ኢዮብ 8 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢዮብ 8:1-22

በልዳዶስ

1ሹሐዊውም በልዳዶስ እንዲህ ሲል መለሰ፤

2“እንዲህ ያለውን ነገር የምትናገረው፣

ቃልህም እንደ ብርቱ ነፋስ የሚሆነው እስከ መቼ ነው?

3እግዚአብሔር ፍትሕን ያጣምማልን?

ሁሉን ቻይ አምላክስ ጽድቅን ያጣምማልን?

4ልጆችህ በእርሱ ላይ ኀጢአት ሠርተው ከሆነ፣

ለኀጢአታቸው ቅጣት አሳልፎ ሰጥቷቸዋል።

5ነገር ግን አንተ ወደ እግዚአብሔር ብትመለከት፣

ሁሉን ቻይ አምላክን ብትማፀን፣

6ንጹሕና ቅን ብትሆን፣ እርሱ ስለ አንተ አሁኑኑ ይነሣል፤

ወደ ተገቢውም ስፍራህ ይመልስሃል።

7ጅማሬህ አነስተኛ ቢመስልም፣

ፍጻሜህ እጅግ ታላቅ ይሆናል።

8“የቀደመውን ትውልድ ጠይቅ፤

አባቶቻቸውም የደረሱበትን መርምረህ አግኝ፤

9እኛ ትናንት ስለ ተወለድን አንዳች አናውቅምና፤

ዘመናችንም በምድር ላይ እንደ ጥላ ነው።

10እነርሱ የሚያስተምሩህና የሚነግሩህ፣

ከልቦናቸውም ቃልን የሚያወጡ አይደሉምን?

11ደንገል ረግረግ በሌለበት ስፍራ ይበቅላልን?

ቄጠማስ ውሃ በሌለበት ይለመልማልን?

12ገና በማደግ ላይ እያለ ሳይታጨድ፣

ከሌሎች ዕፀዋት ፈጥኖ ይደርቃል።

13እግዚአብሔርን የሚረሱ መጨረሻቸው እንዲህ ነው፤

አምላክ የለሽ ኑሮ የሚኖሩም ሁሉ ተስፋቸው ትጠፋለች።

14መተማመኛው ቀጭን ክር፣8፥14 በዕብራይስጥ የዚህ ቃል ትርጕም አይታወቅም።

ድጋፉም የሸረሪት ድር ነው።

15ድሩ ላይ ቢደገፍ ይበጠስበታል፤

አጥብቆም ቢይዘው አይጸናም።

16ውሃ እንደ ጠገበ ተክል፣ ፀሓይ እየሞቀው፣

ቅርንጫፉን ሁሉ በአትክልቱ ስፍራ ላይ ይዘረጋል።

17ሥሩን በድንጋይ ክምር ላይ ይጠመጥማል፤

በዐለትም መካከል ስፍራ ያበጃል።

18ከስፍራው ሲወገድ ግን፣

ያ ቦታ ‘አይቼህ አላውቅም’ ብሎ ይክደዋል።

19እነሆ፤ ሕይወቱ በዚህ ያከትማል፤8፥19 ወይም ያለው ደስታ ሁሉ

ሌሎች አትክልትም ከመሬት ይበቅላሉ።

20“እነሆ፤ እግዚአብሔር እንከን የሌለበትን ሰው አይጥልም፤

የክፉዎችንም እጅ አያበረታም፤

21እንደ ገና አፍህን በሣቅ፤

ከንፈሮችህንም በእልልታ ይሞላል።

22ጠላቶችህ ኀፍረት ይለብሳሉ፤

የክፉዎችም ድንኳን ይጠፋል።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 8:1-22

Bilidadi

1Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé:

2“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó?

Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?

3Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí?

Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?

4Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i,

ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.

5Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò,

tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.

6Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin:

ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ,

òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.

7Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í,

bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.

8“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì

kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.

9Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan,

nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.

10Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ?

Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?

11Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀

tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?

12Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀,

ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀

13Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run,

bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.

14Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò,

àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.

15Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró,

yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.

16Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn,

ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.

17Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká,

ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.

18Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀,

nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’

19Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù

àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.

20“Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù,

bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́

21títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu,

àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,

22ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀,

àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”