ኢሳይያስ 6 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢሳይያስ 6:1-13

የኢሳይያስ ተልእኮ

1ንጉሥ ዖዝያን በሞተበት ዓመት እግዚአብሔርን ከፍ ባለና በከበረ ዙፋን ላይ ተቀምጦ አየሁት፤ የልብሱም ዘርፍ ቤተ መቅደሱን ሞልቶት ነበር። 2ሱራፌልም ከእርሱ በላይ ቆመው ነበር፤ እያንዳንዳቸውም ስድስት ክንፍ ነበራቸው። በሁለት ክንፍ ፊታቸውን ይሸፍኑ ነበር፤ በሁለት ክንፍ እግራቸውን ይሸፍኑ ነበር፤ በሁለቱም ክንፍ ይበርሩ ነበር፤ 3እርስ በርሳቸው በመቀባበልም፣

“ቅዱስ፣ ቅዱስ፣ ቅዱስ የሰራዊት ጌታ እግዚአብሔር

ምድር ሁሉ በክብሩ ተሞልታለች”

ይሉ ነበር። 4ከድምፃቸው ጩኸት የተነሣ የመድረኩ መሠረት ተናወጠ፤ ቤተ መቅደሱም በጢስ ተሞላ።

5እኔም፣ “ከንፈሮቼ የረከሱብኝ ሰው ነኝ፤ የምኖረውም ከንፈሮቹ በረከሱበት ሕዝብ መካከል ነው፤ ዐይኖቼም ንጉሡን፣ የሰራዊት ጌታ እግዚአብሔርን አይተዋልና ጠፍቻለሁ፣ ወዮልኝ!” አልሁ።

6ከዚያም ከሱራፌል አንዱ፣ ከመሠዊያው ላይ የእሳት ፍም በጕጠት ወስዶ፣ ወደ እኔ እየበረረ መጣ። 7አፌንም በእሳቱ ነክቶ፣ “እነሆ፤ ይህ ከንፈሮችህን ነክቷል፤ በደልህ ተወግዶልሃል፤ ኀጢአትህም ተሰርዮልሃል” አለኝ።

8ከዚያም የጌታ ድምፅ፣ “ማንን እልካለሁ? ማንስ ይሄድልናል?” ሲል ሰማሁት።

እኔም፣ “እነሆኝ፤ እኔን ላከኝ” አልሁ።

9እርሱም እንዲህ አለኝ፤ “ወደዚህ ሕዝብ ሂድ፤

“ ‘መስማትን ትሰማላችሁ፤ ነገር ግን አታስተውሉም፤

ማየትንም ታያላችሁ፤ ነገር ግን ልብ አትሉም’ ብለህ ንገራቸው።

10የዚህን ሕዝብ ልብ አደንድን፤

ጆሯቸውን ድፈን፤

ዐይኖቻቸውንም ክደን፤

ይህ ካልሆነማ፣

በዐይናቸው አይተው፣ በጆሯቸው ሰምተው፣

በልባቸውም አስተውለው

በመመለስ ይፈወሳሉ።”

11እኔም፣ “ጌታ ሆይ፤ ይህ የሚሆነው እስከ መቼ ነው?” አልሁት፤

እርሱም መልሶ እንዲህ አለኝ፤

“ከተሞች እስኪፈራርሱና

የሚኖሩባቸው እስኪያጡ፣

ቤቶችም ወና እስኪሆኑና

ምድርም ፈጽሞ ባድማ እስክትሆን ድረስ፤

12እግዚአብሔርም ሰዎችን እስከሚያርቅ፣

ምድሪቱም ጨርሶ ባዶ እስክትሆን፣

13ከዐሥር አንድ ሰው እንኳ በምድሪቱ ቢቀር፣

እርሱም ደግሞ ይጠፋል፤

ነገር ግን የኮምበልና የባሉጥ ዛፍ በተቈረጠ

ጊዜ ጕቶ እንደሚቀር፣

ቅዱሱም ዘር እንዲሁ በምድሪቱ ጕቶ ሆኖ ይቀራል።”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 6:1-13

Ìpè sí iṣẹ́ ìránṣẹ́ Isaiah

1Ní ọdún tí ọba Ussiah kú, mo rí Olúwa tí ó jókòó lórí ìtẹ́ tí ó ga tí a gbé sókè, ìṣẹ́tí aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili. 2Àwọn Serafu wà ní òkè rẹ̀, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ìyẹ́ mẹ́fà, wọ́n fi ìyẹ́ méjì bo ojú wọn, wọ́n fi méjì bo ẹsẹ̀ wọn, wọ́n sí ń fi méjì fò. 36.3: If 4.8.Wọ́n sì ń kọ sí ara wọn wí pé:

“Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun

gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”

46.4: If 15.8.Nípa ìró ohùn un wọn, òpó ìlẹ̀kùn àti gbogbo ògiri ilé náà sì mì tìtì, gbogbo inú tẹmpili sì kún fún èéfín.

5Mo kígbe pé “Ègbé ni fún mi! Mo ti gbé!” Nítorí mo jẹ́ ènìyàn aláìmọ́ ètè, mo sì ń gbé láàrín àwọn ènìyàn aláìmọ́ ètè, ojú mi sì ti rí ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ.

6Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn Serafu wọ̀nyí fò wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹ̀yín iná ní ọwọ́ rẹ̀, èyí tí ó ti fi ẹ̀mú mú ní orí pẹpẹ. 7Èyí ni ó fi kàn mí ní ẹnu tí ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ti kan ètè rẹ; a ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù.”

8Nígbà náà ni mo sì gbọ́ ohùn Olúwa wí pé, “Ta ni èmi yóò rán? Ta ni yóò sì lọ fún wa?”

Nígbà náà ni èmi sì wí pé, “Èmi nìyí, rán mi!”

96.9-10: Mt 13.14-15; Mk 4.12; Lk 8.10; Jh 12.39-41; Ap 28.26-27.Òun sì wí pé, “Tọ àwọn ènìyàn yìí lọ kí o sì wí fún wọn pé:

“ ‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín;

ní rí rí ẹ̀yin yóò ri, ẹ̀yin kì yóò mọ òye.’

10Mú kí àyà àwọn ènìyàn wọ̀nyí yigbì,

mú kí etí wọn kí ó wúwo,

kí o sì dìwọ́n ní ojú.

Kí wọn kí ó má ba fi ojú wọn ríran,

kí wọn kí ó má ba fi etí wọn gbọ́rọ̀,

kí òye kí ó má ba yé ọkàn wọn,

kí wọn kí ó má ba yípadà

kí a má ba mú wọn ní ara dá.”

11Nígbà náà ni mo wí pé, “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó Olúwa?”

Òun sì dáhùn pé:

“Títí àwọn ìlú ńlá yóò fi dahoro,

láìsí olùgbé nínú rẹ̀ mọ́,

títí tí àwọn ilé yóò fi wà láìsí ènìyàn,

títí tí ilẹ̀ yóò fi dahoro pátápátá.

12Títí tí Olúwa yóò fi rán gbogbo wọn jìnnà réré

tí ilẹ̀ náà sì di ìkọ̀sílẹ̀ pátápátá.

13Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá ṣẹ́kù lórí ilẹ̀ náà,

yóò sì tún pàpà padà di rírun.

Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí igi tẹrẹbinti àti igi óákù,

ti í fi kùkùté sílẹ̀ nígbà tí a bá gé wọn lulẹ̀,

bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni irúgbìn mímọ́ náà yóò di kùkùté ní ilẹ̀ náà.”