诗篇 56 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 56:1-13

第 56 篇

信靠上帝的祷告

大卫作的诗,交给乐长,调用“远方无声鸽”,大卫在迦特被非利士人抓住时所作。

1上帝啊,求你怜悯我,

因为仇敌攻击我,整日迫害我。

2我的仇敌整日攻击我,

许多人狂妄地迫害我。

3我害怕的时候,

仍要倚靠你。

4我赞美上帝的应许,

我信靠祂,就不惧怕,

区区世人能把我怎样?

5他们整天歪曲我的话,

总是图谋害我。

6他们勾结起来,

暗中监视我的行踪,

伺机害我。

7上帝啊,

不要让这些作恶的人逃脱,

求你在怒中毁灭他们。

8你知道我的哀伤,

你把我的眼泪收在袋中。

我的遭遇都记录在你的册子上。

9我向你求救的时候,

敌人都落荒而逃。

我知道上帝是我的帮助。

10我因上帝的应许而赞美祂,

我因耶和华的应许而赞美祂。

11我信靠上帝,就不惧怕,

区区世人能把我怎样?

12上帝啊,

我要恪守向你发的誓言,

献上感恩祭。

13因为你救我脱离死亡,

使我没有跌倒,

让我可以活在你面前,

沐浴生命之光。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 56:1-13

Saamu 56

Fún adarí orin. Ti ohùn “Àdàbà lórí Óákù òkè réré.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí àwọn ará Filistini ka mọ́ ní Gati.

1Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, nítorí àwọn ènìyàn ń fi ìgbónára lépa mi;

ní gbogbo ọjọ́ ni wọn ń kọjú ìjà

sí mi, wọn ń ni mi lára.

2Àwọn ọ̀tá mi ń lé mi ní gbogbo ọjọ́,

àwọn ènìyàn ń kọjú ìjà sí mi nínú ìgbéraga wọn.

3Nígbà tí ẹ̀rù bà ń bà mí,

èmi o gbẹ́kẹ̀lé ọ.

4Nínú Ọlọ́run èmi yóò máa yìn ọ̀rọ̀ rẹ,

nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi; ẹ̀rù kì yóò bà mí

kí ni ẹran-ara lè ṣe sí mi?

5Wọn ń yí ọ̀rọ̀ mí ní gbogbo ọjọ́,

wọn ń gbèrò nígbà gbogbo láti ṣe mí níbi.

6Wọn kó ara wọn jọ, wọ́n ba

Wọ́n ń ṣọ́ ìgbésẹ̀ mi

wọn ń làkàkà láti gba ẹ̀mí mi.

7San ẹ̀san iṣẹ́ búburú wọ́n fún wọn;

Ní ìbínú rẹ, Ọlọ́run, wọ́ àwọn ènìyàn náà bọ́ sílẹ̀.

8Kọ ẹkún mi sílẹ̀;

kó omijé mi sí ìgò rẹ,

wọ́n kò ha sí nínú ìkọ̀sílẹ̀ rẹ bí?

9Nígbà náà ni àwọn ọ̀tá mi yóò pẹ̀yìndà

nígbà tí mo bá pè fún ìrànlọ́wọ́

nípa èyí ni mo mọ̀ pé Ọlọ́run ń bẹ fún mi.

10Nínú Ọlọ́run, ẹni tí mo yìn ọ̀rọ̀ rẹ̀

nínú Olúwa, ẹni tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀:

11Nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi:

ẹ̀rù kì yóò bà mí.

Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?

12Mo jẹ́ ẹ̀jẹ́ lábẹ́ rẹ Ọlọ́run:

èmi o mú ìyìn mi wá fún ọ.

13Nítorí ìwọ tí gbà mí lọ́wọ́ ikú

àti ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú,

kí èmí lè máa rìn níwájú Ọlọ́run

ní ìmọ́lẹ̀ àwọn alààyè.