ኤርምያስ 12 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኤርምያስ 12:1-17

የኤርምያስ ማጕረምረም

1እግዚአብሔር ሆይ፤ ጕዳዬን በፊትህ ሳቀርብ፣

አንተ ጻድቅ መሆንህን እያወቅሁ ነው።

የክፉዎች መንገድ ለምን ይሰምራል?

የከዳተኞችስ ኑሮ ለምን ይሳካል?

2አንተ ተክለሃቸዋል፤ ሥርም ሰደዋል፤

አድገዋል፤ ፍሬም አፍርተዋል።

ሁልጊዜ አንተ በአፋቸው ላይ አለህ፤

ከልባቸው ግን ሩቅ ነህ።

3ነገር ግን እግዚአብሔር ሆይ፤ አንተ እኔን ታውቀኛለህ፤ ታየኛለህ፤

ስለ አንተም ያለኝን ሐሳብ ትመረምራለህ።

እንደሚታረዱ በጎች ንዳቸው፤

ለዕርድም ቀን ለይተህ አቈያቸው፤

4ምድሪቱ በዝናብ ዕጦት የምትጐዳው፣12፥4 ወይም ምድሪቱ የምታዝነው

የሜዳውም ሣር ሁሉ በድርቅ የሚመታው እስከ መቼ ነው?

ከነዋሪዎቿ ክፋት የተነሣ፣

እንስሳትና አዕዋፍ ጠፍተዋል፤

ደግሞም ሕዝቡ፣

“በእኛ ላይ የሚሆነውን አያይም” ብለዋል።

የእግዚአብሔር ምላሽ

5“ከእግረኞች ጋር ሮጠህ፣

እነርሱ ካደከሙህ፣

ከፈረሰኞች ጋር እንዴት ልትወዳደር ትችላለህ?

በሰላም አገር ከተሰናከልህ፣12፥5 ወይም በሰላም ምድር ከታመንህ

በዮርዳኖስ ደን ውስጥ እንዴት ልትሆን ነው?

6ወንድሞችህና የገዛ ቤተ ሰብህ፣

እነርሱ እንኳ አሢረውብሃል፣

በአንተም ላይ ይጮኻሉ፤

በመልካም ቢናገሩህም እንኳ

አትመናቸው።

7“ቤቴን እተዋለሁ፤

ርስቴን እጥላለሁ፤

የምወድዳትን እርሷን፣

አሳልፌ በጠላቶቿ እጅ እሰጣታለሁ።

8ርስቴ፣ በዱር እንዳለ አንበሳ

ተነሥታብኛለች፤

በእኔም ላይ ጮኻብኛለች፤

ስለዚህ ጠላኋት።

9ርስቴ ሌሎች አሞሮች ሊበሏት እንደ ከበቧት፣

እንደ ዝንጕርጕር አሞራ አልሆነችምን?

ሂዱ፤ የዱር አራዊትን ሁሉ ሰብስቡ፤

እንዲቀራመቷትም አምጧቸው።

10ብዙ እረኞች የወይን ቦታዬን ያጠፋሉ፤

ይዞታዬንም ይረግጣሉ፤

ደስ የምሰኝበትንም ማሳ፣

ጭር ያለ በረሓ ያደርጉታል።

11በፊቴ ባድማ፣

ደረቅና ወና ይሆናል፤

መላዪቱም ምድር ጠፍ ትሆናለች፤

ስለ እርሷ የሚገድደው የለምና።

12በምድረ በዳ ባሉት ወና ኰረብቶች ላይ፣

አጥፊዎች ይሰማራሉ፤

የእግዚአብሔር ሰይፍ ከምድር ጫፍ እስከ ምድር ጫፍ፣

አንዳች ሳያስቀር ይበላል፤

የሚተርፍም የለም።

13ስንዴን ይዘራሉ፤ እሾኽን ያጭዳሉ፤

ይደክማሉ፤ የሚያገኙት ግን የለም።

ከእግዚአብሔርም ጽኑ ቍጣ የተነሣ፣

በመኸራችሁ ውጤት ታፍራላችሁ።”

14እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤ “ለሕዝቤ ለእስራኤል የሰጠሁትን ርስት የሚይዙትን ክፉ ጎረቤቶቼን ሁሉ ከምድራቸው እነቅላቸዋለሁ፤ የይሁዳንም ቤት ከመካከላቸው እነቅላለሁ፤ 15ከነቀልኋቸው በኋላ ግን መልሼ እምራቸዋለሁ፤ እያንዳንዳቸውንም ወደ ገዛ አገራቸውና ወደ ገዛ ርስታቸው መልሼ አመጣቸዋለሁ። 16የሕዝቤን መንገድ በትጋት ቢማሩና ሕዝቤን በበኣል እንዲምል እንዳስተማሩት ሁሉ፣ ‘ሕያው እግዚአብሔርን’ ብለው በስሜ ቢምሉ፣ በዚያን ጊዜ በሕዝቤ መካከል ይመሠረታሉ፤ 17የማይሰማኝን ሕዝብ ግን ፈጽሜ እነቅለዋለሁ፤ አጠፋዋለሁም” ይላል እግዚአብሔር

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jeremiah 12:1-17

Ọ̀rọ̀ Jeremiah

1Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkúgbà,

nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá.

Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ.

Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé?

Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?

2Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀,

wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso.

Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn,

o jìnnà sí ọkàn wọn.

3Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa,

o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò.

Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa.

Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.

4Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà,

tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ?

Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀.

Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé,

pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé,

“Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”

Ìdáhùn Ọlọ́run

5Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré,

tí àárẹ̀ sì mú ọ,

báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje?

Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà,

bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé,

kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?

6Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn

ìdílé—

ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ

Wọ́n ti hó lé ọ lórí;

Má ṣe gbà wọ́n gbọ́

bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.

7Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀,

èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀.

Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́

lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

8Ogún mi ti rí sí mi

bí i kìnnìún nínú igbó.

Ó ń bú ramúramù mọ́ mi;

nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.

9Ogún mi kò ha ti rí sí mi

bí ẹyẹ kannakánná

tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i?

Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ,

ẹ mú wọn wá jẹ.

10Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́,

tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀;

Wọ́n ó sọ oko dídára mi di

ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.

11A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀

tí kò wúlò níwájú mi,

gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro

nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.

12Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀

ni àwọn apanirun ti gorí,

nítorí idà Olúwa yóò pa

láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà;

kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.

13Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká,

wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn.

Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín,

nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.

14Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Ní ti gbogbo àwọn aládùúgbò mi búburú tí wọ́n gbẹ́sẹ̀ lé ogún tí mo fún àwọn ènìyàn Israẹli mi, Èmi yóò fà wọ́n tu kúrò lórí ilẹ̀ wọn, èmi yóò fa ìdílé Juda tu kúrò ní àárín wọn. 15Ṣùgbọ́n tí mo bá fà wọ́n tu tán, Èmi yóò padà yọ́nú sí wọn. Èmi yóò sì padà fún oníkálùkù ní ogún ìní rẹ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ ìní oníkálùkù. 16Bí wọ́n bá sì kọ ìwà àwọn ènìyàn mi, tí wọ́n sì fi orúkọ mi búra wí pé, ‘níwọ̀n bí Olúwa ń bẹ láààyè,’ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti kọ́ àwọn ènìyàn mi láti fi Baali búra, nígbà náà ni a ó gbé wọn ró láàrín àwọn ènìyàn mi. 17Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kan kò bá gbọ́, Èmi yóò fà á tu pátápátá, èmi yóò sì pa wọ́n run,” ni Olúwa wí.