ኢዮብ 12 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢዮብ 12:1-25

ኢዮብ

1ኢዮብ እንዲህ ሲል መለሰ፤

2“በርግጥ ሰው ማለት እናንተ ናችኋ!

ጥበብም ከእናንተ ጋር ትሞታለቻ!

3ነገር ግን እኔም እንደ እናንተ አእምሮ አለኝ፤

ከእናንተ አላንስም፤

እንዲህ ያለውን ነገር የማያውቅ ማን ነው?

4እግዚአብሔርን ጠርቼ የመለሰልኝ ሰው ብሆንም፣

ለባልንጀሮቼ መሣቂያ ሆኛለሁ፤

ጻድቅና ያለ ነቀፋ ሆኜ እያለሁ፣ መሣቂያ ሆኛለሁ።

5የደላቸው በመከራ ያፌዛሉ፤

እግሩ የተንሸራተተውንም ይገፈትራሉ።

6የቀማኞች ድንኳን አይታወክም፤

አምላካቸውን በእጃቸው ይዘው እየዞሩም፣12፥6 ወይም የእግዚአብሔር እጅ በምታመጣላቸው ነገር

እግዚአብሔርንም እያስቈጡ በሰላም ይኖራሉ።

7“እስቲ እንስሶችን ጠይቁ፤ ያስተምሯችኋል፤

የሰማይ ወፎችንም ጠይቁ፣ ይነግሯችኋል፤

8ለምድር ተናገሩ፤ ታስተምራችኋለች፤

የባሕርም ዓሣ ይነግራችኋል።

9የእግዚአብሔር እጅ ይህን እንዳደረገ፣

ከእነዚህ ሁሉ የማያውቅ ማን ነው?

10የፍጥረት ሁሉ ሕይወት፣

የሰውም ሁሉ መንፈስ በእጁ ናትና፤

11ምላስ የምግብን ጣዕም እንደሚለይ፣

ጆሮ ቃላትን አይለይምን?

12ጥበብ ያለው በአረጋውያን ዘንድ አይደለምን?

ማስተዋልስ ረዥም ዕድሜ ባላቸው ዘንድ አይገኝምን?

13“ጥበብና ኀይል የእግዚአብሔር ናቸው፤

ምክርና ማስተዋልም በእርሱ ዘንድ ይገኛሉ።

14እርሱ ያፈረሰውን መልሶ የሚገነባ የለም፣

እርሱ ያሰረውን የሚፈታ አይገኝም።

15እርሱ ውሃን ቢከለክል፣ ድርቅ ይሆናል፤

ቢለቅቀውም ውሃው ምድሪቱን ያጥለቀልቃል።

16ብርታትና ድል ማድረግ በእርሱ ዘንድ ይገኛል፤

አታላዩም ተታላዩም በእርሱ እጅ ናቸው።

17አማካሪዎችን ከጥበባቸው ያራቍታል፤

ፈራጆችንም ማስተዋል ይነሣል።

18ነገሥታትን ድግ ያስፈታል፤

ገመድም በወገባቸው ያስራል።12፥18 ወይም የነገሥታትን ድግ፤ ሠቅ ያስራል

19ካህናትን ከክህነታቸው ያዋርዳል፤

ለዘመናት የተደላደሉትንም ይገለብጣል።

20ዕውቅ መካሪዎችን ቋንቋ ያሳጣል፤

የሽማግሌዎችንም ማስተዋል ይወስዳል።

21የተከበሩትን ውርደት ያከናንባል፤

ብርቱዎችንም ትጥቅ ያስፈታል።

22የጨለማን ጥልቅ ነገሮች ይገልጣል፤

የሞትንም ጥላ ወደ ብርሃን ያወጣል።

23ሕዝቦችን ታላቅ ያደርጋል፤ መልሶም ያጠፋቸዋል፤

ሕዝቦችን ያበዛል፤ ያፈልሳቸዋልም።

24የዓለም መሪዎችን ማስተዋል ይነሣል፣

መንገድ በሌለበት በረሓም ያቅበዘብዛቸዋል፤

25ብርሃን በሌለበት ጨለማ በዳበሳ ይሄዳሉ፤

እንደ ሰካራምም ይንገዳገዳሉ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Jobu 12:1-25

Ìdáhùn Jobu

1Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé:

2“Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà,

ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!

3Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin:

èmi kò kéré sí i yín:

àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?

4“Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,

tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn:

à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.

5Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà,

gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.

6Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù;

àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu,

àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.

7“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,

àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.

8Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,

àwọn ẹja inú Òkun yóò sì sọ fún ọ.

9Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan

wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?

10Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà,

Àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.

11Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí

tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?

12Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,

àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.

13“Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára:

Òun ló ni ìmọ̀ àti òye.

14Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́;

Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.

15Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ;

Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.

16Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun;

Ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.

17Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò,

A sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.

18Ó tú ìdè ọba,

Ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.

19Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò,

Ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.

20Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò,

Ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.

21Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá,

Ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.

22Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá,

Ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.

23Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;

Òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.

24Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé,

A sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.

25Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀,

Òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.