詩篇 33 – JCB & YCB

Japanese Contemporary Bible

詩篇 33:1-22

33

1神を敬う人々の喜びが、

賛美の声となってわき上がりますように。

主をほめたたえるのは良いことです。

2竪琴と十弦の琴で、

喜びにあふれる賛美の調べをかなでなさい。

3新しい賛美歌を作り、巧みにハープをかき鳴らして、

喜びの歌を歌いなさい。

4主のことばには偽りがなく、

その行為にも裏切りは決してありません。

5主はすべて正しいこと、良いことを愛しておられ、

地上はその優しい愛で潤っています。

6あの星をちりばめた天空も、

主のおことばひとつで造られました。

7神様は海を造り、水を注がれました。

8全世界の人は、老いも若きも、男も女も、

恐れかしこみながら主の前に立ちなさい。

9主のおことばで、この世界は始まったからです。

10主はひと息で、反抗的な国々の策略を吹き消されます。

11主の計画はいつまでも不滅で、

主のお考えはいつの時代にも揺るぎません。

12主を信じる民は幸せです。

主から選ばれた民だからです。

13-15人の心を造られた主は、

天の住まいから全人類を見下ろし、

一人一人の行動をつぶさに眺めておられます。

16-17最強の軍備を誇る軍隊でも、

王を救えるわけではありません。

力だけでは、誰ひとり救うことはできません。

勇ましい軍馬も、勝利を保証してはくれません。

力が救いとはならないのです。

18-19しかし主の目線は、主を信じて従い、

その変わらない愛に頼る者に注がれます。

ききんのときにも、餓死することはありません。

20頼ることができるのは主おひとりです。

主が盾となって守ってくださいます。

21主に信頼する私たちに、喜びがあふれます。

22主よ、尽きることのない愛で包んでください。

あなただけが望みなのです。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 33:1-22

Saamu 33

1Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo

ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.

2Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù;

ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.

3Ẹ kọ orin tuntun sí i;

ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.

4Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin,

gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.

5Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́;

ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.

6Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run,

àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.

7Ó kó àwọn omi Òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò;

ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.

8Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa:

jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.

9Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ

ó sì dúró ṣinṣin.

10Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán;

ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.

11Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé,

àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.

12Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀,

àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.

13Olúwa wò láti ọ̀run wá;

Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.

14Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́

Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé

15ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà,

ó sì kíyèsi ìṣe wọn.

16A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun;

kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.

17Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun;

bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.

18Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.

19Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú

àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.

20Ọkàn wa dúró de Olúwa;

òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.

21Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀,

nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.

22Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa,

àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.