ምሳሌ 13 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

ምሳሌ 13:1-25

1ጠቢብ ልጅ የአባቱን ምክር በማስተዋል ይሰማል፤

ፌዘኛ ግን ተግሣጽን አያዳምጥም።

2ሰው ከከንፈሩ ፍሬ መልካም ነገር ያገኛል፤

ወስላቶች ግን ዐመፅን ይናፍቃሉ።

3አንደበቱን የሚጠብቅ ሕይወቱን ይጠብቃል፤

አፉ እንዳመጣለት የሚናገር ግን ይጠፋል።

4ሰነፍ አጥብቆ ይመኛል፤ አንዳችም አያገኝም፤

የትጉሆች ምኞት ግን ይረካል።

5ጻድቅ ሐሰትን ይጠላል፤

ክፉ ሰው ግን ኀፍረትንና ውርደትን ያመጣል።

6ጽድቅ ቅን የሆነውን ሰው ትጠብቀዋለች፤

ክፋት ግን ኀጢአተኛውን ትጥለዋለች።

7ምንም ሳይኖረው ባለጠጋ መስሎ የሚታይ ሰው አለ፤

ሌላው ድኻ መስሎ ይታያል፤ ግን ብዙ ሀብት አለው።

8የሰው ሀብቱ ለሕይወቱ ቤዛ ሊሆነው ይችላል፤

ድኻው ግን ሥጋት የለበትም።

9የጻድቃን ብርሃን ደምቆ ይበራል፤

የክፉዎች መብራት ግን ይጠፋል።

10ትዕቢት ጠብን ብቻ ያስፋፋል፤

ጥበብ ግን ምክርን በሚቀበሉ ዘንድ ትገኛለች።

11ያላግባብ የተገኘ ገንዘብ እየተመናመነ ያልቃል፤

ገንዘቡን ጥቂት በጥቂት የሚያከማች ግን ይጠራቀምለታል።

12ለነገ የሚባል ተስፋ ልብን ያሳምማል፤

የተሳካ ምኞት ግን የሕይወት ዛፍ ነው።

13ምክርን የሚያቃልል በራሱ ላይ ጥፋት ያመጣል፤

ትእዛዝን የሚያከብር ግን ወሮታን ይቀበላል።

14የጠቢብ ትምህርት የሕይወት ምንጭ ናት፤

ሰውን በሞት ወጥመድ እንዳይያዝ ታደርገዋለች።

15መልካም ማስተዋል ሞገስን ታስገኛለች፤

የከዳተኞች መንገድ ግን አስቸጋሪ ነው።13፥15 ወይም የከዳተኞች መንገድ ግን አይጸናም

16አስተዋይ ሰው ሥራውን በዕውቀት ያከናውናል፤

ተላላ ግን ሞኝነቱን ይገልጣል።

17ክፉ መልእክተኛ መከራ ውስጥ ይገባል፤

ታማኝ መልእክተኛ ግን ፈውስን ያመጣል።

18ተግሣጽን የሚንቅ ወደ ድኽነትና ኀፍረት ይሄዳል፤

ዕርምትን የሚቀበል ሁሉ ግን ይከበራል።

19ምኞት ስትፈጸም ነፍስን ደስ ታሰኛለች፤

ተላሎች ግን ከክፋት መራቅን ይጸየፋሉ።

20ከጠቢብ ጋር የሚሄድ ጠቢብ ይሆናል፤

የተላሎች ባልንጀራ ግን ጕዳት ያገኘዋል።

21መጥፎ ዕድል ኀጢአተኛን ይከታተላል፤

ብልጽግና ግን የጻድቃን ዋጋ ነው።

22ደግ ሰው ለልጅ ልጆቹ ውርስ ትቶ ያልፋል፤

የኀጢአተኞች ሀብት ግን ለጻድቃን ይከማቻል።

23የድኾች ዕርሻ የተትረፈረፈ ምርት ያስገኛል፤

የፍትሕ መጓደል ግን ጠራርጎ ይወስደዋል።

24በአርጩሜ ከመቅጣት የሚሳሳለት ልጁን ይጠላል፤

የሚወድደው ግን በጥንቃቄ ይቀጣዋል።

25ጻድቅ እስኪጠግብ ድረስ ይበላል፤

የክፉዎች ሆድ ግን እንደ ተራበ ይኖራል።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Òwe 13:1-25

1Ọlọ́gbọ́n ọmọ gba ẹ̀kọ́ baba rẹ̀,

ṣùgbọ́n ẹlẹ́gàn kò gbọ́ ìbáwí.

2Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ènìyàn ń gbádùn ohun rere

ṣùgbọ́n, ìfẹ́ ọkàn aláìṣòótọ́ ní ìwà ipá.

3Ẹnikẹ́ni tí ó ṣọ́ ẹnu rẹ̀ pa ẹnu ara rẹ̀ mọ́,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ gbàù gbàù yóò parun.

4Ọkàn ọ̀lẹ ń fẹ́, ṣùgbọ́n kò rí nǹkan kan,

ṣùgbọ́n ọkàn àwọn ti kì í ṣe ọ̀lẹ rí ìtẹ́lọ́rùn.

5Olódodo kórìíra ohun tí í ṣe irọ́

Ṣùgbọ́n ènìyàn búburú hu ìwà ìríra àti ìtìjú.

6Òdodo ń ṣamọ̀nà ènìyàn olóòtítọ́ inú,

ṣùgbọ́n ìwà búburú ṣí ẹlẹ́ṣẹ̀ ní ipò.

7Ènìyàn kan díbọ́n bí ẹni tí ó ní ọrọ̀ síbẹ̀ kò ní nǹkan kan

ẹlòmíràn díbọ́n bí i tálákà, síbẹ̀ ó ní ọrọ̀ púpọ̀.

8Ọrọ̀ ènìyàn le è ra ẹ̀mí rẹ̀

ṣùgbọ́n tálákà kì í gbọ́ ìdẹ́rùbà.

9Ìmọ́lẹ̀ olódodo tàn roro,

ṣùgbọ́n fìtílà ènìyàn búburú ni a pa kú.

10Ìgbéraga máa ń dá ìjà sílẹ̀ ni

ṣùgbọ́n ọgbọ́n wà nínú àwọn tí ń gba ìmọ̀ràn.

11Owó tí a fi ọ̀nà èrú kójọ yóò ṣí lọ,

ṣùgbọ́n ẹni tí ń kó owó jọ díẹ̀díẹ̀ yóò pọ̀ sí i.

12Ìrètí tí ń falẹ̀ máa ń mú kí ọkàn ṣàárẹ̀

ṣùgbọ́n ìrètí tí a rí gbà jẹ́ igi ìyè.

13Ẹni tí ó kẹ́gàn ẹ̀kọ́ yóò jìyà rẹ̀

ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa àṣẹ mọ́ gba èrè rẹ̀.

14Ìkọ́ni ọlọ́gbọ́n jẹ́ orísun ìyè,

tí ń yí ènìyàn padà kúrò nínú ìdẹ̀kùn ikú.

15Òye pípé ń mú ni rí ojúrere

Ṣùgbọ́n ọ̀nà aláìṣòótọ́ kì í tọ́jọ́.

16Gbogbo olóye ènìyàn máa ń hùwà pẹ̀lú ìmọ̀

Ṣùgbọ́n aláìgbọ́n a fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.

17Ìránṣẹ́ búburú bọ́ sínú ìdààmú

ṣùgbọ́n aṣojú olóòtítọ́ mú ìwòsàn wá.

18Ẹni tí ó kọ ìbáwí yóò di tálákà yóò sì rí ìtìjú,

ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí ni yóò rí ọlá.

19Ìfẹ́ tí a mú ṣẹ dùn mọ́ ọkàn

ṣùgbọ́n ìríra ni fún aṣiwèrè láti kúrò nínú ibi.

20Ẹni tí ó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́n

ṣùgbọ́n ẹni tí ń bá aláìgbọ́n kẹ́gbẹ́ ń pa ara rẹ̀ lára.

21Òsì a máa ta ẹlẹ́ṣẹ̀,

ṣùgbọ́n ọrọ̀ ni èrè fún olódodo.

22Ènìyàn rere a máa fi ogún sílẹ̀ fún àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀,

ṣùgbọ́n, a kó ọrọ̀ àwọn tó dẹ́ṣẹ̀ pamọ́ fún àwọn olódodo.

23Ilẹ̀ ẹ tálákà le è mú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìre oko wá

ṣùgbọ́n àìṣòdodo gbá gbogbo rẹ̀ lọ.

24Ẹni tí ó fa ọwọ́ ìbáwí sẹ́yìn kórìíra ọmọ rẹ̀

ṣùgbọ́n ẹni tí ó fẹ́ràn ọmọ rẹ̀ yóò máa bá a wí.

25Olódodo jẹ́wọ́ títí ó fi tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn

ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ikùn ènìyàn búburú.