詩篇 66 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

詩篇 66:1-20

第 66 篇

頌讚與感恩

一首詩歌,交給樂長。

1世人啊,你們要向上帝歡呼,

2頌讚祂榮耀的名,

讚美祂的榮耀。

3要對上帝說:「你的作為令人敬畏!

你的大能使敵人屈膝投降。

4普天下都敬拜你,

頌讚你,頌讚你的名。」(細拉)

5來吧,看看上帝的作為,

祂為世人行了何等奇妙的事!

6祂將滄海變為乾地,

讓百姓步行經過。

讓我們因祂的作為而歡欣吧!

7祂以大能永遠掌權,

祂的眼目鑒察列國,

悖逆之徒不可在祂面前妄自尊大。(細拉)

8列邦啊,要讚美我們的上帝,

讓歌頌祂的聲音四處飄揚。

9祂保全我們的生命,

不讓我們失腳滑倒。

10上帝啊,你試驗我們,

熬煉我們如熬煉銀子。

11你讓我們陷入網羅,

把重擔壓在我們的背上。

12你讓別人騎在我們的頭上。

我們曾經歷水火,

但你帶我們到達豐盛之地。

13我要帶著燔祭來到你殿中,

履行我向你許的誓言,

14就是我在危難中許下的誓言。

15我要獻上肥美的牲畜,

以公綿羊作馨香之祭獻給你,

我要獻上公牛和山羊。(細拉)

16敬畏上帝的人啊,

你們都來聽吧,

我要告訴你們祂為我所做的事。

17我曾開口向祂呼求,

揚聲讚美祂。

18倘若我心中藏匿罪惡,

主必不垂聽我的呼求。

19然而,上帝聽了我的禱告,

傾聽了我的祈求。

20上帝當受稱頌!

祂沒有對我的禱告拒而不聽,

也沒有收回祂對我的慈愛。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 66:1-20

Saamu 66

Fún adarí orin. Orin. Saamu.

1Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!

2Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀;

Ẹ kọrin ìyìnsí i,

3Ẹ wí fún Ọlọ́run “pé,

ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ!

Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá

rẹ yóò fi sìn ọ́.

4Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ;

wọn ń kọrin ìyìn sí ọ,

wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” Sela.

5Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe,

Iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!

6Ó yí Òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ,

wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá,

níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.

7Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀,

ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè

kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. Sela.

8Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn,

jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;

9Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa,

kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀

10Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò;

ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.

11Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n

o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa

12Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí

àwa la iná àti omi kọjá

ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.

13Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,

kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ

14Ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ

nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.

15Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ,

àti ẹbọ ọ̀rá àgbò;

èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. Sela.

16Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run;

ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.

17Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i:

Ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.

18Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi,

Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;

19Ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́

ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.

20Ìyìn ni fún Ọlọ́run

ẹni tí kò kọ àdúrà mi

tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!