ኢሳይያስ 42 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ኢሳይያስ 42:1-25

የእግዚአብሔር አገልጋይ

1“ደግፌ የያዝሁት አገልጋዬ፣

በእርሱም ደስ የሚለኝ ምርጤ ይህ ነው፤

መንፈሴን በእርሱ ላይ አደርጋለሁ፤

ለአሕዛብም ፍትሕን ያመጣል።

2አይጮኽም፣ ቃሉን ከፍ አያደርግም፤

ድምፁን በመንገድ ላይ በኀይል አያሰማም።

3የተቀጠቀጠ ሸምበቆ አይሰብርም፤

የሚጤስም የጧፍ ክር አያጠፋም፤

ፍትሕን በታማኝነት ያመጣል።

4ፍትሕን በምድር እስኪያመጣ ድረስ፣

አይደክምም፤ ተስፋም አይቈርጥም፤

ደሴቶች በሕጉ ይታመናሉ።”

5ሰማያትን የፈጠረ፣ የዘረጋቸውም፣

ምድርንና በውስጧ ያሉትን ሁሉ ያበጀ፣

ለሕዝቧ እስትንፋስን፣

ለሚኖሩባትም ሕይወትን የሚሰጥ፣

ጌታ እግዚአብሔር እንዲህ ይላል፤

6“እኔ እግዚአብሔር በጽድቅ ጠርቼሃለሁ፤

እጅህንም እይዛለሁ፤

እጠብቅሃለሁ፤

ለሕዝቡ ቃል ኪዳን፣

ለአሕዛብም ብርሃን አደርግሃለሁ።

7የዕውሮችን ዐይን ትከፍታለህ፤

ምርኮኞችን ከእስር ቤት፣

በጨለማ የተቀመጡትንም ከወህኒ ታወጣለህ።

8“እኔ እግዚአብሔር ነኝ፤ ስሜም ይህ ነው፤

ክብሬን ለሌላ፣

ምስጋናዬንም ለጣዖት አልሰጥም።

9እነሆ፤ የቀድሞው ነገር ተፈጽሟል፤

እኔም አዲስ ነገር እናገራለሁ፤

ከመብቀሉም በፊት፣

ለእናንተ አስታውቃለሁ።”

ለእግዚአብሔር የውዳሴ መዝሙር

10እናንት ወደ ባሕር የምትወርዱ፣ በዚያም ያላችሁ ሁሉ፣

ደሴቶችና በዚያ የምትኖሩ በሙሉ፣

ለእግዚአብሔር አዲስ መዝሙር፣

ከምድር ዳርቻም ምስጋናውን ዘምሩ።

11ምድረ በዳውና ከተሞቹ ድምፃቸውን ከፍ ያድርጉ፤

ቄዳር ያለችበት መንደር ደስ ይበለው፤

የሴላ ሕዝቦች በደስታ ይዘምሩ፤

ከተራሮችም ራስ ላይ ይጩኹ።

12ክብር ለእግዚአብሔር ይስጡ፤

ምስጋናውንም በደሴቶች ያውጁ።

13እግዚአብሔር እንደ ኀያል ሰው ይዘምታል፤

እንደ ተዋጊ በወኔ ይነሣል፤

የቀረርቶ ጩኸት ያሰማል፤

ጠላቶቹንም ድል ያደርጋል።

14“ለረዥም ጊዜ ዝም አልሁ፤

ጸጥ አልሁ፤ ራሴንም ገታሁ፤

አሁን ግን ምጥ እንደ ያዛት ሴት፣

እጮኻለሁ፤ ቍና ቍና እቃትታለሁ፤ እተነፍሳለሁ።

15ተራራውንና ኰረብታውን አፈርሳለሁ፤

ዕፀዋቱን ሁሉ አደርቃለሁ፤

ወንዙንም ደሴት አደርጋለሁ፤

ኵሬውን አደርቃለሁ።

16ዕውሮችን በማያወቁት መንገድ

እመራቸዋለሁ፤

ባልተለመደ ጐዳና እወስዳቸዋለሁ።

ጨለማውን በፊታቸው ብርሃን አደርጋለሁ፤

ጐርባጣውን ስፍራ አስተካክላለሁ።

ይህን አደርጋለሁ፤

አልተዋቸውም።

17በጣዖት የሚታመኑ ግን፣

ምስሎችን፣ ‘አምላኮቻችን ናችሁ’ የሚሉ፣

ወደ ኋላቸው ይመለሳሉ፤ ፈጽመው ይዋረዳሉም።

ዕውሯና ደንቈሮዋ እስራኤል

18“እናንት ደንቈሮዎች ስሙ፤

እናንት ዕውሮች እዩ፤ ተመልከቱም።

19አገልጋዬ እንጂ፣ ሌላ ዕውር ማን አለ?

ከምልከው መልእክተኛዬስ በቀር ማን ደንቈሮ አለ?

ለእኔ ታማኝ እንደ ሆነ ሰው የታወረ፣

እንደ እግዚአብሔርስ አገልጋይ ዕውር ማነው?

20ብዙ ነገርን አያችሁ፤ ነገር ግን አላስተዋላችሁም፤

ጆሯችሁ ክፍት ነው፤ ነገር ግን ምንም አትሰሙም።”

21እግዚአብሔር ስለ ጽድቁ ሲል፣

ሕጉን ታላቅና የተከበረ በማድረግ ደስ

አለው።

22ይህ ሕዝብ ግን የተበዘበዘና የተዘረፈ፣

በጕድጓድ ውስጥ የተጠመደበት፣

በወህኒ ቤት የተዘጋበት ነው፤

ተበዝብዘዋል፣

የሚያድናቸውም የለም፤

ተማርከዋል፣

“መልሷቸው” የሚልም የለም።

23ከእናንተ ይህን የሚሰማ፣

ለሚመጣውም ጊዜ አስተውሎ የሚያደምጥ ማነው?

24ያዕቆብን ለዝርፊያ፣

እስራኤልን ለምርኮ የዳረገ ማነው?

በኀጢአት የበደልነው፣

እግዚአብሔር አይደለምን?

መንገዱን ለመከተል፣

ለሕጉም መታዘዝ አልፈለጉምና።

25ስለዚህ የሚነድድ ቍጣውን፣

የጦርነትንም መዓት አፈሰሰባቸው፤

በእሳት ነበልባል ከበባቸው፤ እነርሱ ግን አላስተዋሉም፤

አቃጠላቸው፤ እነርሱ ግን ልብ አላሉም።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 42:1-25

Ìránṣẹ́ Olúwa náà

142.1-4: Mt 12.18-21.“Ìránṣẹ́ mi nìyìí, ẹni tí mo gbéró,

àyànfẹ́ mi nínú ẹni tí mo láyọ̀;

Èmi yóò fi Ẹ̀mí mi sínú rẹ̀

òun yóò sì mú ìdájọ́ wá sórí àwọn orílẹ̀-èdè.

2Òun kì yóò pariwo tàbí kígbe sókè,

tàbí kí ó gbóhùn rẹ̀ sókè ní òpópónà.

3Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́,

àti òwú-fìtílà tí ń jó tan an lọ lòun kì yóò fẹ́ pa.

Ní òdodo ni yóò mú ìdájọ́ wá;

4òun kì yóò kọsẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sì

títí tí yóò fi fi ìdájọ́ múlẹ̀ ní ayé.

Nínú òfin rẹ̀ ni àwọn erékùṣù yóò fi ìrètí wọn sí.”

542.5: Ap 17.24-25.Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí

Ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n sóde,

tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú wọn,

Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémí

àti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú rẹ̀:

642.6: Isa 49.6; Lk 2.32; Ap 13.47; 26.23.“Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo;

Èmi yóò di ọwọ́ rẹ mú.

Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́

láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn

àti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà

742.7,16: Ap 26.18.láti la àwọn ojú tí ó fọ́,

láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbú

àti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n

àwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.

8“Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí!

Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn

tàbí ìyìn mi fún ère òrìṣà.

9Kíyèsi i, àwọn nǹkan àtijọ́ ti wáyé,

àti àwọn nǹkan tuntun ni mo ti wí pé;

kí wọn tó hù jáde

mo ti kéde rẹ̀ fún ọ.”

Orin ìyìn sí Olúwa

10Kọ orin tuntun sí Olúwa

ìyìn rẹ̀ láti òpin ilẹ̀ ayé wá,

ẹ̀yin tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú Òkun, àti

ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀

ẹ̀yin erékùṣù, àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú wọn.

11Jẹ́ kí aginjù àti àwọn ìlú rẹ̀ kí ó gbé ohùn wọn sókè;

jẹ́ kí ibùdó ti àwọn igi Kedari ń gbé máa yọ̀.

Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Sela kọrin fún ayọ̀;

jẹ́ kí wọn pariwo láti orí òkè.

12Jẹ́ kí wọn fi ògo fún Olúwa

àti kí wọn sì kéde ìyìn rẹ̀ ní erékùṣù.

13Olúwa yóò rìn jáde gẹ́gẹ́ bí i ọkùnrin alágbára,

yóò ru owú sókè bí ológun;

yóò kígbe nítòótọ́, òun yóò ké igbe ogun,

òun yóò sì ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá rẹ̀.

14“Fún ìgbà pípẹ́ ni mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́,

mo ti wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, mo sì kó ara ró.

Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí,

mo sọkún, mo sì ń mí hẹlẹ hẹlẹ.

15Èmi yóò sọ òkè ńlá àti kékeré di ahoro

tí n ó sì gbẹ gbogbo ewéko rẹ̀ dànù;

Èmi yóò sọ àwọn odò di erékùṣù

n ó sì gbẹ àwọn adágún.

16Èmi yóò tọ àwọn afọ́jú ní ọ̀nà tí wọn kò tí ì mọ̀,

ní ipa ọ̀nà tí ó ṣàjèjì sí wọn ni èmi yóò tọ́ wọn lọ;

Èmi yóò sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀ níwájú wọn

àti ibi pálapàla ni èmi ó sọ di kíkúnná.

Àwọn nǹkan tí máa ṣe nìyìí;

Èmi kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.

17Ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé òrìṣà,

tí wọ́n wí fún ère pé, ‘Ẹ̀yin ni Ọlọ́run wa,’

ni a ó dá padà pẹ̀lú ìtìjú.

Israẹli fọ́jú ó dití

18“Gbọ́, ìwọ adití,

wò ó, ìwọ afọ́jú, o sì rí!

19Ta ló fọ́jú bí kò ṣe ìránṣẹ́ mi,

àti odi gẹ́gẹ́ bí oníṣẹ́ tí mo rán?

Ta ni ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a fi jìnmí,

ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Olúwa?

20Ẹ̀yin ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan, ṣùgbọ́n ẹ kò ṣe àkíyèsí;

etí yín yà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́ nǹkan kan.”

21Ó dùn mọ́ Olúwa

nítorí òdodo rẹ̀

láti mú òfin rẹ lágbára àti ògo.

22Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn kan nìyìí tí a jà lógun

tí a sì kó lẹ́rú,

gbogbo wọn ni ó wà nínú ọ̀gbun,

tàbí tí a fi pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.

Wọ́n ti di ìkógun,

láìsí ẹnìkan tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀;

wọ́n ti di ìkógun,

láìsí ẹni tí yóò sọ pé, “Dá wọn padà.”

23Ta ni nínú yín tí yóò tẹ́tí sí èyí

tàbí kí ó ṣe àkíyèsí gidi ní àsìkò tí ó ń bọ̀?

24Ta ni ó fi Jakọbu lélẹ̀ fún ìkógun,

àti Israẹli sílẹ̀ fún onísùnmọ̀mí?

Kì í ha ṣe Olúwa ni,

ẹni tí àwa ti ṣẹ̀ sí?

Nítorí pé wọn kò ní tẹ̀lé ọ̀nà rẹ̀;

wọn kò mú òfin rẹ̀ ṣẹ.

25Nítorí náà ni ó ṣe rọ̀jò ìbínú un rẹ̀ lé wọn lórí,

rògbòdìyàn ogun.

Èyí tí ó fi ahọ́n iná yí wọn po, síbẹ̀

èdè kò yé wọn;

ó jó wọn run, síbẹ̀ wọn kò fi sọ́kàn wọn rárá.