ኢዮብ 34 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢዮብ 34:1-37

1ኤሊሁ በመቀጠል እንዲህ አለ፤

2“እናንት ጠቢባን፣ ቃሌን ስሙ፤

ዐዋቂዎችም አድምጡኝ።

3ምላስ ምግብን አጣጥሞ እንደሚለይ፣

ጆሮም የንግግርን ለዛ ለይቶ ያውቃል።

4የሚበጀንን እንምረጥ፣

መልካሙንም አብረን እንወቅ።

5“ኢዮብ እንዲህ ይላል፤ ‘እኔ ንጹሕ ነኝ፤

እግዚአብሔር ግን ፍትሕ ነሣኝ፤

6እውነተኛ ብሆንም፣

እንደ ውሸታም ተቈጥሬአለሁ፤

በደል ባይኖርብኝም፣

በማይፈወስ ቍስል ተመትቻለሁ።’

7ፌዝን እንደ ውሃ የሚጠጣት፣

እንደ ኢዮብ ያለ ሰው ማን ነው?

8ከክፉ አድራጊዎች ጋር ይተባበራል፤

ከኀጢአተኞችም ጋር ግንባር ይፈጥራል።

9‘እግዚአብሔርን ለማስደሰት መሞከር፣

ለሰው አንዳች አይጠቅምም’ ብሏልና።

10“ስለዚህ፣ እናንተ አስተዋዮች ስሙኝ፤

ክፋትን ማድረግ ከእግዚአብሔር ዘንድ፣

በደልንም መፈጸም ሁሉን ከሚችል አምላክ ይራቅ።

11ለሰው እንደ ሥራው ይመልስለታል፤

እንደ አካሄዱም ይከፍለዋል።

12በእውነት እግዚአብሔር ክፋትን አይሠራም፤

ሁሉን የሚችል አምላክ ፍትሕን አያጣምምም።

13ምድርን እንዲገዛ የሾመው አለን?

የዓለምስ ሁሉ ባለቤት ያደረገው ማን ነው?

14እርሱ መንፈሱን መልሶ ቢወስድ፣

እስትንፋሱንም ወደ ራሱ ቢሰበስብ፣

15ሥጋ ለባሽ ሁሉ በአንድነት በጠፋ፣

ሰውም ወደ ዐፈር በተመለሰ ነበር።

16“ማስተዋል ካለህ ይህን ስማ፤

እኔ የምለውንም አድምጥ።

17ፍትሕን የሚጠላ ሊያስተዳድር ይችላልን?

አንተስ ጻድቁንና ኀያል የሆነውን ትኰንናለህ?

18ነገሥታትን ‘የማትረቡ ናችሁ፣’

መኳንንትንም፣ ‘ክፉዎች ናችሁ’

የሚላቸው እርሱ አይደለምን?

19ሁሉም የእጁ ሥራ ስለሆኑ፣

እርሱ ለገዦች አያደላም፤

ባለጠጋውንም ከድኻው አብልጦ አይመለከትም።

20እነርሱም እኩለ ሌሊት ላይ በድንገት ይሞታሉ፤

ሕዝብ ተንቀጥቅጦ ሕይወቱ ያልፋል፤

ኀያላኑም የሰው እጅ ሳይነካቸው ይወገዳሉ።

21“ዐይኖቹ የሰውን አካሄድ ይመለከታሉ፤

ርምጃውንም ሁሉ ይከታተላሉ።

22ክፉ አድራጊዎች የሚደበቁበት፣

ጨለማ ስፍራ ወይም የሞት ጥላ የለም።

23ሰው ለፍርድ ፊቱ ይቀርብ ዘንድ፣

እግዚአብሔር ቀጠሮ አይዝለትም።

24ያለ ምንም ጥያቄ ኀያላንን ያንኰታኵታል፤

ሌሎችንም በቦታቸው ይሾማል።

25እርሱ ሥራቸውን ሁሉ ስለሚያውቅ፣

በሌሊት ይገለብጣቸዋል፤

እነርሱም ይደቅቃሉ።

26ስለ ክፋታቸውም፣

በሰው ሁሉ ፊት ይቀጣቸዋል፤

27እርሱን ከመከተል ተመልሰዋልና፤

መንገዱንም ችላ ብለዋል።

28የድኾች ልቅሶ ወደ እርሱ እንዲደርስ ሰበብ ሆኑ፤

የመከረኞችን ጩኸት ሰማ።

29እርሱ ዝም ቢል፣ ማን ሊወቅሰው ይችላል?

ፊቱንስ ቢሰውር፣ ማን ሊያየው ይችላል?

እርሱ ከሰውም፣ ከሕዝብም በላይ ነው፤

30ይህም የሆነው ዐመፀኛው ሕዝቡን እንዳይገዛ፣

ወጥመድም በፊታቸው እንዳይዘረጋ ነው።

31“ሰው ለእግዚአብሔር እንዲህ ቢል የተሻለ ነበር፤

‘እኔ በደለኛ ነኝ፤ ከእንግዲህ ግን አልበድልም፤

32ማየት ያልቻልሁትን አስተምረኝ፤

ኀጢአት ሠርቼ እንደ ሆነም፣ ደግሜ አልሠራም።’

33ታዲያ አንተ ለመናዘዝ ፈቃደኛ ሳትሆን፤

እግዚአብሔር እንደ ወደድህ ይከፍልሃልን?

መወሰን ያለብህ አንተ ነህ እንጂ፣ እኔ አይደለሁም፤

እንግዲህ የምታውቀውን ንገረኝ።

34“አስተዋዮች ይናገራሉ፤

የሚሰሙኝም ጠቢባን እንዲህ ይሉኛል፤

35‘ኢዮብ ያለ ዕውቀት ይናገራል፤

ቃሉም ማስተዋል ይጐድለዋል።’

36ምነው ኢዮብ እስከ መጨረሻ በተፈተነ ኖሮ!

እንደ ክፉ ሰው መልሷልና፤

37በኀጢአቱም ላይ ዐመፅን ጨምሯል፤

በመካከላችን ሆኖ በንቀት አጨብጭቧል፤

በእግዚአብሔርም ላይ ብዙ ተናግሯል።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 34:1-37

Elihu pe Jobu níjà

1Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé:

2“Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,

kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.

3Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò,

bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.

4Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa;

ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.

5“Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi;

Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.

6Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí,

bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi,

ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’

7Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu,

tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?

8Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó

sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.

9Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn,

tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’

10“Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi,

ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye:

Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú,

àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!

11Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe,

yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.

12Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà;

bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.

13Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́,

tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?

14Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀

tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,

15gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀,

ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.

16“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye,

gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.

17Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí?

Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?

18O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘ènìyàn búburú ní ìwọ,’

tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘ìkà ni ẹ̀yin,’

19Mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé

tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ,

nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?

20Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú,

àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ;

a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.

21“Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn,

òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.

22Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú,

níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sápamọ́ sí.

23Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan,

kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.

24Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí,

a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,

25nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn,

ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.

26Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn

níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,

27nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i,

wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,

28kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀,

òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.

29Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi?

Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i?

Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;

30Kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba

kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.

31“Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé,

èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?

32Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi

bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.

33Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà?

Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́,

ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi.

Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀;

Pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!

34“Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi,

àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,

35‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀,

ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’

36Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin,

nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú:

37Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀;

ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa,

ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”