詩篇 9 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

詩篇 9:1-20

第 9 篇

稱頌上帝的公義

大衛的詩,交給樂長,調用「慕拉辨」9·0 慕拉辨」希伯來文的意思是「喪子」。

1耶和華啊,

我要全心全意地讚美你,

傳揚你一切奇妙的作為。

2我要因你歡喜快樂,

至高者啊,我要歌頌你的名。

3我的仇敵必在你面前敗退,

倒地身亡。

4你坐在寶座上按公義審判,

你為我主持公道。

5你斥責列國,消滅惡人,

永永遠遠抹去他們的名字。

6仇敵永遠滅亡了,

你把他們的城池連根拔起,

無人再記得他們。

7耶和華永遠掌權,

祂已設立施行審判的寶座。

8祂要以公義審判世界,

在萬民中伸張正義。

9耶和華是受欺壓之人的避難所,

是他們患難之時的避風港。

10耶和華啊,

凡認識你名的人都必信靠你,

因為你從來不丟棄尋求你的人。

11要歌頌住在錫安的耶和華,

在列邦傳揚祂的作為。

12祂追討血債,顧念受害者,

不忘傾聽受苦者的呼求。

13耶和華啊,

看看仇敵對我的迫害!

求你憐憫我,

救我離開死亡之門,

14我好在錫安的城門口稱頌你,

因你的拯救而歡樂。

15列邦挖了陷阱卻自陷其中,

設下網羅卻纏住自己的腳。

16耶和華彰顯了自己的公義,

使惡人自食其果。(細拉)

17惡人必下陰間,這是所有忘記上帝之人的結局。

18貧乏人不會永遠被遺忘,

受苦人的希望也不會一直落空。

19耶和華啊,求你起來,

別讓人向你誇勝,

願你審判列邦。

20耶和華啊,

求你使列邦恐懼戰抖,

讓他們明白自己不過是人。(細拉)

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 9:1-20

Saamu 9

Fún adarí orin. Ní ti ohun orin “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi.

1Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;

Èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.

2Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ;

Èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà;

Wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.

4Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú;

ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.

5Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;

Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.

6Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá,

Ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu;

àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.

7Olúwa jẹ ọba títí láé;

ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.

89.8: Ap 17.31.Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo;

yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.

9Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,

ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.

10Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ,

nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.

11Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni;

kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.

12Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;

òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!

Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,

14Kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ

ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni

àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.

15Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́;

ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.

16A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀;

àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.

17Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú,

àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run.

18Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé,

ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.

19Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí;

Jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.

20Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa;

jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. Sela.