诗篇 51 – CCB & YCB

Chinese Contemporary Bible (Simplified)

诗篇 51:1-19

第 51 篇

祈求上帝赦免

大卫与拔示芭通奸后,先知拿单来找他,他作了此诗,交给乐长。

1上帝啊,求你怜悯我,

因为你的慈爱永不改变;

求你除去我的过犯,

因为你有无限的怜悯。

2求你洗净我的罪过,

清除我的罪恶。

3我知道自己的过犯,

我的罪恶一直萦绕眼前。

4我犯罪得罪了你,

唯独得罪了你,

做了你看为邪恶的事,

所以你对我的责备是正当的,

你对我的审判是公正的。

5我生来就是个罪人,

在母腹成胎的时候就有罪。

6你所喜爱的是内心的诚实,

求你使我内心有智慧。

7求你用牛膝草洁净我的罪,

使我干净;

求你洗净我,使我比雪更白。

8求你让我听到欢喜快乐的声音,

让我这被你压碎的骨头可以欢跳。

9求你饶恕我的罪过,

除去我一切的罪恶。

10上帝啊,

求你为我造一颗纯洁的心,

使我里面重新有正直的灵。

11不要丢弃我,

使我离开你,

也不要从我身上收回你的圣灵。

12求你让我重新享受蒙你拯救的喜乐,

赐我一颗乐意顺服你的心灵。

13这样,我就能把你的法则教导罪人,

使他们归向你。

14拯救我的上帝啊,

求你赦免我杀人流血的罪,

使我颂扬你的公义。

15主啊,求你开我的口,

我要向你发出赞美。

16你不喜欢祭物,

否则我会献上,

你也不喜爱燔祭。

17你所要的祭是忧伤的心灵。

上帝啊,你必不轻看忧伤痛悔的心。

18求你恩待锡安,重建耶路撒冷的城墙。

19那时,你必悦纳诚心献上的祭物、燔祭和全牲燔祭,

人们必把公牛献在你的坛上。

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn

Saamu 51:1-19

Saamu 51

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba.

1Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí

ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀,

gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀

kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.

2Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò

kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!

3Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi,

nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.

451.4: Ro 3.4.Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí

ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀,

kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀,

kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.

5Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi,

nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.

6Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú;

ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.

7Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́;

fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.

8Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn;

jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.

9Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi

kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.

10Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run,

kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.

11Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ,

kí o má ṣe gba ẹ̀mí mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.

12Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá,

kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.

13Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ,

àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.

14Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run,

ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi,

ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.

15Olúwa, ṣí mi ní ètè mi gbogbo,

àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.

16Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá;

Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.

17Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.

18Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni,

ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.

19Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo,

pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun,

nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.