ምሳሌ 18 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ምሳሌ 18:1-24

1ወዳጅነትን የማይፈልግ ሰው የራሱን ፍላጎት ብቻ ይከተላል፤

ቅን የሆነውንም ፍርድ ሁሉ ይቃወማል።

2ተላላ ከማስተዋል ርካታን አያገኝም፤

የራሱን ሐሳብ በመግለጥ ግን ደስ ይለዋል።

3ክፋት ስትመጣ ንቀት ትከተላለች፤

ከዕፍረትም ጋር ውርደት ትመጣለች።

4ከሰው አፍ የሚወጡ ቃላት ጥልቅ ውሆች ናቸው፤

የጥበብም ምንጭ እንደሚንዶለዶል ፏፏቴ ነው።

5ለክፉ ሰው ማድላት፣

ንጹሑንም ፍትሕ መንሣት ተገቢ አይደለም።

6የተላላ ከንፈር ጠብ ያመጣበታል፤

አፉም በትር ይጋብዛል።

7ተላላ ሰው አፉ መጥፊያው ነው፤

ከንፈሮቹም ለነፍሱ ወጥመድ ናቸው።

8የሐሜተኛ ቃል እንደ ጣፋጭ ጕርሻ ነው፤

ወደ ሰው ውስጣዊ ክፍል ዘልቆ ይገባል።

9ለሥራው ደንታ የሌለው ሰው፣

የአጥፊ ወንድም ነው።

10የእግዚአብሔር ስም ጽኑ ግንብ ነው፤

ጻድቅ ወደ እርሱ በመሮጥ ተገን ያገኝበታል።

11የባለጠጎች ሀብት የተመሸገ ከተማቸው ነው፤

እንደማይወጣ ረዥም ግንብም ይቈጥሩታል።

12ከውድቀቱ በፊት ሰው ልቡ ይታበያል፤

ትሕትና ግን ክብርን ትቀድማለች።

13ከማዳመጡ አስቀድሞ የሚመልስ፣

ቂልነትና ዕፍረት ይሆንበታል።

14በሕመም ጊዜ፣ ሰውን መንፈሱ ትደግፈዋለች፤

የተሰበረውን መንፈስ ግን ማን ሊሸከም ይችላል?

15የአስተዋይ ልብ ዕውቀትን ይገበያል፤

የጠቢብም ጆሮ አጥብቆ ይሻታል።

16እጅ መንሻ ለሰጪው መንገድ ትከፍትለታለች፤

ታላላቅ ሰዎች ፊትም ታቀርበዋለች።

17አስቀድሞ ጕዳዩን የሚያሰማ ትክክለኛ ይመስላል፤

ይኸውም ባላንጣው መጥቶ እስከሚመረመር ድረስ ነው።

18ዕጣ መጣጣል ሙግትን ያስቆማል፤

ኀይለኛ ባላንጣዎችንም ይገላግላል።

19የተበደለ ወንድም ከተመሸገ ከተማ ይበልጥ የማይበገር ነው፤

ጠቡም እንደ ጠንካራ የግንብ መዝጊያ ነው።

20ሰው በአንደበቱ ፍሬ ሆዱ ይጠግባል፤

በከንፈሩም ምርት ይረካል።

21አንደበት የሞትና የሕይወት ኀይል አላት፤

የሚወድዷትም ፍሬዋን ይበላሉ።

22ሚስት የሚያገኝ መልካም ነገርን ያገኛል፤

ከእግዚአብሔርም ዘንድ ሞገስን ይቀበላል።

23ድኻ በመለማመጥ ምሕረት ይለምናል፤

ሀብታም ግን በማናለብኝነት ይመልሳል።

24ወዳጅ የሚያበዛ ሰው ራሱን ለጥፋት ይዳርጋል፤

ነገር ግን ከወንድም አብልጦ የሚቀርብ ጓደኛም አለ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 18:1-24

1Ènìyàn tí kò ba ni rẹ́ a máa lépa ìmọ̀ ara rẹ̀;

ó kọjú ìjà sí gbogbo ìdájọ́ òdodo.

2Aláìgbọ́n kò rí inú dídùn sí òye

ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí sísọ èrò tirẹ̀.

3Nígbà ti ènìyàn búburú dé ni ẹ̀gàn dé,

nígbà ti ẹ̀gàn dé ni ìtìjú dé.

4Ọ̀rọ̀ ẹnu ènìyàn jẹ́ omi jíjìn,

ṣùgbọ́n orísun ọgbọ́n jẹ́ odò tí ń sàn.

5Kò dára kí ènìyàn ṣe ojúsàájú fún ènìyàn búburú

tàbí kí a fi ìdájọ́ òdodo du aláìṣẹ̀.

6Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀

ẹnu rẹ̀ sì ń ṣokùnfà ẹgba.

7Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́

ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹ̀kùn fún ọkàn rẹ̀.

8Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùn

wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.

9Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀

arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.

10Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni;

olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.

11Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọn

wọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.

12Ṣáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéraga

ṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.

13Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́,

èyí ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.

14Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsàn

ṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.

15Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀;

etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.

16Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùn

a sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.

17Ẹni tí ó kọ́kọ́ rọjọ́ máa ń dàbí i pé ó jàre

títí ẹlòmíràn yóò fi bọ́ síwájú kí ó sì tú àṣírí gbogbo.

18Ìbò dídì máa ń parí ìjà

a sì mú kí àwọn alátakò méjì jìnnà sí ara wọn.

19Arákùnrin tí a ṣẹ̀ sí ṣòro yípadà ju ìlú olódi lọ,

ìjà wọ sì dàbí ọ̀pá ìdábùú ààfin.

20Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ikùn ènìyàn a yó;

láti inú ìkórè ẹnu rẹ̀ ni ó ti jẹ yó.

21Ikú àti ìyè ń bẹ nípa ahọ́n wọn,

àwọn tí ó sì fẹ́ràn rẹ̀ yóò jẹ ẹ́.

22Ẹni tí ó rí aya fẹ́, rí ohun rere,

o sì gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa.

23Tálákà ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú,

ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ a dáhùn pẹ̀lú ìkanra.

24Ènìyàn tí ó ní ọ̀rẹ́ púpọ̀ le è parun

ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ kan wà tí ó súnmọ́ ni tímọ́tímọ́ ju arákùnrin.