诗篇 54 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 54:1-7

第 54 篇

祈求上帝的拯救

西弗人去告诉扫罗:“大卫藏在我们那里”,那时大卫作了这首训诲诗,交给乐长,用弦乐器。

1上帝啊,

求你凭你的名拯救我!

求你用你的大能为我申冤!

2上帝啊,求你垂听我的祷告,

留心我口中的话。

3因为傲慢的人起来攻击我,

目无上帝的暴徒正寻索我的性命。(细拉)

4看啊,上帝帮助我,主扶持我,

5祂必使我的仇敌自作自受。

信实的上帝啊,

求你毁灭他们。

6耶和华啊,

我甘心乐意献上祭物,

我要赞美你的名,

因为你的名是美善的。

7你拯救我脱离一切艰难,

让我傲视仇敌。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 54:1-7

Saamu 54

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa”.

1Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ:

dá mi láre nípa agbára rẹ.

2Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run;

fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.

3Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí.

Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa,

àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.

4Kíyèsi i Ọlọ́run ni Olùrànlọ́wọ́ mi;

Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró,

pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.

5Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi;

pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.

6Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ,

èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa,

nítorí tí ó dára.

7Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo

ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.