Yesaya 66 – CCL & YCB

Mawu a Mulungu mu Chichewa Chalero

Yesaya 66:1-24

Chiweruzo ndi Chiyembekezo

1Yehova akuti,

“Kumwamba ndi mpando wanga waufumu

ndipo dziko lapansi ndilo chopondapo mapazi anga.

Tsono nyumba ili kuti yomwe mundimangire,

ndipo malo ali kuti amene inu mungandikonzere kuti ndizipumuliramo?

2Kodi si manja anga amene anapanga zinthu zonsezi,

motero zonsezi ndi zanga?”

Akutero Yehova.

“Koma munthu amene ndimakondwera naye ndi uyu:

amene ali wodzichepetsa ndi wosweka mtima,

ndipo amamvera mawu anga.

3Koma aliyense amene amapereka nsembe ngʼombe yayimuna

amaphanso munthu,

ndipo aliyense amene amapereka mwana wankhosa,

amaphanso galu.

Aliyense amene amapereka nsembe chopereka cha chakudya

amaperekanso magazi a nkhumba.

Ndipo amene amafukiza lubani pa guwa lansembe la chikumbutso

amapembedzanso fano.

Popeza iwo asankha njira zawozawo,

ndiponso kusangalatsidwa ndi zonyansa zawo.

4Inenso ndawasankhira chilango chowawa

ndipo ndidzabweretsa pa iwo zimene amaziopa zija.

Pakuti pamene ndinawayitana palibe amene anayankha,

pamene ndinayankhula palibe amene anatchera khutu.

Anachita zoyipa pamaso panga

ndi kusankha kuchita zimene zimandinyansa zija.”

5Imvani mawu a Yehova,

inu amene mumanjenjemera ndi mawu ake:

“Abale anu amene amakudani,

ndi kukuchotsani pakati pawo chifukwa cha dzina langa, amanena kuti,

‘Yehova alemekezeke

kuti ife tione chimwemwe chanu!’

Koma ndi iwowo amene adzachite manyazi.

6Imvani mfuwu mu mzinda,

imvani phokoso mʼNyumba ya Mulungu!

Limenelo ndi liwu la Yehova,

kulanga adani ake onse.

7“Mzinda uli ngati amayi apakati amene asanayambe kumva zowawa

wachira kale;

asanayambe kumva ululu,

wabala kale mwana wamwamuna.

8Ndani anamvapo zinthu zoterezi?

Ndani anazionapo zinthu zoterezi?

Kodi dziko nʼkupangika tsiku limodzi,

kapena mtundu wa anthu nʼkubadwa tsiku limodzi?

Komatu Ziyoni atangoyamba kumva zowawa

nthawi yomweyo anabereka ana ake.

9Kodi Ine ndingangofikitsa amayi apakati mpaka nthawi yake yochira,

koma osalola kuti abaledi mwana?” akutero Yehova.

“Kodi ndingatseke mimba

pa nthawi yoti abeleke?” akutero Mulungu wako.

10“Kondwera nayeni Yerusalemu ndipo musangalale chifukwa cha Iye,

inu nonse amene mumakonda Yerusalemu,

kondwera nayeni kwambiri,

nonse amene mumamulira.

11Pakuti mudzagawana naye ulemerero wake

ngati kuyamwa ndi kukhuta mkaka wambiri

wa mʼmawere

a chitonthozo chake.”

12Yehova akuti,

“Ndidzamupatsa mtendere ngati mtsinje wa madzi,

ndiponso chuma cha anthu a mitundu ina ngati mtsinje wosefukira.

Mudzakhala ngati mwana woyamwa amene amayi ake amunyamulira pambalipa,

kapena kumufungata pa miyendo yake.

13Monga momwe amayi amasangalatsira mwana wawo,

moteronso Ine ndidzakusangalatsani;

ndipo mudzasangalala chifukwa cha Yerusalemu.”

14Mukadzaona zimenezi mitima yanu idzakondwera. Mudzabiriwira ngati udzu.

Zimenezi zidzakulimbikitsani ndi kukupatsani moyo wamphamvu.

Mudzadziwa kuti ndimathandiza amene amanditumikira

ndi kuti ndimakwiyira adani anga.

15Taonani, Yehova akubwera ngati moto,

ndipo magaleta ake ali ngati kamvuluvulu;

Iye adzaonetsa mkwiyo wake nadzalanga adani ake

ndi malawi amoto.

16Pakuti Yehova adzalanga anthu onse

ndi moto ndi lupanga,

Yehova adzapha anthu ambiri.

17Yehova akuti, “Amene amadzipatula ndi kudziyeretsa okha kuti apite ku minda, ali ndi mtsogoleri awo, nʼkumadya nyama ya nkhumba, mbewa ndi zinthu zina zonyansa, onsewa adzafera limodzi.”

18“Ndipo Ine, chifukwa cha zochita zawo ndi maganizo awo, ndili pafupi kubwera kudzasonkhanitsa mitundu yonse ya anthu ndi ziyankhulo zonse. Iwo adzabwera ndi kuona ulemerero wanga.

19“Ndidzayika chizindikiro pakati pawo, ndipo ndidzatumiza ena mwa iwowa amene anapulumuka kuti apite kwa anthu a mitundu ina inu ku Tarisisi, ku Libiya ndi ku Ludi (akatswiri a mauta) ku Tubala ndi Grisi, ndi ku mayiko akutali a mbali mwa nyanja amene sanamvepo za mbiri yanga kapena kuona ulemerero wanga. Iwo adzalalika za ulemerero wanga pakati pa anthu a mitundu ina. 20Ndipo adzabwera nawo abale anu onse ngati mphatso yopereka kwa Yehova kuchokera kwa anthu a mitundu yonse. Iwo adzakwera nawo kupita ku Yerusalemu, phiri langa loyera ku Yerusalemu monga nsembe kwa Yehova, atakwera akavalo, magaleta ndi ngolo, ndi pa abulu ndi ngamira,” akutero Yehova. “Adzabwera nawo ngati momwe Aisraeli amabwerera ndi zopereka zachakudya ku Nyumba ya Yehova mu ziwiya zoyeretsedwa monga mwa mwambo. 21Ndipo ndidzasankha ena mwa iwonso kukhala ansembe ndi Alevi,” akutero Yehova.

22“Monga momwe mlengalenga mwatsopano ndi dziko lapansi latsopano zimene ndidzapanga zidzakhala mpaka muyaya pamaso panga, ndi chonchonso dzina lanu ndi zidzukulu zanu zidzakhalire.” Akutero Yehova. 23“Anthu a mitundu yonse adzabwera kudzandipembedza ku Yerusalemu, pa chikondwerero chilichonse cha pokhala pa mwezi watsopano ndi tsiku la Sabata lililonse,” akutero Yehova. 24“Akamachoka adzaona mitembo ya anthu amene anandiwukira Ine. Mphutsi zawo sizidzafa, kapena moto wawo sudzazimitsidwa. Anthu a mitundu ina yonse powaona adzanyansidwa nawo.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Isaiah 66:1-24

Ìdájọ́ àti ìrètí

166.1-2: Mt 5.34; Ap 7.49-50.Báyìí ni Olúwa wí:

“Ọ̀run ni ìtẹ́ mi,

ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi,

Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà?

Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?

2Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí,

bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?”

ni Olúwa wí.

“Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí:

ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀,

tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.

3Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ

ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan

àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ,

dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn;

ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ

dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá,

ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí,

dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà.

Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n,

ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn;

4Fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn

n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn.

Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn,

nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀.

Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi

wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”

5Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,

Ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀:

“Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín,

tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé,

‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo,

kí a le rí ayọ̀ yín!’

Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.

666.6: If 16.1,17.Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá,

gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá!

Ariwo tí Olúwa ní í ṣe

tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun

tí ó tọ́ sí wọn.

766.7: If 12.5.“Kí ó tó lọ sí ìrọbí,

ó ti bímọ;

kí ó tó di pé ìrora dé bá a,

ó ti bí ọmọkùnrin.

8Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?

Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?

Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan

tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan?

Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí

bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.

9Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí

kí èmi má sì mú ni bí?”

ni Olúwa wí.

“Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ

nígbà tí mo ń mú ìbí wá?”

Ni Ọlọ́run yín wí.

10“Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i,

gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀;

ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀,

gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.

11Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn

nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára;

Ẹ̀yin yóò mu àmuyó

ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”

12Nítorí báyìí ni Olúwa wí:

“Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò

àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi;

ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀

a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.

13Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú,

bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú

a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”

14Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn

ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko;

ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,

ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.

15Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná

àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle;

òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú,

àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.

16Nítorí pẹ̀lú iná àti idà

ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn,

àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.

17“Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.

18“Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.

19“Èmi yóò sì gbé ààmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè. 20Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́. 21Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.

2266.22: Isa 65.17; 2Pt 3.13; If 21.1.“Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé. 23Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí. 2466.24: Mk 9.48.“Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”