詩篇 147 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

詩篇 147:1-20

第 147 篇

讚美上帝復興耶路撒冷

1你們要讚美耶和華!

歌頌我們的上帝,真是美好!

讚美祂,真是快樂合宜!

2耶和華重建耶路撒冷

召集被擄去的以色列人。

3祂醫治心靈破碎的人,

包紮他們的創傷。

4祂決定眾星的數目,

給它們一一命名。

5我們的主偉大無比,充滿力量,

祂的智慧沒有窮盡。

6耶和華扶持謙卑人,

毀滅邪惡人。

7你們要以感恩的心歌頌耶和華,

彈琴讚美我們的上帝。

8祂以雲霞遮蔽天空,

降雨水滋潤大地,

使山上長出綠草。

9祂賜食物給走獸,

餵養嗷嗷待哺的小烏鴉。

10耶和華所喜悅的不是強健的馬匹,

也不是矯捷的戰士,

11而是敬畏祂、仰望祂慈愛的人。

12耶路撒冷啊,要頌讚耶和華;

錫安啊,要讚美你的上帝。

13因為祂使你的城門堅固,

賜福給你的兒女。

14祂使你四境平安,

飽享上好的麥子。

15祂向大地發出命令,

祂的話迅速傳開。

16祂降下羊毛般的白雪,

撒下爐灰般的寒霜。

17祂拋下碎石般的冰雹,

誰能經得住祂降下的嚴寒呢?

18祂一聲令下,冰雪便溶化,

微風便吹拂,河川便奔流。

19祂將自己的話傳於雅各

將自己的律例和法令指示以色列

20祂未曾這樣對待其他國家,

他們不知道祂的律法。

你們要讚美耶和華!

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 147:1-20

Saamu 147

1Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa,

ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!

2Olúwa kọ́ Jerusalẹmu;

Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.

3Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn

ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.

4Ó ka iye àwọn ìràwọ̀

ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ

5Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára

òye rẹ̀ kò sì ní òpin.

6Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀

bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.

7Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa

fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.

8Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀

ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé

ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè

9Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko

àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.

10Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin

bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin

11Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.

12Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu

yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.

13Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára;

Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ

14Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀

òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.

15Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé

ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.

16Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn

ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú

17Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́

ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀

18Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀

ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́

ó sì mú odò rẹ̀ sàn.

19Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu

àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli

20Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, Bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀

wọn ko mọ òfin rẹ̀.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.