诗篇 85 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 85:1-13

第 85 篇

为国家求福

可拉后裔的诗,交给乐长。

1耶和华啊,你赐福了你的土地,

使雅各的子孙重返家园。

2你赦免了你子民的罪过,

遮盖了他们所有的过犯。(细拉)

3你收回自己的怒气,

不发烈怒。

4拯救我们的上帝啊,

求你复兴我们,

止息你对我们的怒气。

5你要向我们永远发怒吗?

你的怒气要延续到万代吗?

6你不再复兴我们,

使你的子民靠你欢喜吗?

7耶和华啊,求你向我们施慈爱,拯救我们。

8我要听耶和华上帝所说的话,

因为祂应许赐平安给祂忠心的子民。

但我们不可再犯罪。

9祂拯救敬畏祂的人,

好让祂的荣耀常驻在我们的地上。

10慈爱和忠信同行,

公义与平安相亲。

11忠信从地而生,

公义从天而现。

12耶和华赐下祝福,

我们的土地就出产丰富。

13公义要行在祂面前,为祂开路。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 85:1-13

Saamu 85

Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.

1Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa;

ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.

2Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì

ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. Sela.

3Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan

ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.

4Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa,

kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.

5Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé?

Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?

6Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́,

pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?

7Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa,

Kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.

8Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí;

ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀:

Ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.

9Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,

pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.

10Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀;

òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.

11Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá

òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.

12Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́,

ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.

13Òdodo síwájú rẹ lọ

o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.