诗篇 9 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 9:1-20

第 9 篇

称颂上帝的公义

大卫的诗,交给乐长,调用“慕拉辨”9:0 慕拉辨”希伯来文的意思是“丧子”。

1耶和华啊,

我要全心全意地赞美你,

传扬你一切奇妙的作为。

2我要因你欢喜快乐,

至高者啊,我要歌颂你的名。

3我的仇敌必在你面前败退,

倒地身亡。

4你坐在宝座上按公义审判,

你为我主持公道。

5你斥责列国,消灭恶人,

永永远远抹去他们的名字。

6仇敌永远灭亡了,

你把他们的城池连根拔起,

无人再记得他们。

7耶和华永远掌权,

祂已设立施行审判的宝座。

8祂要以公义审判世界,

在万民中伸张正义。

9耶和华是受欺压之人的避难所,

是他们患难之时的避风港。

10耶和华啊,

凡认识你名的人都必信靠你,

因为你从来不丢弃寻求你的人。

11要歌颂住在锡安的耶和华,

在列邦传扬祂的作为。

12祂追讨血债,顾念受害者,

不忘倾听受苦者的呼求。

13耶和华啊,

看看仇敌对我的迫害!

求你怜悯我,

救我离开死亡之门,

14我好在锡安的城门口称颂你,

因你的拯救而欢乐。

15列邦挖了陷阱却自陷其中,

设下网罗却缠住自己的脚。

16耶和华彰显了自己的公义,

使恶人自食其果。(细拉)

17恶人必下阴间,这是所有忘记上帝之人的结局。

18贫乏人不会永远被遗忘,

受苦人的希望也不会一直落空。

19耶和华啊,求你起来,

别让人向你夸胜,

愿你审判列邦。

20耶和华啊,

求你使列邦恐惧战抖,

让他们明白自己不过是人。(细拉)

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 9:1-20

Saamu 9

Fún adarí orin. Ní ti ohun orin “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi.

1Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;

Èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.

2Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ;

Èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà;

Wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.

4Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú;

ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.

5Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;

Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.

6Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá,

Ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu;

àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.

7Olúwa jẹ ọba títí láé;

ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.

89.8: Ap 17.31.Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo;

yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.

9Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,

ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.

10Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ,

nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.

11Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni;

kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.

12Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;

òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!

Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,

14Kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ

ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni

àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.

15Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́;

ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.

16A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀;

àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.

17Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú,

àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run.

18Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé,

ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.

19Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí;

Jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.

20Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa;

jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. Sela.