시편 79 – KLB & YCB

Korean Living Bible

시편 79:1-13

나라의 구원을 위한 기도

(아삽의 시)

1하나님이시여,

이방 나라들이

주의 땅을 침범하여

주의 성전을 더럽히고

예루살렘을 폐허로 만들었습니다.

2그들이 주의 종들의 시체를

공중의 새에게 밥으로 주고

주의 성도들의 육체를

땅의 짐승에게 주었으므로

3그 피가 예루살렘 주변에

물같이 흘렀으나

죽은 자를 매장할 자가 없었습니다.

4우리 인접 국가들이

우리를 비웃고 모욕하며

우리를 조롱하고 있습니다.

5여호와여, 언제까지

우리에게 노하시겠습니까?

영원히 노하실 작정이십니까?

언제까지 주의 분노가

불붙듯 하시겠습니까?

6주를 인정하지 않는 나라와

주의 이름을 부르지 않는 나라에

주의 분노를 쏟으소서.

7그들이 주의 백성을 죽이고

그 땅을 폐허로 만들었습니다.

8우리 조상들의 죄로 인해

우리를 벌하지 마소서.

우리가 아주 비참하게 되었습니다.

우리를 불쌍히 여기시고

우리를 영접하소서.

9우리 구원의 하나님이시여,

주의 이름의 영광을 위하여

우리를 도우시며 우리를 구하시고

우리 죄를 용서하소서.

10어째서 이방 나라들이

“너희 하나님이 어디 있느냐?”

하고 말하게 하십니까?

주의 백성의

피를 흘리게 한 자들에게

주는 보복하신다는 사실을

우리가 보는 데서

온 세상에 알리소서.

11갇힌 자들과 죽게 된 자들이

신음하는 소리를 들으시고

주의 크신 능력으로

그들을 구하소서.

12여호와여, 주를 비웃고 모욕한

우리 인접 국가들에게

칠 배나 갚으소서.

13그러면 주의 백성이며

주의 양떼인 우리가

영원히 주께 감사하며

대대로 주를 찬양하겠습니다.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 79:1-13

Saamu 79

Saamu ti Asafu.

1Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ;

wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́,

wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.

2Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ

fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ,

ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.

3Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi

yí Jerusalẹmu ká,

kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.

4Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká,

àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.

5Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé?

Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?

6Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè

tí kò ní ìmọ̀ rẹ,

lórí àwọn ìjọba

tí kò pe orúkọ rẹ;

7Nítorí wọ́n ti run Jakọbu

wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.

8Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn

jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa,

nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.

9Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa,

fún ògo orúkọ rẹ;

gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì

nítorí orúkọ rẹ.

10Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé,

“Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?”

Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè

kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.

11Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ,

gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ

ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.

12San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje

nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.

13Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ,

àti àgùntàn pápá rẹ,

yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé;

láti ìran dé ìran

ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.