Masalimo 30 – CCL & YCB

Mawu a Mulungu mu Chichewa Chalero

Masalimo 30:1-12

Salimo 30

Salimo la Davide. Nyimbo yoyimba popereka Nyumba ya Mulungu.

1Ndidzakukwezani Yehova,

chifukwa mwanditulutsa kwakuya,

ndipo simunalole kuti adani anga akondwere pa ine.

2Inu Yehova Mulungu wanga ndinapempha kwa Inu thandizo

ndipo Inu munandichiritsa.

3Inu Yehova, munanditulutsa ku manda,

munandisunga kuti ndisatsalire mʼdzenje.

4Imbirani Yehova inu anthu ake okhulupirika;

tamandani dzina lake loyera.

5Pakuti mkwiyo wake umakhala kwa kanthawi

koma kukoma mtima kwake ndi kwa moyo wonse;

utha kuchezera kulira usiku wonse,

koma chimwemwe chimabwera mmawa.

6Pamene ndinaona kuti ndili otetezedwa ndinati,

“Sindidzagwedezekanso.”

7Inu Yehova, pamene munandikomera mtima,

munachititsa phiri langa kuyima chilili;

koma pamene munabisa nkhope yanu,

ndinataya mtima.

8Kwa Inu Yehova ndinayitana;

kwa Ambuye ndinapempha chifundo;

9“Kodi pali phindu lanji powonongeka kwanga

ngati nditsikira ku dzenje?

Kodi fumbi lidzakutamandani Inu?

Kodi lidzalengeza za kukhulupirika kwanu?

10Imvani Yehova ndipo mundichitire chifundo;

Yehova mukhale thandizo langa.”

11Inu munasandutsa kulira kwanga kukhala kuvina;

munachotsa chiguduli changa ndi kundiveka ndi chimwemwe,

12kuti mtima wanga uthe kuyimbira Inu usakhale chete.

Yehova Mulungu wanga, ndidzapereka kwa Inu mayamiko kwamuyaya.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 30:1-12

Saamu 30

Saamu. Orin. Fún ìyàsímímọ́ Tẹmpili. Ti Dafidi.

1Èmi yóò kókìkí i rẹ, Olúwa,

nítorí ìwọ ni ó gbé mi lékè

tí ìwọ kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ mí.

2Olúwa Ọlọ́run mi, èmi ké pè ọ́, fún ìrànlọ́wọ́

ìwọ sì ti wò mí sàn.

3Olúwa, ìwọ ti yọ ọkàn mi jáde kúrò nínú isà òkú,

mú mi padà bọ̀ sípò alààyè kí èmi má ba à lọ sínú ihò.

4Kọ orin ìyìn sí Olúwa, ẹ̀yin olódodo;

kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ̀ mímọ́.

5Nítorí pé ìbínú rẹ̀ wà fún ìgbà díẹ̀,

ojúrere rẹ̀ wà títí ayérayé;

Ẹkún lè pẹ́ títí di alẹ́,

Ṣùgbọ́n ayọ̀ yóò wá ní òwúrọ̀.

6Ní ìgbà ayé mi, mo wí pé,

“a kì yóò ṣí mi ní ipò padà.”

7Nípa ojúrere rẹ, Olúwa,

ìwọ ti gbé mi kalẹ̀ bí òkè tí ó ní agbára;

ìwọ pa ojú rẹ mọ́,

àyà sì fò mí.

8Sí ọ Olúwa, ni mo ké pè é;

àti sí Olúwa ni mo sọkún fún àánú:

9“Èrè kí ni ó wà nínú ikú ìparun mi,

nínú lílọ sí ihò mi?

Eruku yóò a yìn ọ́ bí?

Ǹjẹ́ yóò sọ nípa òdodo rẹ?

10Gbọ́, Olúwa, kí o sì ṣàánú fún mi;

ìwọ Olúwa, jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi.”

11Ìwọ ti yí ìkáàánú mi di ijó fún mi;

ìwọ sì ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ mi, o sì fi aṣọ ayọ̀ wọ̀ mí,

12nítorí ìdí èyí ni kí ọkàn mi máa yìn ọ́, kí o má sì ṣe dákẹ́.

Ìwọ Olúwa Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ títí láé.