mataifa:

wafalme wao wakiongoza maandamano ya ushindi.

1260:12 Isa 11:14; Zek 14:17; Za 2:12; Dan 2:34; Mwa 27:29Kwa maana taifa au ufalme ule ambao hautakutumikia utaangamia;

utaharibiwa kabisa.

1360:13 Isa 35:2; Ezr 3:7; 1Nya 28:2; Isa 41:19“Utukufu wa Lebanoni utakujilia,

msunobari, mvinje pamoja na mteashuri,

ili kupapamba mahali pangu patakatifu,

nami nitapatukuza mahali pa miguu yangu.

1460:14 Mwa 27:29; Ufu 3:9; Ebr 12:22; Isa 14:9; 1:12Wana wa wale waliokuonea watakuja wakisujudu mbele yako,

wote wanaokudharau watasujudu kwenye miguu yako,

nao watakuita Mji wa Bwana,

Sayuni ya Aliye Mtakatifu wa Israeli.

1560:15 Isa 6:12; 54:6; Za 126:5; Isa 65:18; 1:7-9; Kut 14:30; Isa 33:8“Ingawa umeachwa na kuchukiwa,

bila yeyote anayesafiri ndani yako,

nitakufanya kuwa fahari ya milele,

na furaha ya vizazi vyote.

1660:16 Eze 34:30; Kut 6:2; Isa 66:11-12; Ay 19:25; Isa 59:20; Kut 14:30Utanyonya maziwa ya mataifa,

na kunyonyeshwa matiti ya wafalme.

Ndipo utakapojua kwamba Mimi, Bwana, ni Mwokozi wako,

Mkombozi wako, niliye Mwenye Nguvu wa Yakobo.

1760:17 1Fal 10:21; Za 85:8; Isa 66:12; 9:7; Hag 2:9Badala ya shaba nitakuletea dhahabu,

na fedha badala ya chuma.

Badala ya mti nitakuletea shaba,

na chuma badala ya mawe.

Nitafanya amani kuwa mtawala wako,

na haki kuwa mfalme wako.

1860:18 Law 26:6; 2Sam 7:10; Yer 33:9; Sef 3:20; Isa 9:4; 49:19; 33:6; 61:11; 62:7Jeuri hazitasikika tena katika nchi yako,

wala maangamizi au uharibifu ndani ya mipaka yako,

lakini utaita kuta zako Wokovu,

na malango yako Sifa.

1960:19 Zek 2:5; Za 36:9; Ufu 21:23; 22:5; Za 118:27Jua halitakuwa tena nuru yako mchana,

wala mwangaza wa mwezi hautakuangazia,

kwa maana Bwana atakuwa nuru yako ya milele,

naye Mungu wako atakuwa utukufu wako.

2060:20 Amo 8:9; Isa 30:19, 26; Ufu 7:17; Isa 35:10Jua lako halitazama tena,

nao mwezi wako hautafifia tena;

Bwana atakuwa nuru yako milele,

nazo siku zako za huzuni zitakoma.

2160:21 Efe 2:10; Law 10:3; Za 37:11, 22; Zek 8:12; Amo 9:15; Isa 4:3; Yer 32:41; Mt 15:13Ndipo watu wako wote watakuwa waadilifu,

nao wataimiliki nchi milele.

Wao ni chipukizi nililolipanda,

kazi ya mikono yangu,

ili kuonyesha utukufu wangu.

2260:22 Mwa 12:2; Kum 1:10; Isa 5:19Aliye mdogo kwenu atakuwa elfu,

mdogo kuliko wote atakuwa taifa lenye nguvu.

Mimi ndimi Bwana;

katika wakati wake nitayatimiza haya upesi.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 60:1-22

Ògo Sioni

1“Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé,

ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.

2Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé

òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn,

ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́

ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.

3Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ,

àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.

4“Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò:

Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ;

àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn,

àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.

5Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán,

ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀;

ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ,

sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.

660.6: Mt 2.11.Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ,

àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani.

Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá,

wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́

tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.

7Gbogbo agbo ẹran Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ,

àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́;

wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi,

bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.

8“Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru,

gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?

9Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí;

ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi;

mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn,

pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn,

fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ,

Ẹni Mímọ́ Israẹli,

nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.

10“Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ

àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́.

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́,

ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.

1160.11: If 21.25-26.Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀,

a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru,

tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó

ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá

tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní

ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.

12Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun;

pátápátá ni yóò sì dahoro.

13“Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,

igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀,

láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi;

àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.

1460.14: If 3.9.Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò

wá foríbalẹ̀ fún ọ;

gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ

wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa,

Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.

15“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀,

láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá,

Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé

àti ayọ̀ àtìrandíran.

16Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè

a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba.

Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi Olúwa,

èmi ni Olùgbàlà rẹ,

Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.

17Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ,

dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ,

àti irin dípò òkúta.

Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ

àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.

18A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́,

tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ,

ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà

àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.

19Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́,

tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́,

nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé,

àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.

20Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́,

àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́;

Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ,

àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.

21Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo

àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé.

Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn,

iṣẹ́ ọwọ́ mi,

láti fi ọláńlá mi hàn.

22Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan,

èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá.

Èmi ni Olúwa;

ní àkókò rẹ̀ Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”