Isaya 51 – NEN & YCB

Kiswahili Contemporary Version (Neno: Bibilia Takatifu)

Isaya 51:1-23

Wokovu Wa Milele Kwa Sayuni

151:1 Isa 46:3; Kum 7:13; Mit 26:27; Kum 16:20; Za 94:15; Isa 63:8; Rum 9:30-31; Isa 17:10“Nisikilizeni, ninyi mnaofuatia haki

na mnaomtafuta Bwana:

Tazameni mwamba ambako mlichongwa,

na mahali pa kuvunjia mawe ambako mlichimbwa;

251:2 Mwa 17:6; Ebr 11:11; Mwa 12:2; Isa 29:22; Rum 4:16mwangalieni Abrahamu, baba yenu,

na Sara, ambaye aliwazaa.

Wakati nilipomwita alikuwa mmoja tu,

nami nikambariki na kumfanya kuwa wengi.

351:3 Isa 40:1; Mwa 13:10; Yer 16:9; Za 102:13; Isa 44:26; Za 51:18; Isa 61:4Hakika Bwana ataifariji Sayuni,

naye atayaangalia kwa huruma magofu yake yote;

atayafanya majangwa yake yawe kama Edeni,

nazo sehemu zake zisizolimika ziwe kama bustani ya Bwana.

Shangwe na furaha zitakuwako ndani yake,

shukrani na sauti za kuimba.

451:4 Kut 6:7; Isa 26:18; 42:4-6; Za 50:7; Isa 3:15; 63:8“Nisikilizeni, watu wangu;

nisikieni, taifa langu:

Sheria itatoka kwangu;

haki yangu itakuwa nuru kwa mataifa.

551:5 Isa 35:4; 46:13; Za 98:1; 85:9; Mwa 49:10; Isa 52:10Haki yangu inakaribia mbio,

wokovu wangu unakuja,

nao mkono wangu utaleta hukumu kwa mataifa.

Visiwa vitanitegemea

na kungojea mkono wangu kwa matumaini.

651:6 Za 37:20; Lk 21:33; Za 102:25-26; Ebr 1:10-12; Mt 24:35; Isa 54:10Inueni macho yenu mbinguni,

mkaitazame dunia chini;

mbingu zitatoweka kama moshi,

dunia itachakaa kama vazi,

na wakazi wake kufa kama mainzi.

Bali wokovu wangu utadumu milele,

haki yangu haitakoma kamwe.

751:7 Za 37:31; Mt 10:28; Mdo 5:41; Za 119:39; Lk 6:22; Isa 54:4; 50:7“Nisikieni, ninyi mnaojua lililo sawa,

ninyi watu ambao mna sheria yangu mioyoni mwenu:

Msiogope mashutumu ya wanadamu

wala msitiwe hofu na matukano yao.

851:8 Ay 13:28; Yak 5:2; Isa 14:11Kwa maana nondo atawala kama vazi,

nao funza atawatafuna kama sufu.

Lakini haki yangu itadumu milele,

wokovu wangu kwa vizazi vyote.”

951:9 Kut 32:7; Za 68:30; Ay 26:12; Eze 29:3; Amu 5:12; Mwa 18:14; Za 65:6; 74:13Amka, Amka! Jivike nguvu,

ewe mkono wa Bwana,

Amka, kama siku zilizopita,

kama vile vizazi vya zamani.

Si ni wewe uliyemkata Rahabu vipande vipande,

uliyemchoma yule joka?

1051:10 Zek 10:11; Kut 14:21; Ufu 16:12; Kut 15:5, 8, 13; Ay 36:30Si ni wewe uliyekausha bahari,

maji ya kilindi kikuu,

uliyefanya barabara katika vilindi vya bahari

ili waliokombolewa wapate kuvuka?

1151:11 Isa 35:9; 44:23; 48:20; Ufu 7:17; Yer 31:13; 30:19; Sef 3:17; Isa 30:19Wale waliolipiwa fidia na Bwana watarudi.

Wataingia Sayuni wakiimba;

furaha ya milele itakuwa taji juu ya vichwa vyao.

Furaha na shangwe zitawapata,

huzuni na kulia kwa uchungu kutatoweka.

1251:12 Za 118:6; 2Kor 1:3-4; 1Pet 1:24; Isa 15:6; 2Fal 1:15; Isa 2:22; 40:6-7“Mimi, naam mimi,

ndimi niwafarijie ninyi.

Ninyi ni nani hata kuwaogopa

wanadamu wanaokufa,

wanadamu ambao ni majani tu,

1351:13 Ay 8:13; 4:17; Isa 17:10; 7:4; Ay 20:7; Isa 45:11; 48:13; 9:4kwamba mnamsahau Bwana Muumba wenu,

aliyezitanda mbingu

na kuiweka misingi ya dunia,

kwamba mnaishi katika hofu siku zote

kwa sababu ya ghadhabu ya mdhalimu,

ambaye nia yake ni kuangamiza?

Iko wapi basi ghadhabu ya mdhalimu?

1451:14 Isa 49:10; Zek 9:11; Isa 42:7Wafungwa waliojikunyata kwa hofu

watawekwa huru karibuni;

hawatafia kwenye gereza lao,

wala hawatakosa chakula.

1551:15 Kut 14:21; Isa 43:16; Za 74:13; Yer 31:35; Za 93:3; Isa 13:4Kwa maana Mimi ndimi Bwana, Mungu wako,

ambaye huisukasuka bahari ili mawimbi yake yangurume:

Bwana Mwenye Nguvu Zote ndilo jina lake.

1651:16 Kut 4:12-15; 2Pet 3:13; Kum 18:18; 33:22; Zek 8:8; Eze 14:11; Yer 7:23; 24:7Nimeweka maneno yangu kinywani mwako

na kukufunika kwa uvuli wa mkono wangu:

Mimi niliyeweka mbingu mahali pake,

niliyeweka misingi ya dunia,

niwaambiaye Sayuni,

‘Ninyi ni watu wangu.’ ”

Kikombe Cha Ghadhabu Ya Bwana

1751:17 Amu 5:12; Ay 21:20; Ufu 16:19; Za 60:3; 16:5; Mt 20:22; Isa 42:25Amka, amka!

Simama, ee Yerusalemu,

wewe uliyekunywa kutoka mkono wa Bwana

kikombe cha ghadhabu yake,

wewe uliyekunywa mpaka kufikia machujo yake,

kikombe kile cha kunywea

kiwafanyacho watu kuyumbayumba.

1851:18 Ay 31:18; Za 88:18; Isa 49:21; 41:13Kati ya wana wote aliowazaa

hakuwepo hata mmoja wa kumwongoza,

kati ya wana wote aliowalea

hakuwepo hata mmoja wa kumshika mkono.

1951:19 Isa 40:2; 47:9; 49:13; Yer 14:12; 24:10Majanga haya mawili yamekuja juu yako:

ni nani awezaye kukufariji?

Maangamizi, uharibifu, njaa na upanga:

ni nani awezaye kukutuliza?

2051:20 Yer 14:16; Mao 2:19; Isa 5:25; Ay 18:10; Yer 44:6; Ay 40:11; Kum 28:20Wana wako wamezimia,

wamelala kwenye mwanzo wa kila barabara,

kama swala aliyenaswa kwenye wavu.

Wamejazwa na ghadhabu ya Bwana

na makaripio ya Mungu wako.

2151:21 Isa 14:32; 29:9; Mao 3:15Kwa hiyo sikiliza hili, wewe uliyeteswa,

uliyelewa, lakini si kwa mvinyo.

2251:22 Yer 50:34; Hab 2:16; Isa 49:25; Yer 25:15; Mt 20:2251:22 Yer 50:34; Hab 2:16; Isa 49:25; Yer 25:15; Mt 20:22Hili ndilo asemalo Bwana Mwenyezi wako,

Mungu wako, yeye ambaye huwatetea watu wake:

“Tazama, nimeondoa mkononi mwako

kikombe kilichokufanya uyumbayumbe;

kutoka kikombe hicho,

kikombe cha kunywa cha ghadhabu yangu,

kamwe hutakunywa tena.

2351:23 Yer 49:12; Zek 12:3; Yos 10:24; Isa 14:4; 49:26; Yer 25:15-17, 26; Mik 7:1051:23 Yer 49:12; Zek 12:3; Yos 10:24; Isa 14:4; 49:26; Yer 25:15-17, 26; Mik 7:10Nitakiweka mikononi mwa watesi wako,

wale waliokuambia,

‘Anguka kifudifudi

ili tuweze kutembea juu yako.’

Ukaufanya mgongo wako kama ardhi,

kama njia yao ya kupita.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 51:1-23

Ìgbàlà ayérayé fún Sioni

1“Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodo

àti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa:

Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jáde

àti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;

2ẹ wo Abrahamu baba yín,

àti Sara, ẹni tó bí i yín.

Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni,

Èmi sì bùkún un, mo sì ṣọ́ ọ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.

3Dájúdájú, Olúwa yóò tu Sioni nínú

yóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀;

Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Edeni,

àti aṣálẹ̀ rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa.

Ayọ̀ àti inú dídùn ni a ó rí nínú rẹ̀,

ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.

4“Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ènìyàn mi;

gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè mi:

Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá;

ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀-èdè.

5Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan,

ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà,

àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wá

sí àwọn orílẹ̀-èdè.

Àwọn erékùṣù yóò wò mí

wọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.

651.6: Hb 1.11.Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run,

wo ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀;

Àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín,

ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wù

àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin.

Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé,

òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.

7“Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun òtítọ́,

ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyà yín:

Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàn

tàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.

8Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ;

Ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.

Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé,

àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”

9Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbára

Ìwọ apá Olúwa;

dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì,

àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́.

Ìwọ kọ́ lo ké Rahabu sí wẹ́wẹ́

tí o sì fa ẹ̀mí búburú ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?

10Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi Òkun bí

àti àwọn omi inú ọ̀gbun,

Tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìsàlẹ̀ Òkun

tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?

11Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá.

Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin kíkọ;

ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo orí wọn.

Ayọ̀ àti inú dídùn yóò sì bà lé wọn

ìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.

12“Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú.

Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran ara,

àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,

13tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ,

ẹni tí ó ta àwọn ọ̀run

tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀,

tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́

nítorí ìbínú àwọn aninilára,

tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀lé ìpanirun?

Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?

14Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ

wọn kò ní kú sínú túbú wọn,

bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.

15Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,

tí ó ń ru Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí

ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo

Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

16Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹ

mo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́

Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí ààyè rẹ̀,

ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀,

àti ẹni tí ó sọ fún Sioni pé,

‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’ ”

Ago ìbínú Olúwa

17Jí, jí!

Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu,

ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa

ago ìbínú rẹ̀,

ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀

tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.

18Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí

kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà

nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́

kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.

19Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ—

ta ni yóò tù ọ́ nínú?

Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà

ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?

20Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú;

wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà,

gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n.

Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́

àti ìbáwí Ọlọ́run yín.

21Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́,

tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì

22Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí,

Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́,

“Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ

ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n;

láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi,

ni ìwọ kì yóò mu mọ́.

23Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́,

àwọn tí ó wí fún ọ pé,

‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’

Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀

gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”