መዝሙር 104 – NASV & YCB

New Amharic Standard Version

መዝሙር 104:1-35

መዝሙር 104

የፍጥረት መብት

1ነፍሴ ሆይ፤ እግዚአብሔርን ባርኪ፤

እግዚአብሔር አምላኬ ሆይ፤ አንተ እጅግ ታላቅ ነህ፤

ክብርንና ግርማን ለብሰሃል።

2ብርሃንን እንደ ሸማ ተጐናጽፈሃል፤

ሰማያትንም እንደ ድንኳን መጋረጃ ዘረጋህ፤

3የእልፍኝህን አግዳሚ በውሆች ላይ አኖርህ፤

ደመናትን ሠረገላህ አደረግህ፤

በነፋስ ክንፍ ትሄዳለህ።

4መላእክትህን104፥4 መልእክተኞቹን ወይም አገልጋዮቹን መንፈስ፣

አገልጋዮችህንም የእሳት ነበልባል ታደርጋለህ።

5ለዘላለም እንዳትናወጥ፣

ምድርን በመሠረቷ ላይ አጸናሃት።

6በጥልቁ እንደ ልብስ ሸፈንሃት፤

ውሆችም ከተራሮች በላይ ቆሙ።

7በገሠጽሃቸው ጊዜ ግን ፈጥነው ሄዱ፤

የነጐድጓድህንም ድምፅ በሰሙ ጊዜ ሸሹ።

8በተራሮች ላይ ፈሰሱ፤

ወዳዘጋጀህላቸው ስፍራ፣

ወደ ሸለቆዎች ወረዱ።

9ተመልሰው ምድርን እንዳይሸፍኑ፣

ዐልፈውም እንዳይመጡ ድንበር አበጀህላቸው።

10ምንጮችን በሸለቆ ውስጥ እንዲሄዱ አደረግህ፤

በተራሮችም መካከል ይፈስሳሉ፤

11የዱር እንስሳትም ከዚያ ይጠጣሉ፤

የሜዳ አህዮችም ጥማቸውን ይቈርጣሉ።

12የሰማይ ወፎች ጎጇቸውን በወንዞቹ ዳር ይሠራሉ፤

በቅርንጫፎችም መካከል ይዘምራሉ።

13ከላይ ከእልፍኝህ ተራሮችህን ታጠጣለህ፤

ምድርም በሥራህ ፍሬ ትረካለች።

14ከምድር ምግብን ታወጣ ዘንድ፣

ለእንስሳት ሣርን፣

ለሰው ልጆች ሥራ ዕፀዋትን ታበቅላለህ፤

15የሰውን ልብ ደስ የሚያሰኝ ወይን፣

ፊቱን የሚያወዛ ዘይት፣

ልቡን የሚያበረታ እህል በዚህ ይገኛል።

16ደግሞም የእግዚአብሔር ዛፎች፣

እርሱ የተከላቸውም የሊባኖስ ዝግባዎች ጠጥተው ይረካሉ፤

17ወፎች ጎጇቸውን በዚያ ይሠራሉ፤

ሽመላ በጥዶቹ ውስጥ ማደሪያ ታገኛለች።

18ረጃጅሙ ተራራ የዋሊያ መኖሪያ፣

የዐለቱም ዋሻዎች የሽኮኮ መሸሸጊያ ናቸው።

19ጨረቃን የወቅቶች መለያ አደረግሃት፤

ፀሓይም የምትጠልቅበትን ጊዜ ታውቃለች።

20ጨለማን ታመጣለህ፤ ሌሊትም ይሆናል፤

የዱር አራዊትም ሁሉ በዚህ ጊዜ ወጥተው ይራወጣሉ።

21የአንበሳ ግልገሎች ምግብ ፍለጋ ይጮኻሉ፤

የሚበሉትንም ከእግዚአብሔር ይሻሉ።

22ፀሓይ በወጣች ጊዜም ይመለሳሉ፤

በየጐሬያቸውም ገብተው ይተኛሉ።

23ሰውም ወደ ሥራው ይሄዳል፤

እስኪመሽም በተግባሩ ላይ ይሰማራል።

24እግዚአብሔር ሆይ፤ ሥራህ እንዴት ብዙ ነው!

ሁሉን በጥበብ ሠራህ፤

ምድርም በፍጥረትህ ተሞላች።

25ይህች ባሕር ሰፊና የተንጣለለች ናት፤

ታላላቅና ታናናሽ እንስሳት፣

ስፍር ቍጥር የሌላቸውም ነፍሳት በውስጧ አሉ።

26መርከቦች በላይዋ ይመላለሳሉ፤

አንተ የፈጠርኸውም ሌዋታን በውስጧ ይፈነጫል።

27ምግባቸውን በወቅቱ ትሰጣቸው ዘንድ፣

እነዚህ ሁሉ አንተን ተስፋ ያደርጋሉ።

28በሰጠሃቸውም ጊዜ፣

አንድ ላይ ያከማቻሉ፤

እጅህንም ስትዘረጋ፣

በመልካም ነገር ይጠግባሉ።

29ፊትህን ስትሰውር፣

በድንጋጤ ይሞላሉ፤

እስትንፋሳቸውንም ስትወስድባቸው ይሞታሉ፤

ወደ ዐፈራቸውም ይመለሳሉ።

30መንፈስህን ስትልክ፣

እነርሱ ይፈጠራሉ፤

የምድርንም ገጽ ታድሳለህ።

31የእግዚአብሔር ክብር ለዘላለም ጸንቶ ይኑር፤

እግዚአብሔር በሥራው ደስ ይበለው፤

32እርሱ ምድርን ሲመለከት፣ ትንቀጠቀጣለች፤

ተራሮችም እርሱ ሲዳስሳቸው ይጤሳሉ።

33በሕይወት ሳለሁ ለእግዚአብሔር እዘምራለሁ፤

ቆሜ እስከ ሄድሁ ድረስም አምላኬን እወድሳለሁ።

34እኔ በእግዚአብሔር ደስ እንደሚለኝ፣

የልቤ ሐሳብ እርሱን ደስ ያሰኘው።

35ኀጥኣን ከምድር ገጽ ይጥፉ፤

ዐመፀኞች ከእንግዲህ አይገኙ።

ነፍሴ ሆይ፤ እግዚአብሔርን ባርኪ፤

ሃሌ ሉያ።104፥35 እግዚአብሔር ይመስገን የሚሉ ትርጕሞች አሉ፤ በሰብዓ ሊቃናት ትርጕም ይህ መሥመር በመዝ 105 መጀመሪያ ላይ ይገኛል።

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 104:1-35

Saamu 104

1Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ tóbi jọjọ;

ọlá àti ọláńlá ni ìwọ wọ̀ ní aṣọ.

2Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ;

ó tẹ ọ̀run bí títẹ́ ẹní

3Ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ.

Ìwọ tí o ṣe àwọsánmọ̀ ní kẹ̀kẹ́ ogun rẹ

ìwọ tí ó ń rìn lórí apá ìyẹ́ afẹ́fẹ́.

4104.4: Hb 1.7.Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ,

Ọ̀wọ́-iná ni àwọn olùránṣẹ́ rẹ.

5O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀;

tí a kò le è mì láéláé.

6Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ;

àwọn omi sì dúró lórí àwọn òkè ńlá.

7Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ,

nípa ohùn àrá rẹ ni wọ́n sálọ;

8Wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè,

wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀,

sí ibi tí ìwọ ti yàn fún wọn.

9Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀;

láéláé ni wọ́n kò ní lè bo ayé mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.

10Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn Àfonífojì;

tí ó ń sàn láàrín àwọn òkè.

11Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi

àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ń pa òǹgbẹ wọn.

12Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi

wọ́n ń kọrin láàrín àwọn ẹ̀ka.

13Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá;

a tẹ́ ayé lọ́rùn nípa èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

14Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ

àti àwọn ewébẹ̀ fún ènìyàn láti lò

kí ó lè mú oúnjẹ jáde láti ilẹ̀ wá:

15Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀,

òróró láti mú ojú rẹ̀ tan,

àti àkàrà láti ra ọkàn rẹ̀ padà.

16Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára,

kedari ti Lebanoni tí ó gbìn.

17Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn

bí ó ṣe tí àkọ̀ ni, orí igi gíga ni ilé rẹ̀.

18Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó;

àti àwọn àlàpà jẹ́ ààbò fún àwọn ehoro.

19Òṣùpá jẹ́ ààmì fún àkókò

oòrùn sì mọ ìgbà tí yóò wọ̀.

20Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru,

nínú èyí tí gbogbo ẹranko igbó ń rìn kiri.

21Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn

wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.

22Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ,

wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ihò wọn.

23Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,

àti sí làálàá rẹ̀ títí di àṣálẹ́.

24Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa!

Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn:

ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá á rẹ.

25Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú,

tí ó kún fún àwọn ẹ̀dá alààyè ní ìsàlẹ̀ láìníye

ohun alààyè tí tóbi àti kékeré.

26Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn,

àti Lefitani, tí ìwọ dá láti ṣe àríyá nínú rẹ̀.

27Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́

láti fún wọn ní oúnjẹ wọn lákòókò rẹ̀.

28Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn,

wọn yóò kó jọ;

nígbà tí ìwọ bá la ọwọ́ rẹ̀,

a tẹ́ wọn lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere.

29Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́

ara kò rọ̀ wọ́n

nígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ,

wọn ó kú, wọn ó sì padà sí erùpẹ̀.

30Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ,

ni a dá wọn,

ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.

31Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé;

kí inú Olúwa kí ó dùn ní ti iṣẹ́ rẹ̀

32Ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì,

ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.

33Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa:

èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa

níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè.

34Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn

bí mo ti ń yọ̀ nínú Olúwa.

35Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé

kí ènìyàn búburú má sì sí mọ́.

Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Yin Olúwa.