መዝሙር 5 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 5:1-12

መዝሙር 5

የጧት ጸሎት

ለመዘምራን አለቃ፤ በዋሽንት የሚዘመር፣ የዳዊት መዝሙር።

1እግዚአብሔር ሆይ፤ ቃሌን አድምጥ፤

መቃተቴንም ቸል አትበል።

2ንጉሤና አምላኬ ሆይ፤

ወደ አንተ እጸልያለሁና፣

ድረስልኝ ብዬ ስጮኽ ስማኝ።

3እግዚአብሔር ሆይ፤ በማለዳ ድምፄን ትሰማለህ፤

በማለዳ ልመናዬን በፊትህ አቀርባለሁ፤

ፈቃድህንም በጥሞና እጠባበቃለሁ፤

4አንተ በክፋት ደስ የምትሰኝ አምላክ አይደለህም፤

ክፉም ከአንተ ጋር አያድርም።

5እብሪተኞች በፊትህ መቆም አይችሉም፤

ክፉ አድራጊዎችንም ሁሉ ጠላህ።

6ሐሰት የሚናገሩትን ታጠፋቸዋለህ፤

ደም የተጠሙትንና አታላዮችን፣

እግዚአብሔር ይጸየፋቸዋል።

7እኔ ግን በምሕረትህ ብዛት

ወደ ቤትህ እገባለሁ፤

አንተንም በመፍራት፣

ወደ ተቀደሰው መቅደስህ እሰግዳለሁ።

8እግዚአብሔር ሆይ፤ ከጠላቶቼ የተነሣ፣

በጽድቅህ ምራኝ፤

መንገድህንም በፊቴ አቅናልኝ።

9በንግግራቸው ውስጥ እውነት የለም፤

ልባቸው የጥፋት ጐሬ ነው፤

ጕረሯቸው የተከፈተ መቃብር ነው፤

በምላሳቸውም ይሸነግላሉ።

10አምላክ ሆይ፤ የእጃቸውን ስጣቸው!

ተንኰላቸው መውደቂያቸው ይሁን፤

ከኀጢአታቸው ብዛት የተነሣ አስወግዳቸው፣

በአንተ ላይ ዐምፀዋልና።

11አንተን መጠጊያ የሚያደርጉ ሁሉ ግን ደስ ይበላቸው፤

ዘላለም በደስታ ይዘምሩ፤

ስምህን የሚወድዱ በአንተ ደስ እንዲላቸው፣

ተከላካይ ሁንላቸው።

12እግዚአብሔር ሆይ፤ አንተ ጻድቃንን ትባርካቸዋለህ፤

በሞገስህም እንደ ጋሻ ትከልላቸዋለህ።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 5:1-12

Saamu 5

Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin fífọn. Saamu ti Dafidi.

1Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, Olúwa,

kíyèsi àròyé mi.

2Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́,

ọba mi àti Ọlọ́run mi,

nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.

3Ní òwúrọ̀, Olúwa, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi;

ní òwúrọ̀, èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú rẹ̀

èmi yóò sì dúró ní ìrètí.

4Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú;

bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.

5Àwọn agbéraga kò le è dúró

níwájú rẹ̀.

Ìwọ kórìíra gbogbo àwọn aṣebi;

6ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run.

Apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyàn

ni Olúwa yóò kórìíra.

7Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú rẹ̀,

èmi yóò wá sínú ilé rẹ̀;

ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríba

sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀.

8Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo rẹ,

nítorí àwọn ọ̀tá mi,

mú ọ̀nà rẹ tọ́ níwájú mi.

95.9: Ro 3.13.Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́;

ọkàn wọn kún fún ìparun.

Ọ̀nà ọ̀fun wọn ni isà òkú tí ó ṣí sílẹ̀;

pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.

10Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run!

Jẹ́ kí rìkíṣí wọn jẹ́ ìṣubú wọn.

Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn,

nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.

11Ṣùgbọ́n, jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀;

jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí.

Tan ààbò rẹ sórí wọn,

àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ yóò máa yọ̀ nínú rẹ.

12Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo;

ìwọ fi ojúrere rẹ yí wọn ká bí asà.