傳道書 12 – CCBT & YCB

Chinese Contemporary Bible (Traditional)

傳道書 12:1-14

1年輕時要記住你的創造主,不要等到衰老的歲月來臨時才哀歎:「我的日子毫無樂趣。」 2那時,太陽、月亮、星星都暗淡無光,雨後烏雲再現; 3守衛家園的手腳顫抖,強壯的身軀變得彎腰駝背;牙齒稀少,無法咀嚼;視力衰退,看不清楚; 4耳朵發背,聽不到推磨聲;小鳥一叫,人就起來;歌聲沙啞,不再美妙; 5懼怕高處,走路戰戰兢兢;頭髮白如銀杏,精力枯竭,慾望蕩然無存;人都走向永遠的歸宿,弔喪的人往來於街上; 6銀鏈斷裂,金碗摔壞,泉旁的瓶子破碎,井口的輪子朽爛。 7那時塵土必歸於塵土,靈也要歸回賜靈的上帝。 8傳道者說:「虛空的虛空,一切都是虛空。」 9傳道者不但有智慧,還把知識傳授給眾人。他經過細心推敲和研究之後,編寫了許多警世的箴言。 10傳道者費盡心思尋找金玉良言,所寫的都是正直誠實的道理。 11智者的言語好像趕牛的刺棍,他們收集的箴言像釘穩的釘子一樣牢靠,都是一位牧者所賜的。 12我親愛的兒子,還有一件事,你要聽我的忠告:著書多,沒有窮盡;讀書多,身體疲勞。

13以上所說的,總而言之,就是要敬畏上帝,遵守祂的誡命,這是人的本分。 14因為人一切的行為,無論善惡,包括一切隱秘事,上帝都必審問。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Oniwaasu 12:1-14

1Rántí Ẹlẹ́dàá rẹ

ní ọjọ́ èwe rẹ,

nígbà tí ọjọ́ ibi kò tí ì dé

àti tí ọdún kò tí ì ní súnmọ́ etílé, nígbà tí ìwọ yóò wí pé,

“Èmi kò ní ìdùnnú nínú wọn”

2Kí oòrùn àti ìmọ́lẹ̀

àti òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ tó ṣókùnkùn,

àti kí àwọsánmọ̀ tó padà lẹ́yìn òjò;

3Nígbà tí olùṣọ́ ilé yóò wárìrì

tí àwọn ọkùnrin alágbára yóò tẹríba,

nígbà tí àwọn tí ó ń lọ dákẹ́ nítorí pé wọn kò pọ̀,

tí àwọn tí ń wo òde láti ojú fèrèsé yóò ṣókùnkùn;

4Nígbà tí ìlẹ̀kùn sí ìgboro yóò tì

tí ariwo ọlọ yóò dákẹ́;

nígbà tí àwọn ènìyàn yóò dìde sí ariwo àwọn ẹyẹ

ṣùgbọ́n gbogbo orin wọn yóò máa lọ ilẹ̀.

5Nígbà tí ènìyàn yóò bẹ̀rù ibi gíga

àti ti ìfarapa ní ìgboro;

nígbà tí igi almondi yóò tanná

àti tí ẹlẹ́ǹgà yóò wọ́ ara rẹ̀ lọ

tí ìfẹ́ kò sì ní ru sókè mọ́

nígbà náà ni ènìyàn yóò lọ ilé rẹ́ ayérayé

tí àwọn aṣọ̀fọ̀ yóò máa rìn kiri ìgboro.

6Rántí rẹ̀ kí okùn fàdákà tó já,

tàbí kí ọpọ́n wúrà tó fọ́;

kí iṣà tó fọ́ níbi ìsun,

tàbí kí àyíká kẹ̀kẹ́ kí ó tó kán níbi kànga.

7Tí erùpẹ̀ yóò sì padà sí ilẹ̀ ibi tí ó ti wà,

tí ẹ̀mí yóò sì padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run tí ó fi í fún ni.

8“Asán! Asán!” ni Oniwaasu wí.

“Gbogbo rẹ̀ asán ni!”

Òpin gbogbo ọrọ̀

9Kì í ṣe wí pé Oniwaasu jẹ́ ọlọ́gbọ́n nìkan, ṣùgbọ́n ó tún kọ́ àwọn ènìyàn ní ìmọ̀. Ó rò ó dáradára ó sì ṣe àwárí, ó sì gbé ọ̀pọ̀lọpọ̀ òwe kalẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ. 10Oniwaasu wádìí láti rí àwọn ọ̀rọ̀ tí ó tọ̀nà, ohun tí ó kọ sì dúró ṣinṣin ó sì jẹ́ òtítọ́.

11Ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n dàbí ẹ̀gún, àkójọpọ̀ ọ̀rọ̀ wọn sì dàbí ìṣó tí a kàn pọ̀ dáradára, tí olùṣọ́-àgùntàn kan fi fún ni. 12Àti síwájú láti inú èyí, Ọmọ mi, gba ìmọ̀ràn.

Nínú ìwé púpọ̀, òpin kò sí, ìwé kíkà púpọ̀ a máa mú ara ṣàárẹ̀.

13Nísinsin yìí,

òpin gbogbo ọ̀rọ̀ tí a gbọ́ ni pé:

Bẹ̀rù Ọlọ́run, kí o sì pa òfin rẹ̀ mọ́,

nítorí èyí ni ojúṣe gbogbo ènìyàn.

14Nítorí Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ olúkúlùkù iṣẹ́

àti ohun ìkọ̀kọ̀,

kì bá à ṣe rere kì bá à ṣe búburú.