詩篇 51 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

詩篇 51:1-19

第 51 篇

祈求上帝赦免

大衛與拔示芭通姦後,先知拿單來找他,他作了此詩,交給樂長。

1上帝啊,求你憐憫我,

因為你的慈愛永不改變;

求你除去我的過犯,

因為你有無限的憐憫。

2求你洗淨我的罪過,

清除我的罪惡。

3我知道自己的過犯,

我的罪惡一直縈繞眼前。

4我犯罪得罪了你,

唯獨得罪了你,

做了你看為邪惡的事,

所以你對我的責備是正當的,

你對我的審判是公正的。

5我生來就是個罪人,

在母腹成胎的時候就有罪。

6你所喜愛的是內心的誠實,

求你使我內心有智慧。

7求你用牛膝草潔淨我的罪,

使我乾淨;

求你洗淨我,使我比雪更白。

8求你讓我聽到歡喜快樂的聲音,

讓我這被你壓碎的骨頭可以歡跳。

9求你饒恕我的罪過,

除去我一切的罪惡。

10上帝啊,

求你為我造一顆純潔的心,

使我裡面重新有正直的靈。

11不要丟棄我,

使我離開你,

也不要從我身上收回你的聖靈。

12求你讓我重新享受蒙你拯救的喜樂,

賜我一顆樂意順服你的心靈。

13這樣,我就能把你的法則教導罪人,

使他們歸向你。

14拯救我的上帝啊,

求你赦免我殺人流血的罪,

使我頌揚你的公義。

15主啊,求你開我的口,

我要向你發出讚美。

16你不喜歡祭物,

否則我會獻上,

你也不喜愛燔祭。

17你所要的祭是憂傷的心靈。

上帝啊,你必不輕看憂傷痛悔的心。

18求你恩待錫安,重建耶路撒冷的城牆。

19那時,你必悅納誠心獻上的祭物、燔祭和全牲燔祭,

人們必把公牛獻在你的壇上。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 51:1-19

Saamu 51

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba.

1Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí

ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀,

gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀

kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.

2Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò

kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!

3Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi,

nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.

451.4: Ro 3.4.Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí

ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀,

kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀,

kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.

5Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi,

nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.

6Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú;

ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.

7Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́;

fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.

8Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn;

jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.

9Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi

kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.

10Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run,

kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.

11Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ,

kí o má ṣe gba ẹ̀mí mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.

12Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá,

kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.

13Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ,

àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.

14Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run,

ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi,

ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.

15Olúwa, ṣí mi ní ètè mi gbogbo,

àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.

16Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá;

Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.

17Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.

18Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni,

ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.

19Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo,

pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun,

nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.